March 11-17
RÓÒMÙ 15-16
Orin 33 àti Àdúrà
Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN
“Bẹ Jèhófà Pé Kó Fún Ẹ Ní Ìfaradà Kó sì Tù Ẹ́ Nínú”: (10 min.)
Ro 15:4—Máa ka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run kó o lè rí ìtùnú gbà (w17.07 14 ¶11)
Ro 15:5—Bẹ Jèhófà pé kó fún ẹ ní “ìfaradà àti ìtùnú” (w16.04 10 ¶5)
Ro 15:13—Jèhófà máa ń fún wa ní ìrètí (w14 6/15 14 ¶11)
Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: (8 min.)
Ro 15:27—Báwo ni àwọn Kèfèrí tó di Kristẹni ṣe jẹ́ “ajigbèsè” sí àwọn Kristẹni tó wà ní Jerúsálẹ́mù? (w89 12/1 24 ¶3)
Ro 16:25—Kí ni “àṣírí ọlọ́wọ̀ tí a ti pa mọ́ ní ìdákẹ́jẹ́ẹ́ tipẹ́tipẹ́”? (it-1 858 ¶5)
Kí ni Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí kọ́ ẹ nípa Jèhófà?
Àwọn ìṣúra tẹ̀mí wo lo tún rí látinú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí?
Bíbélì Kíkà: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Ro 15:1-16 (th ẹ̀kọ́ 10)
MÁA LO ARA RẸ LẸ́NU IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ
Nígbà Àkọ́kọ́—Fídíò: (4 min.) Ẹ wo fídíò náà, kẹ́ ẹ sì jíròrò rẹ̀.
Nígbà Àkọ́kọ́: (2 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Lo ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ tó wà lójú ìwé 1. (th ẹ̀kọ́ 3)
Nígbà Àkọ́kọ́: (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Lo ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ tó wà lójú ìwé 1. Onílé sọ ohun táwọn èèyàn sábà máa ń sọ ní ìpínlẹ̀ yín tí wọn kò bá fẹ́ gbọ́ ìwàásù. Fèsì ní ṣókí, kó o sì máa bá ọ̀rọ̀ rẹ lọ. (th ẹ̀kọ́ 10)
Nígbà Àkọ́kọ́: (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Lo ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ tó wà lójú ìwé 1. Onílé sọ ohun táwọn èèyàn sábà máa ń sọ ní ìpínlẹ̀ yín tí wọn kò bá fẹ́ gbọ́ ìwàásù. Fèsì ní ṣókí, kó o sì máa bá ọ̀rọ̀ rẹ lọ. (th ẹ̀kọ́ 11)
MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Bí Jèhófà Ṣe Ń “Pèsè Ìfaradà àti Ìtùnú”: (15 min.) Jẹ́ kí àwọn ará wo fídíò náà (lára àwọn fídíò tó wà ní abala BÍBÉLÌ). Lẹ́yìn náà, ẹ jíròrò àwọn ìbéèrè yìí:
Ẹ̀kọ́ wo lo rí kọ́ nípa bá a ṣe ń rí ìtùnú gbà?
Ẹ̀kọ́ wo lo rí kọ́ nípa bá a ṣe lè fún àwọn míì ní ìṣírí?
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: (30 min.) bh orí 3 ¶21-24
Àtúnyẹ̀wò àti Ohun Tá A Máa Kọ́ Lọ́sẹ̀ Tó Ń Bọ̀ (3 min.)
Orin 34 àti Àdúrà