Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

August 26–September 1

SÁÀMÙ 78

August 26–September 1

Orin 97 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. Ìkìlọ̀ Ni Ìwà Àìṣòótọ́ Àwọn Ọmọ Ísírẹ́lì Jẹ́ fún Wa

(10 min.)

Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gbàgbé àwọn iṣẹ́ àgbàyanu tí Jèhófà ṣe (Sm 78:11, 42; w96 12/1 29-30)

Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ò mọyì àwọn nǹkan tí Jèhófà pèsè fún wọn (Sm 78:19; w06 7/15 17 ¶16)

Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ò kẹ́kọ̀ọ́ látinú àṣìṣe wọn, dípò bẹ́ẹ̀ ṣe ni wọ́n sọ ìwà burúkú dàṣà (Sm 78:40, 41, 56, 57; w11 7/1 10 ¶3-4)


RONÚ LÓRÍ ÌBÉÈRÈ YÌÍ: Kí ni ò ní jẹ́ ká di aláìṣòótọ́ sí Jèhófà?

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Sm 78:24, 25—Kí nìdí tí Bíbélì fi pe mánà ní “ọkà ọ̀run” àti “oúnjẹ àwọn alágbára”? (w06 7/15 11 ¶5)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(3 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Fi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ ẹni náà. (lmd ẹ̀kọ́ 5 kókó 5)

5. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(3 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Fi ọ̀kan nínú àwọn ìwé ìléwọ́ wa bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò. Fi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ ẹni náà. (lmd ẹ̀kọ́ 5 kókó 4)

6. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(1 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Ẹni náà sọ fún ẹ pé kó o má jẹ́ kọ́rọ̀ ẹ gùn jù. Fi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ ẹni náà. (lmd ẹ̀kọ́ 2 kókó 5)

7. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ÀÌJẸ́-BÍ-ÀṢÀ. Wá ọ̀nà tó o lè gbà jẹ́ kẹ́ni náà mọ̀ pé Ẹlẹ́rìí Jèhófà ni ẹ́ láìjẹ́ pé o mẹ́nu ba ọ̀rọ̀ Bíbélì, kó o sì fi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ̀ ọ́. (lmd ẹ̀kọ́ 2 kókó 4)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 96

8. Kẹ́kọ̀ọ́ Lára Fílípì Ajíhìnrere

(15 min.) Ìjíròrò.

Ọ̀pọ̀ àpẹẹrẹ àwọn tó ṣe ohun rere àtàwọn tó ṣe búburú ló wà nínú Bíbélì. Ó máa gba àkókò àti ìsapá ká tó lè kẹ́kọ̀ọ́ látinú àwọn àpẹẹrẹ yẹn. Yàtọ̀ sí kíka àwọn ìtàn Bíbélì yìí, ó tún yẹ ká ronú lórí ohun tá a kà, ká sì fi àwọn ẹ̀kọ́ inú ẹ̀ sílò nígbèésí ayé wa.

Àwọn èèyàn mọ Fílípì ajíhìnrere sí Kristẹni tó “kún fún ẹ̀mí àti ọgbọ́n.” (Iṣe 6:3, 5) Kí la lè kọ́ lára ẹ̀?

Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ Kẹ́kọ̀ọ́ Lára Wọn—Fílípì Ajíhìnrere. Lẹ́yìn náà, béèrè ohun táwọn ará kọ́ nínú àwọn ohun tó tẹ̀ lé e yìí:

  • Kí ni Fílípì ṣe nígbà tí nǹkan yí pa dà fún un?—Iṣe 8:1, 4, 5

  • Àwọn ìbùkún wo ni Fílípì rí torí pé ó lọ sìn níbi tí àìní wà?—Iṣe 8:6-8, 26-31, 34-40

  • Àǹfààní wo ni Fílípì àti ìdílé ẹ̀ rí torí pé wọ́n gba àwọn míì lálejò?—Iṣe 21:8-10

  • Àǹfààní wo ni ìdílé inú fídíò náà rí torí pé wọ́n tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Fílípì?

9. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

(30 min.) bt orí 14 ¶11-20

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 101 àti Àdúrà