Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Àwọn Ọ̀nà Ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ Tá A Lè Lò

Àwọn Ọ̀nà Ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ Tá A Lè Lò

ILÉ ÌṢỌ́

Béèrè ìbéèrè: Kí lẹ rò pé ó jẹ́ ẹ̀bùn tó dára jù lọ tí Ọlọ́run tíì fún wa?

Ka Bíbélì: Jo 3:16

Fi ìwé lọni: Ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́ yìí sọ ìdí tí Ọlọ́run fi rán Jésù wá sáyé àti bá a ṣe lè fi hàn pé a mọ rírì ẹ̀bùn náà.

KÍ NI ÌJỌBA ỌLỌ́RUN?

Béèrè ìbéèrè: [Fi iwájú ìwé àṣàrò kúkúrú náà hàn án.] Kí ni èrò yín nípa ìbéèrè yìí? Ṣé ọkàn èèyàn ni Ìjọba Ọlọ́run wà? àbí àkànlò èdè ni? àbí ìjọba kan ní ọ̀run?

Ka Bíbélì: Da 2:44; Ais 9:6

Fi ìwé lọni: Ìwé àṣàrò kúkúrú yìí jẹ́ ká mọ àǹfààní tí Ìjọba Ọlọ́run máa ṣe fún wa.

ÌWÉ ÌKÉSÍNI SÍBI ÌRÀNTÍ IKÚ KRISTI

Fi ìwé lọni: À ń pe àwọn èèyàn wá síbi ìṣẹ̀lẹ̀ pàtàkì kan. [Fún un ní ìwé ìkésíni.] Ní April 11, ọ̀pọ̀ èèyàn jákèjádò ayé máa pé jọ láti ṣe ìrántí ikú Jésù, wọ́n á sì gbọ́ àsọyé kan tó dá lórí Bíbélì nípa bí ikú Jésù ṣe lè ṣe wá láǹfààní, ọ̀fẹ́ sì ni. Wàá rí àkókò àti ibi tá a ti máa ṣe ìpàdé náà nínú ìwé yìí. A ó máa retí yín o.

KỌ Ọ̀NÀ ÌGBỌ́RỌ̀KALẸ̀ RẸ

Wo àwọn ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ tá a fi ṣe àpẹẹrẹ yìí, kó o sì kọ ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ tìrẹ.