Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

October 7-13

SÁÀMÙ 92-95

October 7-13

Orin 84 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. Ohun Tó Dáa Jù Téèyàn Lè Fayé Ẹ̀ Ṣe Ni Pé Kó Sin Jèhófà

(10 min.)

Jèhófà ló yẹ ká máa sìn (Sm 92:1, 4; w18.04 26 ¶5)

Ó fún wa lọ́gbọ́n táá jẹ́ ká lè ṣèpinnu tó dáa, táá sì jẹ́ ká gbádùn ayé wa (Sm 92:5; w18.11 20 ¶8)

Ó mọyì àwọn àgbàlagbà tó ń sìn ín (Sm 92:12-15; w20.01 19 ¶18)

BI ARA RẸ PÉ, ‘Kí ló ń dí mi lọ́wọ́ láti ya ara mi sí mímọ́ fún Jèhófà kí n sì ṣèrìbọmi?’

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Sm 92:5—Báwo ni ẹsẹ Bíbélì yìí ṣe jẹ́ ká mọ bí ọgbọ́n Jèhófà ṣe pọ̀ tó? (cl 176 ¶18)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ÀÌJẸ́-BÍ-ÀṢÀ. Wá bó o ṣe lè sọ fún ẹnì kan tẹ́ ẹ jọ ń sọ̀rọ̀ nípa bó o ṣe máa ń ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ láti kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. (lmd ẹ̀kọ́ 5 kókó 3)

5. Pa Dà Lọ

(3 min.) ÌWÀÁSÙ ÀÌJẸ́-BÍ-ÀṢÀ. O ti fi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ ẹni náà nígbà kan rí, àmọ́ kò gbà. Gbìyànjú láti tún fi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ̀ ọ́. (lmd ẹ̀kọ́ 8 kókó 4)

6. Sọ Àwọn Èèyàn Di Ọmọ Ẹ̀yìn

(5 min.) Ìjíròrò pẹ̀lú akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì kan tí ò tẹ̀ síwájú. (lmd ẹ̀kọ́ 12 kókó 5)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 5

7. Ohun Táwọn Ọ̀dọ́ Lè Ṣe Tí Ọkàn Wọn Ò Bá Balẹ̀

(15 min.) Ìjíròrò.

Gbogbo èèyàn ló máa ń ṣàníyàn, èyí ò sì yọ àwọn tó ń sin Jèhófà sílẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, àwọn ìgbà kan wà tí ọkàn Dáfídì ò balẹ̀, bó sì ṣe rí fáwọn ará wa lónìí náà nìyẹn. (Sm 13:2; 139:23) Kódà, àwọn ọ̀dọ́ náà máa ń bára wọn nírú ipò yìí. Nígbà míì, àníyàn lè jẹ́ kí àwọn nǹkan tá à ń ṣe lójoojúmọ́ di ohun tó ń kà wá láyà, irú bíi lílọ sílé ìwé tàbí àwọn ìpàdé ìjọ. Téèyàn bá ń ṣàníyàn jù, ó lè jẹ́ káyà èèyàn máa já láìnídìí tàbí kéèyàn tiẹ̀ máa ronú láti pa ara ẹ̀.

Ẹ̀yin ọ̀dọ́, tí nǹkan kan bá ń kó yín lọ́kàn sókè, tó sì mú kí gbogbo nǹkan tojú sú yín, ẹ fọ̀rọ̀ náà lọ àwọn òbí yín tàbí àgbàlagbà kan tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú ẹ̀. Ẹ má sì gbàgbé láti gbàdúrà sí Jèhófà. (Flp 4:6) Torí pé ó ṣe tán láti ràn yín lọ́wọ́. (Sm 94:17-19; Ais 41:10) Ẹ jẹ́ ká wo àpẹẹrẹ Steing.

Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ Jèhófà Bìkítà Nípa Mi. Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

• Ẹsẹ Bíbélì wo ló ran Steing lọ́wọ́, báwo ló sì ṣe ràn án lọ́wọ́?

• Báwo ni Jèhófà ṣe ràn án lọ́wọ́?

Ẹ̀yin òbí, ẹ máa fara balẹ̀ tẹ́tí sáwọn ọmọ yín, kẹ́ ẹ sì máa ṣe ohun tó fi hàn pé ẹ nífẹ̀ẹ́ wọn. Bákan náà, ẹ máa ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọ́n lè fọkàn tán Jèhófà, kí wọ́n sì gbà pé ó nífẹ̀ẹ́ wọn. Tẹ́ ẹ bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, wọ́n á lè borí ìṣòro èyíkéyìí tó ń kó wọn lọ́kàn sókè. (Tit 2:4; Jem 1:19) Bẹ Jèhófà pé kó fún ẹ lókùn, kó sì fi ẹ́ lọ́kàn balẹ̀ kó o lè ran àwọn ọmọ rẹ lọ́wọ́.

A lè má mọ̀ tí ẹnì kan nínú ìjọ bá ní ìṣòro kan tó ń kó o lọ́kàn sókè, a sì lè má mọ bí nǹkan ṣe rí lára ẹ̀. Àmọ́, a lè ran irú àwọn ẹni bẹ́ẹ lọ́wọ́ tá a bá ń fìfẹ́ hàn sí gbogbo àwọn ará, tá a sì ń ṣe ohun táá mára tù wọ́n.—Owe 12:25; Heb 10:24.

8. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 81 àti Àdúrà