April 4 sí 10
JÓÒBÙ 16-20
Orin 79 àti Àdúrà
Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN
“Máa Sọ Ọ̀rọ̀ Rere Tó Ń Gbéni Ró Tó sì Ń Fúnni Lókun”: (10 min.)
Job 16:4, 5
—Ó yẹ kí ọ̀rọ̀ ẹni tó ń gbani nímọ̀ràn máa gbéni ró (w90 3/15 ojú ìwé 27 ìpínrọ̀ 1 àti 2) Job 19:2
—Ọ̀rọ̀ kòbákùngbé tí Bílídádì sọ sí Jóòbù mú kí Jóòbù fi ìbínú sọ̀rọ̀ (w06 3/15 ojú ìwé 15 ìpínrọ̀ 6; w94 10/1 ojú ìwé 32) Job 19:25
—Nígbà tí wàhálà bá Jóòbù dé góńgó, ìrètí àjíǹde tù ú nínú (w06 3/15 ojú ìwé 15 ìpínrọ̀ 5; it-2 735 ojú ìwé 735 ìpínrọ̀ 2 àti 3)
Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: (8 min.)
Job 19:20
—Kí ni Jóòbù ní lọ́kàn nígbà tó sọ pé ‘bí awọ eyín mi ni mo fi yèbọ́’? (w06 3/15 ojú ìwé 15 ìpínrọ̀ 1; it-2 ojú ìwé 977 ìpínrọ̀ 1) Job 19:26
—Báwo ni Jóòbù ṣe “rí Ọlọ́run,” nígbà tí èèyàn kankan ò lè rí Jèhófà? (w94 11/15 ojú ìwé 19 ìpínrọ̀ 17) Ẹ̀kọ́ wo ni Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí kọ́ mi nípa Jèhófà?
Àwọn kókó wo látinú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí ni mo lè lò lóde ẹ̀rí?
Bíbélì Kíkà: Job 19:1-23 (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
MÁA LO ARA RẸ LẸ́NU IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ
Múra Ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ Oṣù Yìí Sílẹ̀: (15 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ kí àwọn ará wo ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn fídíò ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀, kó o sì jíròrò àwọn kókó pàtàkì látinú àwọn fídíò náà. Gba àwọn ará níyànjú pé kí wọ́n kọ àwọn ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ wọn sílẹ̀.
MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Orin 42
“Ohun Tuntun Tá A Lè Fi Bẹ̀rẹ̀ Ìjíròrò”: (10 min.) Ìjíròrò. Gba àwọn ará níyànjú pé kí wọ́n máa lo apá tá a pè ní “Ohun Tí Bíbélì Sọ” láti fi bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò táá yọrí sí ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì.
Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn Òǹkàwé: (5 min.) Alàgbà ni kó sọ àsọyé yìí. A gbé e ka Ilé Ìṣọ́ February 15, 2015, ojú ìwé 30, ìpínrọ̀ 4 sí 6.
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: ia orí 12 ìpínrọ̀ 13 sí 25, àti àtúnyẹ̀wò tó wà lójú ìwé 107 (30 min.)
Àtúnyẹ̀wò àti Ohun Tá A Máa Kọ́ Lọ́sẹ̀ Tó Ń Bọ̀ (3 min.)
Orin 65 àti Àdúrà