Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN | GÁLÁTÍÀ 4-6

“Àkàwé” Kan àti Ìtumọ̀ Rẹ̀

“Àkàwé” Kan àti Ìtumọ̀ Rẹ̀

4:​24-31

Pọ́ọ̀lù lo “àkàwé” yìí láti jẹ́ ká mọ̀ pé májẹ̀mú tuntun kì í ṣẹgbẹ́ májẹ̀mú Òfin. Lábẹ́ ìṣàkóso onífẹ̀ẹ́ Kristi àtàwọn tó máa bá a jọba, gbogbo aráyé máa gba òmìnira kúrò lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀, àìpé, ìbànújẹ́ àti ikú.​—Ais 25:​8, 9.

 

ẸRÚ NÁÀ HÁGÁRÌ

Orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì lábẹ́ májẹ̀mú Òfin, Jerúsálẹ́mù sì ni olú ìlú rẹ̀

SÁRÀ​—OBÌNRIN TÓ LÓMÌNIRA

Jerúsálẹ́mù ti òkè, apá ti ọ̀run lára ètò Ọlọ́run

ÀWỌN “ỌMỌ” HÁGÁRÌ

Àwọn Júù (tó ṣèlérí pé àwọn á máa tẹ̀ lé májẹ̀mú Òfin) kọ Jésù, wọ́n sì pa á

ÀWỌN “ỌMỌ” SÁRÀ

Kristi àti àwọn Kristẹni tá a fẹ̀mí yàn tí iye wọ́n jẹ́ ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì (144,000)

MÁJẸ̀MÚ ÒFIN TÓ MÚNI LẸ́RÚ

Òfin yẹn ló ń rán àwọn ọmọ Ísírẹ́lì létí pé ẹrú ẹ̀ṣẹ̀ ni wọ́n jẹ́

MÁJÈMÚ TUNTUN TÓ SỌNI DI ÒMÌNIRA

Ìgbàgbọ́ nínú ẹbọ ìràpadà Kristi máa dáni sílẹ̀ lọ́wọ́ ìdálẹ́bi Òfin, á sì sọni di òmìnira