MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Fọgbọ́n Yan Eré Ìnàjú Tí Wàá Máa Ṣe
Kí nìdí tó fi yẹ ká fọgbọ́n yan eré ìnàjú tá a máa ṣe? Ìdí ni pé tá a bá yan fíìmù kan tá a fẹ́ wò, orin tá a fẹ́ gbọ́, ìkànnì kan tá a fẹ́ lọ, ìwé kan tá a fẹ́ kà tàbí géèmù tá a fẹ́ gbá, ṣe là ń yan ohun tá a fẹ́ fi kúnnú ọkàn wa. Ohun tá a bá yàn máa nípa lórí ìwà wa. Ó ṣeni láàánú pé púpọ̀ lára àwọn eré ìnàjú tó wà lónìí ló ní àwọn nǹkan tí Jèhófà kórìíra nínú. (Sm 11:5; Ga 5:19-21) Ìdí nìyẹn tí Bíbélì fi rọ̀ wá pé ká máa ronú lórí àwọn nǹkan tó máa mú ògo wá fún Jèhófà.—Flp 4:8.
WO FÍDÍÒ NÁÀ ERÉ ÌNÀJÚ WO LÓ YẸ KÍ N YÀN LÁÀYÒ? KÓ O SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:
-
Báwo ni ìjà àjàkú akátá tí wọ́n ń jà ní Róòmù láyé àtijọ́ ṣe jọra pẹ̀lú àwọn eré ìnàjú kan lóde òní?
-
Báwo ni àwọn ará ìjọ ṣe lè ran àwọn ọ̀dọ́ lọ́wọ́ láti yan eré ìnàjú tó gbámúṣé?
-
Báwo ló ṣe yẹ kí Róòmù 12:9 ràn wá lọ́wọ́ tá a bá fẹ́ yan eré ìnàjú?
-
Irú àwọn eré ìnàjú tó gbámúṣé wo ló wà ní àdúgbò rẹ?