Wọ́n Fìmọ̀ Ṣọ̀kan Láti Ṣe Ìpinnu Tó Dá Lórí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run
Ẹ̀kọ́ wo la rí kọ́ nínú bí wọ́n ṣe yanjú ìṣòro náà?
15:1, 2—Jẹ́ ẹlẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀ àti onísùúrù. Pọ́ọ̀lù àti Bánábà ò fi ọgbọ́n ara wọn yanjú ọ̀rọ̀ náà, ṣe ni wọ́n béèrè ìtọ́sọ́nà lọ́dọ̀ ètò Ọlọ́run.
15:28, 29—Fọkàn tán ètò Ọlọ́run. Ó dá ìjọ lójú pé Jèhófà máa lo ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ àti Jésù láti yanjú ọ̀rọ̀ náà.
16:4, 5—Jẹ́ onígbọràn. Àwọn ìjọ ń pọ̀ sí i bí wọ́n ṣe ń tẹ̀ lé ìtọ́ni tí ìgbìmọ̀ olùdarí ń fún wọn.