Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Báwo Ni Mo Ṣe Lè Gbádùn Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì?

Báwo Ni Mo Ṣe Lè Gbádùn Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì?

Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé

Báwo Ni Mo Ṣe Lè Gbádùn Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì?

Ṣé ó tiẹ̀ yẹ kó o máa kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì? Wò ó báyìí ná:

Tó o bá ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, wàá rí ohun iyebíye kan. Tó o bá ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, tó jẹ́ ìwé tó ń tà jù lọ láyé yìí, ará àwọn nǹkan tó o máa jèrè nìyí:

● Wàá mọ ohun tó o lè ṣe láti gbé ìgbé ayé tó dára jù lọ

● Wàá kẹ́kọ̀ọ́ nípa àwọn ohun tó máa ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú àti àwọn ohun tó ti ṣẹlẹ̀ kọjá, àwọn ohun tí o kò lè rí níbòmíì

● Wàá mọ irú èèyàn tí ìwọ fúnra rẹ jẹ́, wàá sì mọ bó o ṣe lè mú kí ìwà rẹ̀ dára sí i a

Ó GBA ìsapá kí èèyàn tó lè máa kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, ṣùgbọ́n ó tó bẹ́ẹ̀, ó jù bẹ́ẹ̀ lọ! Ṣé o fẹ́ mọ bí àwọn ọ̀dọ́ kan ṣe ń ṣe é? Gé ojú ìwé tó tẹ̀ lé èyí, kó o sì ká a sí méjì. Ó máa di ìwé olójú mẹ́rin kékeré kan tó máa jẹ́ kó o mọ bí àwọn ọ̀dọ́ bíi tìẹ ṣe borí ìṣòro tí kì í jẹ́ kí wọ́n lè máa kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì fúnra wọn, àti àǹfààní tí wọ́n ń rí nínú rẹ̀.

“Kò sí ẹni tó máa ka Bíbélì tí kò ní rí nǹkan jèrè. Ẹ̀kọ́ tí èèyàn lè kọ́ látinú Bíbélì kò lópin!”—Valerie. b

O lè ka púpọ̀ sí i nínú ọ̀wọ́ àpilẹ̀kọ “Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé” nínú ìkànnì wa lórí Íńtánẹ́ẹ̀tì, ìyẹn www.watchtower.org/ype

[Àwọn Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]

a Kí o lè túbọ̀ mọ bí Bíbélì ṣe lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti ṣe àwọn ohun tá a sọ yìí, kàn sí àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ládùúgbò rẹ tàbí kó o kọ̀wé sí àdírẹ́sì tó bá yẹ lára èyí tá a tò sójú ewé 5 nínú ìwé ìròyìn yìí.

b A ti yí àwọn orúkọ kan pa dà nínú àpilẹ̀kọ yìí.

[Àpótí/Àwọn àwòrán tó wà ní ojú ìwé 15, 16]

BÍ O ṢE LÈ KẸ́KỌ̀Ọ́ BÍBÉLÌ

Ìṣòro: KÌ Í WÙ MÍ LÁTI KẸ́KỌ̀Ọ́

“Kì í fìgbà gbogbo wù mí láti máa fi odindi wákàtí kan jókòó láti máa kàwé.”—Lena.

Ohun tó o nílò: RONÚ NÍPA ÀǸFÀÀNÍ TÓ O MÁA RÍ

Kí o bàa lè gbádùn kíkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, ó yẹ kó o dáhùn ìbéèrè yìí: Àǹfààní wo ni màá rí níbẹ̀? Ṣé o fẹ́ láti di ọ̀rẹ́ Ọlọ́run? Ṣé o fẹ́ lóye ìdí tí àwọn nǹkan tó ń ṣẹlẹ̀ láyé fi ń ṣẹlẹ̀? Ṣé o fẹ́ kí ìwà rẹ̀ túbọ̀ dára sí i? Bíbélì lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ kí o lè ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí, àti àwọn nǹkan míì!

“Má ṣe wo ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ tàbí bí ẹni pé o fẹ́ ṣe ìdánwò ní ilé ìwé. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ni kó o wò ó gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà tó o lè gbà túbọ̀ sún mọ́ Ọ̀rẹ́ rẹ tó ga jù lọ, ìyẹn Jèhófà Ọlọ́run.”—Bethany.

“Tí o bá ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, ó jẹ́ àkókò tí o fi ń dá wà pẹ̀lú Jèhófà Ọlọ́run. Tó bá jẹ́ pé kìkì ìgbà tí àwọn òbí rẹ bá wà lọ́dọ̀ ẹnì kan lo máa ń fẹ́ wà pẹ̀lú ẹni náà, ǹjẹ́ a lè sọ pé ọ̀rẹ́ rẹ ni ẹnì náà lóòótọ́ àbí ọ̀rẹ́ àwọn òbí rẹ? Tó o bá ń dá kẹ́kọ̀ọ́, ńṣe ni Jèhófà máa di ọ̀rẹ́ ìwọ fúnra rẹ.”Bianca.

Rántí pé: “Gbogbo Ìwé Mímọ́ ni Ọlọ́run mí sí, ó sì ṣàǹfààní fún kíkọ́ni, fún fífi ìbáwí tọ́ni sọ́nà, fún mímú àwọn nǹkan tọ́, fún bíbániwí nínú òdodo.” (2 Tímótì 3:16) Ìwọ́ náà lè rí àwọn àǹfààní yìí látinú Bíbélì!

“Àwọn àǹfààní tó wà nínú rẹ̀ ni mo máa ń gbìyànjú láti ronú lé. Bí àwọn nǹkan kan bá wà tí mo ní láti ṣàtúnṣe nípa wọn, mo máa ń lo ìkẹ́kọ̀ọ́ mi láti rí sí àwọn apá yìí kí n sì wá nǹkan ṣe nípa wọn.”—Max.

Ohun tó yẹ kó o ronú lé:

Àwọn nǹkan wo lo lè ṣe tó máa jẹ́ kó wù ẹ́ láti máa kẹ́kọ̀ọ́?

Ìṣòro: Ó MÁA Ń SÚ MI

“Tó bá ti tó ìṣẹ́jú mẹ́wàá tí mo ti ń kẹ́kọ̀ọ́, ńṣe ló máa bẹ̀rẹ̀ sí í rẹ̀ mí; tó bá fi tó nǹkan bí ogún ìṣẹ́jú, ọkàn mi ti kúrò níbẹ̀; nígbà tó bá fi máa tó ọgbọ̀n ìṣẹ́jú, ó ti sú mi pátápátá!”—Allison.

Ohun tó o nílò: LO ỌGBỌ́N ÌDÁNÚṢE

Máa lo oríṣiríṣi ọgbọ́n ìdánúṣe, bóyá lórí ohun tí ò ń kẹ́kọ̀ọ́, ọ̀nà tí ò ń gbà kẹ́kọ̀ọ́, àti ibi tí o ti máa ń kẹ́kọ̀ọ́.

“Wá àyè láti ṣèwádìí nípa àwọn ìbéèrè tó o ní. Tó o bá kẹ́kọ̀ọ́ nípa ohun kan tó o ti ń ronú nípa rẹ̀ tẹ́lẹ̀, nígbà tó o bá fi máa parí ìkẹ́kọ̀ọ́ náà, wàá rí i pé kì í ṣe pé o kàn fi àkókò rẹ ṣòfò lásán, inú rẹ sì máa dùn gan-an.”—Richard.

“Tó o bá ń kà nípa ìṣẹ̀lẹ̀ kan, fojú inú wò ó bíi pé ìwọ náà wà nínú ìtàn yẹn. Ṣe bíi pé ìwọ ni ọ̀rọ̀ náà dá lé lórí tàbí pé ńṣe lo wà ní ibì kan tí ò ń wo ohun tó ń ṣẹlẹ̀. Gbìyànjú láti máa fi ojú inú bá ìṣẹ̀lẹ̀ náà lọ.”—Steven.

“Ṣe ohun tó máa mú kí ìkẹ́kọ̀ọ́ náà gbádùn mọ́ ẹ. Jókòó sí ẹ̀yìnkùlé, kí o sì máa wá nǹkan fi panu. Mo fẹ́ràn láti máa jẹ ìpápánu nígbà tí mo bá ń kẹ́kọ̀ọ́. Àbí, tani kò fẹ́ irú ẹ̀?”—Alexandra.

Rántí pé: Ojú tí èèyàn fi ń wo nǹkan ló sábà máa ń jẹ́ kí nǹkan súni, kì í ṣe pé ohun tí èèyàn ń ṣe yẹn gan-an ló ń súni. Dípò tí wàá fi sọ pé “ìkẹ́kọ̀ọ́ máa ń sú mi,” á dáa kó o sọ pé, “kò wù láti kẹ́kọ̀ọ́.” Ojú tó o bá fi wo ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ló máa mú kó gbádùn mọ́ ẹ tàbí kó sú ẹ. Èyí ló máa mú ìwọ fúnra rẹ kíyè sára kó o sì sapá láti ṣe nǹkan kan nípa rẹ̀.—Òwe 2:10, 11.

“Ìdákẹ́kọ̀ọ́ kì í ṣe ohun tó yẹ kó súni. Bóyá ó máa sú ẹ tàbí kò ní sú ẹ, ọwọ́ rẹ ló wà.”—Vanessa.

Ohun tó yẹ kó o ronú lé:

Àwọn ọgbọ́n ìdánúṣe wo ni ìwọ lè lò tó máa jẹ́ kí ìkẹ́kọ̀ọ́ gbádùn mọ́ ẹ?

Ìṣòro: MI KÌ Í RÁYÈ

“Ó máa ń wù mí pé kí n túbọ̀ máa kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, àmọ́ pẹ̀lú bí ọwọ́ mi ṣe máa ń dí, ó máa ń ṣòro fún mi gan-an láti rí àyè jókòó kí n sì ka Bíbélì!”—Maria.

Ohun tó o nílò: OHUN TÓ ṢE PÀTÀKÌ JÙ

Lára ohun tó máa fi hàn pé o ti ń dàgbà ni pé kó o mọ béèyàn ṣe máa ń “wádìí dájú àwọn ohun tí ó ṣe pàtàkì jù.”—Fílípì 1:10.

“Mọ́mì mi máa ń sọ fún mi pé kò sígbà tí màá rí àyè fún ìkẹ́kọ̀ọ́, ńṣe ni mo gbọ́dọ̀ wá àyè fún un. Lẹ́yìn tí mo ti wá rí ìdí tó fi yẹ kí n máa kẹ́kọ̀ọ́, mo wá wá àyè fún un.”—Natanya.

“Ní báyìí tí mo ti wá dàgbà ni mó rí i pé ó yẹ kí n ṣètò àkókò tí màá máa kẹ́kọ̀ọ́, àkókò yẹn gan-an ni mo sì máa ń ṣe é, láìka ohun yòówù tó lè ṣẹlẹ̀ sí.”—Yolanda.

“Tó bá jẹ́ pé ìkẹ́kọ̀ọ́ lo fi ṣáájú eré ìnàjú, mó fi dá ẹ lójú pé wàá túbọ̀ gbádùn ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ, ọkàn rẹ kò sì ní dá ẹ lẹ́bi tó o bá wá ṣe eré ìnàjú.”—Diana.

Rántí pé: Tí o kò bá mọ ohun tó yẹ kó o fi ṣáájú, àkókò máa lọ mọ́ ẹ lọ́wọ́, o ò sì ní lè ṣe ohunkóhun ní àṣeyọrí. Ó sàn pé kó o wá nǹkan ṣe sọ́rọ̀ náà, kó o sì wá àyè láti máa kẹ́kọ̀ọ́.—Éfésù 5:15, 16.

“Bó ṣe jẹ́ pé ilé ẹ̀kọ́ girama ni mò ń lọ, kò sí ìgbà tí ọwọ́ mi kì í dí! Àmọ́, mo rí i pé ó ṣe pàtàkì gan-an pé kí n sa gbogbo ipá mi láti máa wá àyè kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì.”—Jordan.

Ohun tó yẹ kó o ronú lé:

Irú ètò wo ni ìwọ lè ṣe láti máa kẹ́kọ̀ọ́?

[Àpótí/Àwọn àwòrán tó wà ní ojú ìwé 15]

OHUN TÍ ÀWỌN OJÚGBÀ RẸ SỌ

Zachary—Má kàn máa ka ìwé kan nítorí pé òun ni àwọn òbí rẹ tàbí àwọn míì ń kà. Tó bá jẹ́ pé ohun tí ìwọ alára fẹ́ láti mọ̀ lò ń kà, a jẹ́ pé ìdákẹ́kọ̀ọ́ lò ń ṣe yẹn.

Kaley—Díẹ̀díẹ̀ ni kó o bẹ̀rẹ̀. Ì báà jẹ́ ìṣẹ́jú márùn-ún lo lè lò, ṣáà rí i pé ò ń ṣe é lójoojúmọ́. Ní kẹ̀rẹ̀kẹ̀rẹ̀, o lè wá máa lo ìṣẹ́jú mẹ́wàá, ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, . . . Tó bá yá, ńṣe ni wàá máa gbádùn rẹ̀ gan-an!

Daniela—Àwọn nǹkan kéékèèké kan wà tó o lè máa ṣe tó lè mú kí ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì gbádùn mọ́ ẹ. Wá àwọn ìkọ̀wé tó jẹ́ oríṣiríṣi àwọ̀ àti ìwé àjákọ, o sì lè ṣí abala kan lórí kọ̀ǹpútà rẹ tí wàá pe àkọlé rẹ̀ ní Ìdákẹ́kọ̀ọ́.

Jordan—Tó bá jẹ́ kókó kan tí mo nífẹ̀ẹ́ sí ni mo yàn láti kẹ́kọ̀ọ́, mi kì í mọ̀ pé àkókò ti lọ. Bákan náà, mo máa ń fẹ́ láti kẹ́kọ̀ọ́ níbi tó pa rọ́rọ́. Mi ò lè kẹ́kọ̀ọ́ níbi tí ariwo bá wà.

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 14]

(Láti rí bá a ṣe to ọ̀rọ̀ sójú ìwé, wo ìtẹ̀jáde náà gan-an)

Gé e

Ká a sí méjì