March 25-31
1 KỌ́RÍŃTÌ 4-6
Orin 123 àti Àdúrà
Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN
“Ìwúkàrà Díẹ̀ Ní Í Mú Gbogbo Ìṣùpọ̀ Di Wíwú”: (10 min.)
1Kọ 5:1, 2—Àwọn tó wà ní ìjọ Kọ́ríńtì ń fàyè gba oníwà àìtọ́ kan tí kò ronú pìwà dà
1Kọ 5:5-8, 13—Pọ́ọ̀lù sọ pé kí ìjọ yọ “ìwúkàrà” náà kúrò láàárín wọn, kí wọ́n sì fi ẹni tó hùwà àìtọ́ náà lé Sátánì lọ́wọ́ (it-2 230, 869-870)
1Kọ 5:9-11—Ẹnì kankan nínu ìjọ ò gbọdọ̀ bá oníwà àìtọ́ tí kò ronú pìwà dà náà kẹ́gbẹ́ (lv 207 ¶1-3, àfikún “Ọwọ́ Tó Yẹ Ká Fi Mú Ẹni Tí Wọ́n Bá Yọ Lẹ́gbẹ́.”)
Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: (8 min.)
1Kọ 4:9—Báwo ni àwọn èèyàn tó jẹ́ ìránṣẹ́ Ọlọ́run ṣe di “ìran àpéwò ní gbọ̀ngàn ìwòran” fún àwọn áńgẹ́lì? (w09 5/15 24 ¶16)
1Kọ 6:3—Kí ni Pọ́ọ̀lù ń tọ́ka sí nígbà tó kọ̀wé pé: “Àwa ni yóò ṣèdájọ́ àwọn áńgẹ́lì”? (it-2 211)
Kí ni Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí kọ́ ẹ nípa Jèhófà?
Àwọn ìṣúra tẹ̀mí wo lo tún rí látinú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí?
Bíbélì Kíkà: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) 1Kọ 6:1-14 (th ẹ̀kọ́ 10)
MÁA LO ARA RẸ LẸ́NU IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ
Ìpadàbẹ̀wò Kejì—Fídíò: (5 min.) Ẹ wo fídíò náà, kẹ́ ẹ sì jíròrò rẹ̀.
Ìpadàbẹ̀wò Kejì: (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Lo ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ tó wà lójú ìwé 1. (th ẹ̀kọ́ 11)
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì: (5 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) lv 207 ¶2, 3 (th ẹ̀kọ́ 3)
MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
“Máa Fi Fídíò Kọ́ Àwọn Tó Ò Ń Kọ́ Lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì”: (15 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ kí àwọn ará wo fídíò náà, kẹ́ ẹ sì jíròrò rẹ̀. Fídíò náà jẹ́ ká rí bí akéde kan ṣe fi fídíò tó dá lórí ẹ̀kọ́ 4 nínú ìwé Ìròyìn Ayọ̀ kọ́ ẹni tó ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì.
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: (30 min.) bh orí 4 ¶10-11 àti àfikún “Bí Dáníẹ́lì Ṣe Sọ Àsọtẹ́lẹ̀ Ìgbà Tí Mèsáyà Yóò Dé.”
Àtúnyẹ̀wò àti Ohun Tá A Máa Kọ́ Lọ́sẹ̀ Tó Ń Bọ̀ (3 min.)
Orin 23 àti Àdúrà