“Ìwúkàrà Díẹ̀ Ní Í Mú Gbogbo Ìṣùpọ̀ Di Wíwú”
Kí nìdí tá a fi máa ń sọ pé ìfẹ́ ló mú kí Jèhófà ṣètò ìyọlẹ́gbẹ́ nígbà tó jẹ́ pé ó máa ń dunni gan-an tó bá ṣẹlẹ̀?
Ìyọlẹ́gbẹ́ fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ . . .
-
Jèhófà, a sì ń bọlá fún orúkọ mímọ́ rẹ̀.—1Pe 1:15, 16
-
àwọn ará ìjọ, a sì fẹ́ dáàbò bò wọ́n kí ìwà burúkú máa bàa gbilẹ̀.—1Kọ 5:6
-
ẹni tó dẹ́ṣẹ̀ náà, a sì fẹ́ ràn án lọ́wọ́, ká sì pe orí rẹ̀ wálé.—Heb 12:11
Tí wọ́n bá yọ ẹnì kan lẹ́gbẹ́ nínú ìdílé Kristẹni kan, báwo lo ṣe lè ràn wọ́n lọ́wọ́?