Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

February 3-9

SÁÀMÙ 144-146

February 3-9

Orin 145 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. “Aláyọ̀ Ni Àwọn Tí Jèhófà Jẹ́ Ọlọ́run Wọn!”

(10 min.)

Jèhófà máa ń bù kún àwọn tó bá gbẹ́kẹ̀ lé e (Sm 144:11-15; w18.04 32 ¶3-4)

Ìrètí tá a ní ń múnú wa dùn (Sm 146:5; w22.10 28 ¶16-17)

Títí láé làwọn tí Jèhófà jẹ́ Ọlọ́run wọn á máa láyọ̀ (Sm 146:10; w18.01 26 ¶19-20)

Tá a bá ń sin Jèhófà tọkàntọkàn, a máa láyọ̀ bá a tiẹ̀ níṣòro

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Sm 145:15, 16—Tá a bá ronú jinlẹ̀ lórí ẹsẹ Bíbélì yìí, ọwọ́ wo ló yẹ ká fi máa mú àwọn ẹranko? (it-1 111 ¶9)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Ẹni náà sọ fún ẹ pé ọmọ yunifásítì lòun. (lmd ẹ̀kọ́ 1 kókó 5)

5. Pa Dà Lọ

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ÀÌJẸ́-BÍ-ÀṢÀ. Fi fídíò kan látinú Àpótí Ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́ hàn án, kẹ́ ẹ sì jíròrò ẹ̀. (lmd ẹ̀kọ́ 7 kókó 4)

6. Àsọyé

(4 min.) lmd àfikún A kókó 7—Àkòrí: Ó Yẹ Kí Aya Ní Ọ̀wọ̀ Tó Jinlẹ̀ fún Ọkọ Ẹ̀. (th ẹ̀kọ́ 1)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 59

7. Jèhófà Fẹ́ Kó O Máa Láyọ̀

(10 min.) Ìjíròrò.

Ọlọ́run aláyọ̀ ni Jèhófà. (1Ti 1:11) Ọ̀pọ̀ ẹ̀bùn rere tó fún wa jẹ́ ká rí i pé ó nífẹ̀ẹ́ wa, ó sì fẹ́ ká láyọ̀. (Onw 3:12, 13) Ẹ jẹ́ ká wo méjì lára àwọn ẹ̀bùn yìí, ìyẹn oúnjẹ àti ohùn tó ń tuni lára.

Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ Àwọn Ohun Tí Jèhófà Dá Fi Hàn Pé Ó Fẹ́ Ká Máa Yọ̀—Oúnjẹ Aládùn àti Ohùn Tó Ń Tuni Lára. Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

  • Báwo ni ẹ̀bùn oúnjẹ àti ohùn tó ń tuni lára tí Jèhófà fún wa ṣe jẹ́ kó dá ẹ lójú pé ó fẹ́ kó o láyọ̀?

Ka Sáàmù 32:8. Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

  • Torí o mọ̀ pé Jèhófà fẹ́ kó o láyọ̀, báwo nìyẹn ṣe máa jẹ́ kó túbọ̀ wù ẹ́ láti máa tẹ̀ lé ìmọ̀ràn ẹ̀ tó wà nínú Bíbélì àti èyí tí ètò ẹ̀ ń fún wa?

8. Ohun Tó Ń Fẹ́ Àbójútó Nínú Ìjọ

(5 min.)

9. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

(30 min.) bt orí 22 ¶1-6

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 85 àti Àdúrà