Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Dáfídì ń ronú lórí májẹ̀mú tí Jèhófà dá pẹ̀lú rẹ̀

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

Jèhófà Bá Dáfídì Dá Májẹ̀mú

Jèhófà Bá Dáfídì Dá Májẹ̀mú

Jèhófà ṣèlérí fún Dáfídì pé òun máa fìdí ìjọba rẹ̀ àti ti àtọmọdọ́mọ rẹ̀ múlẹ̀ (2Sa 7:11, 12, àlàyé ìsàlẹ̀; w10 4/1 20 ¶3; wo àwòrán iwájú ìwé)

Àwọn apá kan lára májẹ̀mú tí Jèhófà bá Dáfídì dá ṣẹ sí Mèsáyà lára (2Sa 7:13, 14; Heb 1:5; w10 4/1 20 ¶4)

Títí láé la máa gbádùn àwọn ìbùkún tí Ìjọba Mèsáyà máa mú wá (2Sa 7:15, 16; Heb 1:8; w14 10/15 10 ¶14)

Bó ṣe dá wa lójú pé kò sóhun tó lè mú kí oòrùn àti òṣùpá má yọ, bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe dá wa lójú pé ìṣàkóso Mèsáyà máa wà títí láé. (Sm 89:35-37) Torí náà tó o bá ti ń rí oòrùn àti òṣùpá, máa ronú nípa ìlérí tí Jèhófà ṣe pé Ìjọba òun máa mú ìbùkún wá fún ìwọ àti ìdílé rẹ.