Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

April 22-28

SÁÀMÙ 32-33

April 22-28

Orin 103 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. Ìdí Tó Fi Yẹ Ká Jẹ́wọ́ Ẹ̀ṣẹ̀ Tó Wúwo

(10 min.)

Ọkàn Dáfídì ò balẹ̀ nígbà tó ń gbìyànjú láti bo ẹ̀ṣẹ̀ tó ṣeé ṣe kó dá pẹ̀lú Bátí-ṣébà mọ́lẹ̀ (Sm 32:3, 4; w93 3/15 9 ¶7)

Dáfídì jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, Jèhófà sì dárí jì í (Sm 32:5; cl 262 ¶8)

Ara tu Dáfídì nígbà tí Jèhófà dárí jì í (Sm 32:1; w01 6/1 30 ¶1)

Tá a bá dá ẹ̀ṣẹ̀ tó wúwo, ó yẹ ká jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wa fún Jèhófà ká sì bẹ̀ ẹ́ pé kó dárí jì wá. Ó tún yẹ ká sọ fún àwọn alàgbà kí wọ́n lè ràn wá lọ́wọ́ láti pa dà ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà. (Jem 5:14-16) Èyí á jẹ́ ká lè rí ìtura gbà látọ̀dọ̀ Jèhófà.—Iṣe 3:19.

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Sm 33:6—Kí ni “èémí” ẹnu Jèhófà? (w06 5/15 20 ¶1)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Jẹ́ Onírẹ̀lẹ̀—Ohun Tí Pọ́ọ̀lù Ṣe

(7 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ náà, lẹ́yìn náà, ẹ jíròrò lmd ẹ̀kọ́ 4 kókó 1-2.

5. Jẹ́ Onírẹ̀lẹ̀—Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù

(8 min.) Ìjíròrò tó dá lórí lmd ẹ̀kọ́ 4 kókó 3-5 àti “Tún Wo.”

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 74

6. Ohun Tó Ń Fẹ́ Àbójútó Nínú Ìjọ

(15 min.)

7. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 39 àti Àdúrà