February 22 sí 28
NEHEMÁYÀ 12-13
Orin 106 àti Àdúrà
Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN
“Àwọn Ẹ̀kọ́ Tí A Rí Kọ́ Lára Nehemáyà”: (10 min.)
Ne 13:4-9
—Yẹra fún ẹgbẹ́ búburú (w13 8/15 ojú ìwé 4 ìpínrọ̀ 5 sí 8) Ne 13:15-21
—Máa fi nǹkan tẹ̀mí ṣáájú (w13 8/15 ojú ìwé 5 sí 6 ìpínrọ̀ 13 sí 15) Ne 13:23-27
—Máa hùwà tó yẹ Kristẹni ní gbogbo ìgbà (w13 8/15 ojú ìwé 6 sí 7 ìpínrọ̀ 16 sí 18)
Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: (8 min.)
Ne 12:31
—Àǹfààní wo ló wà nínú bí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe ní ẹgbẹ́ akọrin méjì? (it-2 ojú ìwé 454 ìpínrọ̀ 1) Ne 13:31b
—Kí ni Nehemáyà ń bẹ Jèhófà pé kó ṣe? (w11 2/1 ojú ìwé 14 ìpínrọ̀ 3 sí 5) Ẹ̀kọ́ wo ni Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí kọ́ mi nípa Jèhófà?
Àwọn kókó wo látinú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí ni mo lè lò lóde ẹ̀rí?
Bíbélì Kíkà: Ne 12:1-26 (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
MÁA LO ARA RẸ LẸ́NU IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ
Nígbà Àkọ́kọ́: (2 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Fún ẹnì kan tí kò fi bẹ́ẹ̀ nífẹ̀ẹ́ sí ọ̀rọ̀ rẹ ní ìwé ìkésíni sí Ìrántí Ikú Kristi.
Nígbà Àkọ́kọ́: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Fún ẹnì kan tó nífẹ̀ẹ́ sí ọ̀rọ̀ rẹ ní ìwé ìkésíni sí Ìrántí Ikú Kristi àti ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́. Sọ ohun tí wàá bá ẹni náà jíròrò nígbà tó o bá pa dà wá.
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì: (6 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Fi ojú ìwé 206 sí 208 nínú ìwé Bíbélì Fi Kọ́ni ṣàlàyé ohun tí Ìrántí Ikú Kristi túmọ̀ sí fún akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì rẹ. Sọ fún akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì rẹ bí o ṣe fẹ́ ràn án lọ́wọ́ kó lè wá sí Ìrántí Ikú Kristi.
MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Orin 5
“Pe Àwọn Èèyàn ní Ìpínlẹ̀ Ìwàásù Yín Wá sí Ìrántí Ikú Kristi!”: (15 min.) Ìjíròrò. Sọ bí ẹ ṣe máa pín ìwé ìkésíni yìí fáwọn tó wà ní ìpínlẹ̀ ìwàásù ìjọ yín. Nígbà tó o bá ń bójú tó ìsọ̀rí tá a pè ní “Ohun Tó O Lè Ṣe,” jẹ́ kí àwọn ará wo fídíò Ìrántí Ikú Kristi. Gba àwọn ará níyànjú láti kópa ní kíkún nígbà tá a bá ń pín ìwé ìkésíni náà, kí wọ́n pa dà lọ sọ́dọ̀ àwọn tó nífẹ̀ẹ́ sí ọ̀rọ̀ wọn. Ṣe àṣefihàn kan.
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: ia orí 9 ìpínrọ̀ 14 sí 24, àtúnyẹ̀wò tó wà lójú ìwé 82 (30 min.)
Àtúnyẹ̀wò àti Ohun Tá A Máa Kọ́ Lọ́sẹ̀ Tó Ń Bọ̀ (3 min.)
Orin 147 àti Àdúrà