Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Kí Ló Ṣe Pàtàkì Jù Sí Mi?

Kí Ló Ṣe Pàtàkì Jù Sí Mi?

Jékọ́bù bá áńgẹ́lì jìjàkadì torí kó lè gba ohun kan tó ṣe pàtàkì gan-an, ìyẹn ìbùkún Jèhófà. (Jẹ 32:24-31; Ho 12:3, 4) Àwa ńkọ́? Ṣé a ṣe tán láti fi gbogbo okun àti agbára wa ṣègbọràn sí Jèhófà, ká lè gba ìbùkún rẹ̀? Bí àpẹẹrẹ, tí àsìkò ìpàdé bá forígbárí pẹ̀lú àsìkò tá a lè ṣe àfikún iṣẹ́, èwo la máa ṣe? Tá a bá ń lo àkókò wa, okun wa àtàwọn ohun ìní wa fún Jèhófà, ó máa ‘tú ìbùkún sórí wa títí a kò fi ní ṣaláìní ohunkóhun.’ (Mal 3:10) Á máa tọ́ wa sọ́nà, á máa dáàbò bò wá, á sì máa pèsè gbogbo ohun tá a nílò.​—Mt 6:33; Heb 13:5.

WO FÍDÍÒ NÁÀ JẸ́ KÍ ÀWỌN ÀFOJÚSÙN TẸ̀MÍ WÀ LỌ́KÀN RẸ DIGBÍ, KÓ O SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Báwo ni ohun tí arábìnrin yìí fẹ́ràn ṣe di ìdẹwò fún un?

  • Báwo ni iṣẹ́ oúnjẹ òòjọ́ wa ṣe lè di ìdẹwò fún wa?

  • Kí nìdí tó fi yẹ kí Tímótì máa ní àfojúsùn tẹ̀mí kódà lẹ́yìn tí òtítọ́ ti jinlẹ̀ nínú rẹ̀?​—1Ti 4:16

  • Kí ló ṣe pàtàkì jù nígbèésí ayé rẹ?

    Báwo la ṣe lè fi hàn pé iṣẹ́ Ọlọ́run la kà sí pàtàkì jù?