ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN
Yẹra fún Ojúsàájú, Kó O Lè Fìwà Jọ Jèhófà
Àwọn ọmọbìnrin Sélóféhádì márùn-ún fẹ́ gba ogún bàbá wọn (Nọ 27:1-4; w13 6/15 10 ¶14; wo àwòrán iwájú ìwé)
Ìpinnu tí Jèhófà ṣe fi hàn pé kì í ṣe ojúsàájú (Nọ 27:5-7; w13 6/15 11 ¶15)
Àwa náà gbọ́dọ̀ yẹra fún ojúsàájú (Nọ 27:8-11; w13 6/15 11 ¶16)
Tá a bá ń fìfẹ́ hàn sáwọn ará wa, tá à ń bọ̀wọ̀ fún wọn, tá a sì ń wàásù fún onírúurú èèyàn láìka ibi tí wọ́n ti wá sí, ṣe là ń fi hàn pé a kì í ṣe ojúsàájú, àá sì máa fìwà jọ Jèhófà.