Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Jèhófà Ni “Bàbá Àwọn Ọmọ Aláìníbaba”

Jèhófà Ni “Bàbá Àwọn Ọmọ Aláìníbaba”

Ọdọọdún ni àìmọye àwọn ọ̀dọ́ ń pinnu láti di ọ̀rẹ́ Jèhófà. (Sm 110:3) Jèhófà mọyì ẹnì kọ̀ọ̀kan yín, ó sì nífẹ̀ẹ́ yín gan-an. Ó mọ àwọn nǹkan tí ẹ̀ ń bá yí, ó sì ti ṣèlérí pé òun máa ràn yín lọ́wọ́ kẹ́ ẹ lè jẹ́ olóòótọ́ sí òun. Tó bá jẹ́ pé òbí kan ṣoṣo ló ń tọ́ ẹ, rántí pé Jèhófà ni “Bàbá àwọn ọmọ aláìníbaba.” (Sm 68:5) Torí náà, láìka ti pé òbí kan ló ń tọ́ ẹ, Jèhófà máa dá ẹ lẹ́kọ̀ọ́, wàá sì ṣàṣeyọrí.​—1Pe 5: 10.

Ẹ WO FÍDÍÒ NÁÀ ÌGBÀGBỌ́ Ń MÚ KÍ WỌ́N JA ÀJÀṢẸ́GUN​—ÀWỌN TÍ ÒBÍ KAN ṢOṢO TỌ́, KẸ́ Ẹ SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Kí lo rí kọ́ lára Tammy, Charles àti Jimmy?

  • Kí ni Sáàmù 27:10 sọ tó lè fi àwọn tí òbí kan ṣoṣo ń tọ́ lọ́kàn balẹ̀?