Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

Má Ṣe Máa Gbéra Ga, Má sì Dá Ara Rẹ Lójú Jù

Má Ṣe Máa Gbéra Ga, Má sì Dá Ara Rẹ Lójú Jù

Kórà di agbéraga, ó sì dá ara ẹ̀ lójú jù, torí náà kò fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ètò tí Jèhófà ṣe (Nọ 16:​1-3; w11 9/15 27 ¶12)

Ọmọ Léfì táwọn èèyàn bọ̀wọ̀ fún ni Kórà, ọ̀pọ̀ àǹfààní iṣẹ́ ìsìn ló sì ní (Nọ 16:​8-10; w11 9/15 27 ¶11)

Kórà gba èròkerò láyè, ohun tó sì tẹ̀yìn ẹ̀ yọ ò dáa rárá (Nọ 16:​32, 35)

A ò gbọ́dọ̀ jẹ́ kí àwọn àṣeyọrí tá a ṣe lẹ́nu iṣẹ́ Jèhófà mú ká di agbéraga tàbí ká máa dá ara wa lójú jù. Bá a bá ṣe ń pẹ́ sí i nínú òtítọ́ tàbí bí iṣẹ́ tá à ń bójú tó nínú ètò Ọlọ́run bá ṣe ń pọ̀ sí i, bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe yẹ ká túbọ̀ máa jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ sí i.