Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

April 1-​7

1 KỌ́RÍŃTÌ 7-9

April 1-​7
  • Orin 136 àti Àdúrà

  • Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

  • Ẹ̀bùn Ni Wíwà Láìní Ọkọ Tàbí Aya”: (10 min.)

    • 1Kọ 7:32​—Ẹni tí kò ṣègbéyàwó lè sin Jèhófà láìsí àwọn àníyàn tí àwọn tọkọtaya máa ń ní (w11 1/15 18 ¶3)

    • 1Kọ 7:​33, 34​—Àwọn Kristẹni tó ti ṣègbéyàwó “máa ń ṣàníyàn nípa àwọn ohun ti ayé” (w08 7/15 27 ¶1)

    • 1Kọ 7:​37, 38​—Àwọn Kristẹni tí kò bá ṣègbéyàwó nítorí àwọn àfojúsùn tẹ̀mí tí wọ́n ń lé, máa “ṣe dáadáa” ju àwọn tó ti ṣègbéyàwó lọ (w96 10/15 12-13 ¶14)

  • Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: (8 min.)

    • 1Kọ 7:11​—Kí ló lè mú kí tọkọtaya Kristẹni kan sọ pé àwọn fẹ́ pínyà? (lv àfikún 219 ¶2-221 ¶3)

    • 1Kọ 7:36​—Kí nìdí tó fi yẹ kí àwọn Kristẹni “kọjá ìgbà ìtànná èwe” kí wọ́n tó ṣe ìgbéyàwó? (w00 7/15 31 ¶2)

    • Kí ni Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí kọ́ ẹ nípa Jèhófà?

    • Àwọn ìṣúra tẹ̀mí wo lo tún rí látinú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí?

  • Bíbélì Kíkà: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) 1Kọ 8:​1-13 (th ẹ̀kọ́ 5)

MÁA LO ARA RẸ LẸ́NU IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

  • Tẹra Mọ́ Kíkàwé àti Kíkọ́ni: (10 min.) Ìjíròrò. Ẹ wo fídíò Nasẹ̀ Ìwé Mímọ́ Lọ́nà Tó Yẹ, lẹ́yìn náà, ẹ jíròrò ẹ̀kọ́ 4 nínú ìwé pẹlẹbẹ Kíkọ́ni.

  • Àsọyé: (5 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) w12 11/15 20​—Àkòrí: Ṣé Àwọn Tó Yàn Láti Má Ṣe Ní Ọkọ Tàbí Aya Gba Ẹ̀bùn Yìí Lọ́nà Ìyanu? (th ẹ̀kọ́ 12)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

  • Orin 37

  • O Lè Fipò Àpọ́n Ẹ Ṣàṣeyọrí Lẹ́nu Iṣẹ́ Ìsìn Jèhófà: (15 min.) Jẹ́ kí àwọn ará wo fídíò náà. Lẹ́yìn náà, bi àwọn ará ní ìbéèrè yìí: Ìṣòro wo ni àwọn tí kò tíì ṣègbéyàwó ń dojú kọ? (1Kọ 7:39) Kí la rí kọ́ lára ọmọbìnrin Jẹ́fútà? Kí ni Jèhófà máa ń fún àwọn tó ń rìn nínú ìwà títọ́? (Sm 84:11) Báwo làwọn ará ìjọ ṣe lè fún àwọn tí kò tíì ṣe ìgbéyàwó ní ìṣírí? Kí làwọn nǹkan tí ẹni tí kò tíì ṣe ìgbéyàwó lè ṣe nínú ètò Ọlọ́run?

  • Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: (30 min.) bh orí 4 ¶12-14 àti àfikún Òtítọ́ Nípa Baba, Ọmọ, àti Ẹ̀mí Mímọ́

  • Àtúnyẹ̀wò àti Ohun Tá A Máa Kọ́ Lọ́sẹ̀ Tó Ń Bọ̀ (3 min.)

  • Orin 42 àti Àdúrà