March 16-22
JẸ́NẸ́SÍSÌ 25-26
Orin 18 àti Àdúrà
Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN
“Ísọ̀ Ta Ogún Ìbí Rẹ̀”: (10 min.)
Jẹ 25:27, 28—Ìbejì ni Ísọ̀ àti Jékọ́bù, àmọ́ ìwà wọn yàtọ̀ síra (it-1 1242)
Jẹ 25:29, 30—Ísọ̀ ò ronú kó tó ṣèpinnu torí pé ó ti rẹ̀ ẹ́, ebi sì ń pa á
Jẹ 25:31-34—Aláìmoore ni Ísọ̀, ó fi ìwàǹwára ta ogún ìbí rẹ̀ fún Jékọ́bù nítorí oúnjẹ ẹ̀ẹ̀kan péré (w19.02 16 ¶11; it-1 835)
Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: (10 min.)
Jẹ 25:31-34—Kí nìdí tí a ò fi lè lo ẹsẹ Bíbélì yìí láti fìdí ẹ̀ múlẹ̀ pé àwọn baba ńlá Mèsáyà gbọ́dọ̀ jẹ́ àkọ́bí? (Heb 12:16; w17.12 15 ¶5-7)
Jẹ 26:7—Kí nìdí tí Ísákì ò fi sọ òkodoro ọ̀rọ̀ nínú ipò tó bá ara rẹ̀ yìí? (it-2 245 ¶6)
Àwọn ìṣúra tẹ̀mí wo lo tún rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí nípa Jèhófà, iṣẹ́ ìwàásù tàbí àwọn nǹkan míì?
Bíbélì Kíkà: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Jẹ 26:1-18 (th ẹ̀kọ́ 5)
MÁA LO ARA RẸ LẸ́NU IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ
Ìpadàbẹ̀wò Àkọ́kọ́—Fídíò: (5 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ kí àwọn ará wo fídíò náà, lẹ́yìn náà béèrè àwọn ìbéèrè yìí: Kí la lè ṣe tá ò fi ní dójú ti onílé tí kò bá mọ ìdáhùn sí ìbéèrè wa? Báwo ni akéde náà ṣe ṣàlàyé Mátíù 20:28 kó lè wọ onílé lọ́kàn?
Ìpadàbẹ̀wò Àkọ́kọ́: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Lo ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ tó wà lójú ìwé 1. (th ẹ̀kọ́ 3)
Ìpadàbẹ̀wò Àkọ́kọ́: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Lo ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ tó wà lójú ìwé 1. Lẹ́yìn náà fún onílé ní ìwé Kí Ni Bíbélì Kọ́ Wa? (th ẹ̀kọ́ 15)
MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Máa Lo Fídíò Tó O Bá Ń Fi Ìwé Ìròyìn Ayọ̀ Látọ̀dọ̀ Ọlọ́run! Kọ́ni: (15 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ kí àwọn ará wo fídíò náà Kí Ló Ń Ṣẹlẹ̀ sí Àwọn Tó Ti Kú? àti Kí Nìdí Tí Ọlọ́run Fi Gbà Pé Ká Máa Jìyà? Lẹ́yìn tẹ́ ẹ bá wo fídíò kọ̀ọ̀kan tán, béèrè àwọn ìbéèrè yìí: Báwo lo ṣe lè lo fídíò yìí nígbà tó o bá ń fí ìwé Ìròyìn Ayọ̀ kọ́ ẹnì kan lẹ́kọ̀ọ́? (mwb19.03 7) Kí lo kíyè sí nínú fídíò náà tó máa wúlò fún ẹ lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù? Rán àwọn ara létí pé ẹ̀dà ìwé Ìròyìn Ayọ̀ tó wà lórí ẹ̀rọ̀ ní ìlujá tó máa gbé wọn lọ síbi tí fídíò kọ̀ọ̀kan wà.
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: (30 min.) bh orí 17 ¶1-8
Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
Orin 107 àti Àdúrà