May 2-8
1 SÁMÚẸ́LÌ 27-29
Orin 71 àti Àdúrà
Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN
“Ọgbọ́n Tí Dáfídì Dá Kó lè Dáàbò Bo Àwọn Èèyàn Ọlọ́run”: (10 min.)
Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì: (10 min.)
1Sa 28:15—Ṣé Sámúẹ́lì ni Sọ́ọ̀lù “rí” nígbà tó lọ sọ́dọ̀ abẹ́mìílò? (w10 1/1 20 ¶5-6)
Àwọn ìṣúra wo lo tún rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí nípa Jèhófà, iṣẹ́ ìwàásù tàbí àwọn nǹkan míì?
Bíbélì Kíkà: (4 min.) 1Sa 27:1-12 (th ẹ̀kọ́ 5)
TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ
Fídíò Nígbà Àkọ́kọ́: (5 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ káwọn ará wo fídíò Nígbà Àkọ́kọ́: Ìyà—Jem 1:13. Ẹ dá fídíò náà dúró láwọn ibi tẹ́ ẹ bá ti rí ìbéèrè, kẹ́ ẹ sì jíròrò ìbéèrè náà kẹ́ ẹ tó máa wò ó lọ.
Nígbà Àkọ́kọ́: (3 min.) Lo ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ. (th ẹ̀kọ́ 1)
Nígbà Àkọ́kọ́: (5 min.) Ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ ni kó o fi bẹ̀rẹ̀. Lẹ́yìn náà, fún ẹni náà ní ìwé Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìbẹ̀rẹ̀ Ẹ̀kọ́ Bíbélì, kó o sì ṣe bíi pé ẹ wo fídíò Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kó O Kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì? (àmọ́ ẹ má ṣe wò ó) (th ẹ̀kọ́ 6)
MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Dúró Ṣinṣin Lójú Àtakò: (15 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ káwọn ará wo fídíò náà. Lẹ́yìn náà, bi àwọn ará láwọn ìbéèrè yìí: Kí la rí kọ́ látinú àpẹẹrẹ àwọn ará wa nígbà ìjọba Násì lórílẹ̀-èdè Jámánì? Kí ni àpẹẹrẹ àwọn ará wa ní Rọ́ṣíà ati Soviet Union àtijọ́ kọ́ wa?
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: (30 min.) lff ẹ̀kọ́ 02
Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.)
Orin 94 àti Àdúrà