Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Lẹ́tà Látọ̀dọ̀ Ẹni Ọ̀wọ́n Kan

Lẹ́tà Látọ̀dọ̀ Ẹni Ọ̀wọ́n Kan

Lẹ́tà Látọ̀dọ̀ Ẹni Ọ̀wọ́n Kan

Òǹkàwé kan láti ìpínlẹ̀ New York lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà sọ pé ńṣe ni ìwé Sún Mọ́ Jèhófà dà bíi lẹ́tà kan tí ẹni ọ̀wọ́n kan kọ síni, ó ṣàlàyé pé: “Àkòrí kọ̀ọ̀kan ń runi lọ́kàn sókè gan-an ni, ó sì ń jẹ́ kí ìfẹ́ téèyàn ní fún Jèhófà pọ̀ sí i.” Ó fi kún un pé: “Ní báyìí tí mo ti ka gbogbo ìwé náà tán, mo tún ti ń hára gàgà láti tún kà á lẹ́ẹ̀kan sí i, gẹ́gẹ́ béèyàn ṣe máa ń ka lẹ́tà tí ẹni ọ̀wọ́n kan bá kọ síni ní àkàtúnkà.” Kíyè sí ohun tí àwọn mìíràn sọ nípa ìwé náà.

Òǹkàwé kan ní ìpínlẹ̀ Kansas sọ pé: “Mo nímọ̀lára pé mo túbọ̀ ń sún mọ́ Baba mi ọ̀run sí i. Ńṣe ni ìfẹ́ fún Jèhófà túbọ̀ ń kún inú ọkàn mi ṣáá . . . Mo máa ń wọ̀nà láti ka púpọ̀ sí i láràárọ̀, màá sì rí i pé mo ka ìwé náà ní àkàtúnkà.”

Obìnrin kan láti ìpínlẹ̀ Maine kọ̀wé pé: “Ó ti jẹ́ kí n túbọ̀ lóye irú ẹni tí Jèhófà jẹ́! Gbólóhùn tó wà lójú ìwé 74 mà ń tuni lára o, èyí tó sọ pé: ‘Ní ti àwọn tó bá kú, kò tún sí abẹ́ ààbò téèyàn lè wà tó ju pé kí Ọlọ́run fini sí ìrántí rẹ̀.’” Òǹkọ̀wé kan ní ìpínlẹ̀ Alaska náà gbà bẹ́ẹ̀, ó ní: “Ó wọ̀ mí lọ́kàn gan-an débi pé ńṣe ni mò ń sunkún ṣáá.” Ó fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé: “Ó dájú pé, àkàtúnkà ni màá máa kà á, màá sì máa lo ọ̀rọ̀ inú rẹ̀ látìgbàdégbà.”

A gbà pé bọ́rọ̀ á ṣe rí lára ìwọ náà nìyí bó o bá ka ìwé yìí. Lẹ́yìn àwọn àkòrí mẹ́ta tó ṣáájú, a pín ìwé náà sí ìsọ̀rí mẹ́rin, ìyẹn ni: “Ó ‘Ní Agbára Ńlá’,” “Olùfẹ́ Ìdájọ́ Òdodo,” “Ọlọ́gbọ́n ní Ọkàn-Àyà,” àti “Ọlọ́run Jẹ́ Ìfẹ́.” Àkòrí tó gbẹ̀yìn nínú ìwé náà ni, “Ẹ Sún Mọ́ Ọlọ́run, Yóò sì Sún Mọ́ Yín.”

Bó o bá fẹ́ láti gba ẹ̀dà kan ìwé olójú ewé 320 yìí, jọ̀wọ́ kàn sí àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó wà ládùúgbò rẹ. Bó o bá fẹ́ kí ẹnì kan wá ọ wá, jọ̀wọ́ kọ̀wé sínú fọ́ọ̀mù tó wà nísàlẹ̀ yìí kí o sì fi ránṣẹ́ sí àdírẹ́sì tá a kọ síbẹ̀ tàbí sí àdírẹ́sì tó bá yẹ lára èyí tá a tò sójú ìwé 5 ìwé ìròyìn yìí.

□ Ẹ jọ̀wọ́, ẹ kàn sí mi nípa ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì inú ilé lọ́fẹ̀ẹ́.