Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

‘Ẹ Má Ṣe Dí Iṣẹ́ Náà Lọ́wọ́’

‘Ẹ Má Ṣe Dí Iṣẹ́ Náà Lọ́wọ́’

Jéṣúà (tàbí Jóṣúà) Àlùfáà Àgbà àti Gómínà Serubábélì bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ tẹ́ńpìlì láìka àṣẹ ọba tí wọ́n fi fòfin de iṣẹ́ náà sí (Ẹsr 5:1, 2; w22.03 18 ¶13)

Nígbà táwọn alátakò béèrè ẹni tó fún wọn láṣẹ láti kọ́ ilé náà, àwọn Júù tọ́ka sí àṣẹ tí Ọba Kírúsì pa (Ẹsr 5:3, 17; w86 6/1 29, àpótí ¶2-3)

Ọba náà ṣèwádìí, ó sì rí i pé lóòótọ́ ni Ọba Kírúsì fún wọn láṣẹ láti kọ́ ilé náà, ó wá pàṣẹ fáwọn alátakò náà pé wọn ò gbọ́dọ̀ dí iṣẹ́ náà lọ́wọ́ (Ẹsr 6:7, 8; w22.03 15 ¶7)

RONÚ LÓRÍ ÌBÉÈRÈ YÌÍ: Báwo ni ìtàn Bíbélì yìí ṣe jẹ́ ká rí i pé ó yẹ ká máa tẹ̀ lé ìtọ́ni àwọn tí Jèhófà yàn láti máa bójú tó wa, kódà tí ohun tí wọ́n ní ká ṣe ò bá fi bẹ́ẹ̀ yé wa?​—w22.03 19 ¶16.