Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Fi Ọ̀yàyà Kí Wọn Káàbọ̀

Fi Ọ̀yàyà Kí Wọn Káàbọ̀

Àwọn wo la fẹ́ fi ọ̀yàyà kí káàbọ̀? Ẹnikẹ́ni tó bá wá sí àwọn ìpàdé wa, ì báà jẹ́ àwọn tó ṣẹ̀sẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í wá tàbí àwọn tá a ti jọ wà tipẹ́. (Ro 15:7; Heb 13:2) Ó lè jẹ́ àwọn ará wa tó wá láti orílẹ̀-èdè míì tàbí àwọn aláìṣiṣẹ́mọ́ tó jẹ́ pé fún ọ̀pọ̀ ọdún ni wọn ò ti wá sípàdé mọ́. Tó bá jẹ́ pé àwa la wà ní èyíkéyìí lára àwọn ipò tá a sọ yìí, ṣé a ò ní fẹ́ kí wọ́n fi ọ̀yàyà kí wa káàbọ̀? (Mt 7:12) Torí náà, á dáa tá a bá lè gbìyànjú láti máa kí àwọn tó wà nínú Gbọ̀ngàn Ìjọba kí ìpàdé tó bẹ̀rẹ̀ àti nígbà tí ìpàdé bá parí. Èyí á mú kí ara tu gbogbo wa, ìfẹ́ á máa gbilẹ̀ láàárín wa, a ó sì máa tipa bẹ́ẹ̀ bọlá fún Jèhófà. (Mt 5:16) Òótọ́ ni pé ó lè má ṣeé ṣe fún wa láti kí gbogbo àwọn tó wà nípàdé lọ́kọ̀ọ̀kan. Síbẹ̀, tí kálukú wa bá ń ṣe ipa tirẹ̀, ara máa tu gbogbo wa. *

Kì í ṣe ìgbà tá a bá ń ṣe àwọn àkànṣe ìpàdé bí Ìrántí Ikú Kristi nìkan ló yẹ ká máa fọ̀yàyà kí àwọn èèyàn, ìgbà gbogbo ló yẹ ká máa ṣe bẹ́ẹ̀. Tí àwọn ẹni tuntun bá rí i pé a nífẹ̀ẹ́ ara wa lóòótọ́, èyí á mú kí wọ́n máa yin Ọlọ́run, wọ́n sì lè wá dara pọ̀ mọ́ wa nínú ìjọsìn tòótọ́.Jo 13:35.

^ ìpínrọ̀ 3 Tí àwọn tá a ti yọ lẹ́gbẹ́ àtàwọn tó mú ara wọn kúrò lẹ́gbẹ́ bá wá sípàdé, ká má gbàgbé ìlànà Bíbélì tó sọ pé ká fi ààlà sí àjọṣe wa pẹ̀lú irú àwọn èèyàn bẹ́ẹ̀.1Kọ 5:11; 2Jo 10.