Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

November 11-17

SÁÀMÙ 106

November 11-17

Orin 36 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. “Wọ́n Gbàgbé Ọlọ́run Olùgbàlà Wọn”

(10 min.)

Nígbà tí ẹ̀rù ba àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Jèhófà (Ẹk 14:11, 12; Sm 106:7-9)

Nígbà tí òùngbẹ ń gbẹ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, tí ebi sì ń pa wọ́n, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í kùn sí Jèhófà (Ẹk 15:24; 16:3, 8; 17:2, 3; Sm 106:13, 14)

Nígbà tí ọkàn àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ò balẹ̀, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í jọ́sìn òrìṣà (Ẹk 32:1; Sm 106:19-21; w18.07 20 ¶13)

RONÚ LÓRÍ ÌBÉÈRÈ YÌÍ: Tá a bá níṣòro, kí nìdí tó fi dáa ká máa ronú nípa àwọn ọ̀nà tí Jèhófà ti gbà ràn wá lọ́wọ́ láwọn ìgbà kan rí?

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Sm 106:36, 37—Tẹ́nì kan bá ń jọ́sìn òrìṣà, ṣé a lè sọ pé irú ẹni bẹ́ẹ̀ ń rúbọ sáwọn ẹ̀mí èṣù? (w06 7/15 13 ¶9)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Kọ́ni Lọ́nà Tó Rọrùn—Ohun Tí Jésù Ṣe

(7 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ káwọn ará wo FÍDÍÒ náà, kẹ́ ẹ sì jíròrò lmd ẹ̀kọ́ 11 kókó 1-2.

5. Kọ́ni Lọ́nà Tó Rọrùn—Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Jésù

(8 min.) Ìjíròrò tó dá lórí lmd ẹ̀kọ́ 11 kókó 3-5 àti apá “Tún Wo.”

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 78

6. Ohun Tó Ń Fẹ́ Àbójútó Nínú Ìjọ

(15 min.)

7. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 77 àti Àdúrà