MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Fi Orin Yin Jèhófà
Pọ́ọ̀lù àti Sílà fi orin yin Jèhófà nígbà tí wọ́n wà lẹ́wọ̀n. (Iṣe 16:25) Ó dájú pé orin tí wọ́n ń kọ yẹn fún wọn lókun láti fara da ipò tí wọ́n wà. Àwa náà ńkọ́ lónìí? Tá a bá wà nínú ìṣòro, àwọn orin tá à ń lò ní ìpàdé àti àwọn orin tí wọ́n fẹnu kọ máa ń fún wa lókun, ó sì máa ń ràn wá lọ́wọ́ láti jẹ́ olóòótọ́ sí Jèhófà. Àmọ́ ju gbogbo ìyẹn lọ, àwọn orin yẹn tún máa ń fìyìn fún Jèhófà. (Sm 28:7) Ó ti pẹ́ tí ètò Ọlọ́run ti máa ń rọ̀ wá pé ká gbìyànjú láti mọ àwọn ọ̀rọ̀ orin náà sórí. Ṣé o ti ṣe bẹ́ẹ̀? A lè fi àwọn orin yẹn dánra wò ká sì kọ́ àwọn ọ̀rọ̀ inú wọn nígbà ìjọsìn ìdílé.
WO FÍDÍÒ NÁÀ ÀWỌN ỌMỌDÉ Ń FI ORIN YIN JÈHÓFÀ, LẸ́YÌN NÁÀ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:
-
Tá a bá ń kọ orin Ìjọba Ọlọ́run, àǹfààní wo ló máa ṣe fún wa?
-
Báwo làwọn tó ń ṣiṣẹ́ ní ẹ̀ka tí wọ́n ti ń gbohùn sílẹ̀ ṣe máa ń múra sílẹ̀ fún àwọn tó fẹ́ wá kọrin?
-
Báwo làwọn ọmọdé àti ìdílé wọn ṣe máa ń múra sílẹ̀ fún orin tí wọ́n fẹ́ lọ kọ?
-
Àwọn orin Ìjọba Ọlọ́run wo lo fẹ́ràn jù, kí sì nìdí?