Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ìmọ̀ràn Àtàtà fún Àwọn Ọ̀dọ́

Ìmọ̀ràn Àtàtà fún Àwọn Ọ̀dọ́

Ìmọ̀ràn Àtàtà fún Àwọn Ọ̀dọ́

Nígbà tí Bill, tó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń fi ìwé ìròyìn lọni nítòsí ilé ẹjọ́ kan ní ìpínlẹ̀ California, ní orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà, ọkùnrin kan wá bá a ó sì sọ fún un pé kó jẹ́ kí òun rí gbogbo ẹ̀dà ìwé ìròyìn Jí! tó ní lọ́wọ́. Bill sọ pé: “Ṣáájú ìgbà yẹn, àwọn kan nínú ìjọ wa ti kó àwọn ìwé ìròyìn tọ́jọ́ wọn ti pẹ́ díẹ̀ fún mi, nípa bẹ́ẹ̀ ó ṣeé ṣe fún mi láti rí ọ̀kan-ò-jọ̀kan ìwé ìròyìn láti fi han ọkùnrin náà.

“Kíákíá ni ọkùnrin yìí yanjú àwọn ìwé ìròyìn náà sọ́tọ̀ọ̀tọ̀ tó sì ṣa gbogbo àwọn tí kò tíì kà jọ gègèrè. Ó béèrè bóyá òun lè gba gbogbo wọn. Ó sọ pé òṣìṣẹ́ ilé ẹjọ́ ìjọba ìbílẹ̀ náà ni òun àti pé òun lòún máa ń gba àwọn ọ̀dọ́ tó bá wà nínú ìṣòro nímọ̀ràn. Ó ṣàlàyé pé ìdí tí òun fi ń gba Jí! ni láti lè ṣe ẹ̀dà àwọn àpilẹ̀kọ ‘Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé’ tó máa ń wà nínú rẹ̀. Lẹ́yìn náà, yóò tò wọ́n níbàámu pẹ̀lú kókó tí wọ́n jíròrò, yóò sì kó wọn sí àrọ́wọ́tó rẹ̀ láti máa fún àwọn ọ̀dọ́ tó ń gbà nímọ̀ràn. Ọkùnrin náà sọ pé: ‘Àwọn ìṣòro tó ń dààmú àwọn ọ̀dọ́ ayé òde òní gẹ́lẹ́ ni àwọn kókó tí wọ́n jíròrò dá lé.’ Ó wá gbóríyìn fún àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà fún títẹ̀ tí wọ́n ń tẹ irú àwọn ìsọfúnni tó wúlò bẹ́ẹ̀ jáde láti fi ran àwọn ọ̀dọ́ lọ́wọ́. Ó fi kún un pé, òun á máa wò mí níbẹ̀ lóòrèkóòrè láti gba àwọn ìwé ìròyìn Jí! tuntun èyíkéyìí tí mo bá lè rí fún òun.”

Púpọ̀ lára àwọn ìsọfúnni tá a ti tẹ̀ jáde nínú ọ̀wọ́ àpilẹ̀kọ “Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè” wà nínú ìwé náà, Awọn Ìbéèrè Tí Awọn Ọ̀dọ́ Ń Béèrè—Awọn Ìdáhùn Tí Ó Gbéṣẹ́. O lè béèrè fún ẹ̀dà kan ìwé olójú ewé 320 yìí nípa kíkàn sí àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó wà ládùúgbò rẹ. Bó o bá fẹ́ kí ẹnì kan wá ọ wá, jọ̀wọ́ kọ̀wé sínú fọ́ọ̀mù tó wà nísàlẹ̀ yìí kí o sì fi ránṣẹ́ sí àdírẹ́sì tá a kọ síbẹ̀ tàbí sí àdírẹ́sì tó bá yẹ lára èyí tá a tò sójú ìwé 5 nínú ìwé ìròyìn yìí.

□ Ẹ jọ̀wọ́, ẹ kàn sí mi nípa ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì inú ilé lọ́fẹ̀ẹ́.