MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
“Bọlá fún Baba Rẹ àti Ìyá Rẹ”
Nígbà tí Jésù wà láyé, ó sọ̀rọ̀ nípa àṣẹ pàtàkì náà: “Bọlá fún baba rẹ àti ìyá rẹ.” (Ẹk 20:12; Mt 15:4) Jésù lẹ́nu ọ̀rọ̀ torí pé ó ṣègbọràn sí àwọn òbí rẹ̀ nígbà tó wà ní ọ̀dọ́. (Lk 2:51) Nígbà tó sì dàgbà, ó ṣètò pé kí ẹnì kan máa tọ́jú ìyá rẹ̀ tí òun bá kú. —Joh 19:26, 27.
Bákan náà, lóde òní, tí àwọn ọ̀dọ́ Kristẹni bá ń gbọ́ràn sí àwọn òbí wọn lẹ́nu tí wọ́n sì ń bá wọn sọ̀rọ̀ tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀, ńṣe ni wọ́n ń fi hàn pé àwọn ń bọlá fún wọn. Àṣẹ yìí kò yọ ẹnikẹ́ni sílẹ̀. Kódà, bí àwọn òbí wa bá tiẹ̀ ti darúgbó pàápàá, a gbọ́dọ̀ máa bá a nìṣó láti bọlá fún wọn ká sì máa jàǹfààní látinú ọgbọ́n wọn. (Owe 23:22) Ọ̀nà míì tá a tún lè gbà bọlá fún àwọn òbí wa ni pé ká máa bójú tó ìmọ̀lára wọn àti ìnáwó wọn nígbà tó bá yẹ bẹ́ẹ̀. (1Ti 5:8) Yálà a jẹ́ ọ̀dọ́ tàbí a ti dàgbà, tá a bá ní ìjùmọ̀sọ̀rọ̀pọ̀ tó dán mọ́rán pẹ̀lú àwọn òbí wa, ńṣe là ń fi hàn pé a bọlá fún wọn.
WO ERÉ OJÚ PÁTÁKÓ NÁÀ BÁWO NI MO ṢE LÈ MÁA SỌ TINÚ MI FÁWỌN ÒBÍ MI? LẸ́YÌN NÁÀ, DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:
-
Kí ló lè mú kó ṣòro fún ẹ láti bá àwọn òbí ẹ sọ̀rọ̀?
-
Báwo lo ṣe lè bọlá fún àwọn òbí rẹ tó o bá ń bá wọn sọ̀rọ̀?
-
Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé kó o máa sapá láti bá àwọn òbí rẹ sọ̀rọ̀? (Owe 15:22)