Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ǹjẹ́ O Rántí?

Ǹjẹ́ O Rántí?

Ṣé o lè dáhùn àwọn ìbéèrè tó dá lórí àwọn àpilẹ̀kọ tó wà nínú àwọn Ilé Ìṣọ́ tó jáde lọ́dún 2019?

Kí ni ìlérí tí Jèhófà ṣe yìí túmọ̀ sí: “Ohun ìjà èyíkéyìí tí wọ́n bá ṣe sí ọ kò ní ṣàṣeyọrí”? (Àìsá. 54:17)

Ọkàn wa balẹ̀ pé Jèhófà máa dáàbò bò wá lọ́wọ́ “ẹ̀fúùfù òjijì àwọn afìkà-gboni-mọ́lẹ̀.” (Àìsá. 25:​4, 5) Ó sì dájú pé àwọn ọ̀tá wa kò ní lè pa wá run.​—w19.01, ojú ìwé 6 àti 7.

Kí ló fi hàn pé Jèhófà jẹ́ onídàájọ́ òdodo nínú ìbálò rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ Kénáánì àtàwọn ọmọ Ísírẹ́lì tó jẹ́ aláìgbọràn?

Jèhófà dẹ́bi fáwọn tó ń lọ́wọ́ nínú ìṣekúṣe àtàwọn tó ń fojú pọ́n àwọn obìnrin àtàwọn ọmọ tí kò ní olùrànlọ́wọ́. Lọ́wọ́ kejì ẹ̀wẹ̀, Jèhófà máa ń bù kún àwọn èèyàn rẹ̀ tí wọ́n bá pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọ́n sì ń ṣèdájọ́ òdodo.​—w19.02, ojú ìwé 22 àti 23.

Kí ló yẹ ká ṣe tí ẹnì kan tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí Jèhófà bá ń gbàdúrà?

A lè dákẹ́ ká sì fi hàn pé a bọ̀wọ̀ fún wọn. Àmọ́, a ò ní bá wọn ṣàmín tàbí ká di àwọn tó kù lọ́wọ́ mú bí àdúrà náà ṣe ń lọ. A lè pinnu láti gbàdúrà tiwa sínú.​—w19.03, ojú ìwé 31.

Báwo ni bíbá ọmọdé ṣèṣekúṣe ṣe burú tó?

Ìwà ìkà lẹni tó bọ́mọdé ṣèṣekúṣe hù sí ọmọ náà, ó sì tún ṣẹ̀ sí ìjọ. Yàtọ̀ síyẹn, ìwà ọ̀daràn lẹni tó bọ́mọdé ṣèṣekúṣe hù, ó tàpá sí òfin ìjọba, ó sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run. Láwọn ilẹ̀ tí wọ́n bá ti ṣòfin pé kí wọ́n fi ẹ̀sùn bíbá ọmọdé ṣèṣekúṣe tó ìjọba létí, àwọn alàgbà máa ń pa òfin náà mọ́, wọ́n á sì rí i pé ọ̀rọ̀ náà dé etí ìjọba.​—w19.05, ojú ìwé 9 àti 10.

Báwo lo ṣe lè yí pa dà tàbí yí agbára tó ń darí ìrònú rẹ pa dà?

Àwọn ohun pàtàkì tó o lè ṣe ni pé: Gbàdúrà sí Jèhófà pé kó ràn ẹ́ lọ́wọ́. Máa ṣàṣàrò kó o lè mọ àwọn ìyípadà tó yẹ kó o ṣe nínú èrò àti ìṣe rẹ, kó o sì rí i pé àwọn tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú wọn lo yàn lọ́rẹ̀ẹ́.​—w19.06, ojú ìwé 11.

Báwo la ṣe lè múra sílẹ̀ de inúnibíni?

Máa ṣe ohun táá mú kí àjọṣe rẹ pẹ̀lú Jèhófà túbọ̀ lágbára. Jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Jèhófà nífẹ̀ẹ́ àwa ìránṣẹ́ rẹ̀, kò sì ní fi wá sílẹ̀ láé. Máa ka Bíbélì déédéé kó o sì máa gbàdúrà. Jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Ìjọba Ọlọ́run máa mú àwọn ìlérí Ọlọ́run ṣẹ. Há àwọn ẹsẹ Bíbélì tó o fẹ́ràn sórí àtàwọn orin Ìjọba Ọlọ́run.​—w19.07, ojú ìwé 2 sí 4.

Báwo la ṣe lè ran àwọn mọ̀lẹ́bí wa lọ́wọ́ kí wọ́n lè rí ìgbàlà?

Ó yẹ ká máa gba tiwọn rò, ká sì máa hùwà tó dáa ká lè yí wọn lérò pa dà. Yàtọ̀ síyẹn, ó yẹ ká máa mú sùúrù ká sì fọgbọ́n ṣe é tá a bá ń wàásù fún wọn.​—w19.08, ojú ìwé 15 sí 17.

Báwo ni Jésù ṣe ń tù wá lára bó ṣe wà nínú Mátíù 11:28?

Àwọn alábòójútó tó nífẹ̀ẹ́ wa dénú ló ń bójú tó wa, àwọn ọ̀rẹ́ tó dáa jù la ní, iṣẹ́ tó dáa jù la sì ń ṣe.​—w19.09, ojú ìwé 23.

Báwo ni Ọlọ́run ṣe ń mú kó máa wù wá láti gbé ìgbésẹ̀, tó sì ń fún wa ní agbára láti ṣe é? (Fílí. 2:13)

Bá a ṣe ń ka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tá a sì ń ṣàṣàrò lé e lórí, Jèhófà máa ń mú kó wù wá láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀, ó sì ń fún wa lágbára tá a máa fi ṣe é. Bákan náà, ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ máa ń ràn wá lọ́wọ́ kí ẹ̀bùn àbínibí wa lè túbọ̀ wúlò.​—w19.10, ojú ìwé 21.

Àwọn ìgbésẹ̀ wo ló yẹ kó o gbé kó o tó ṣe àwọn ìpinnu pàtàkì?

Àwọn ìgbésẹ̀ márùn-ún tó yẹ kó o gbé rèé: Ṣe ìwádìí tó jinlẹ̀. Bẹ Jèhófà pé kó fún ẹ lọ́gbọ́n. Mọ ìdí tó o fi ṣèpinnu. Mọ ohun tó o fẹ́ ṣe gan-an. Má tanra ẹ jẹ.​—w19.11, ojú ìwé 27 sí 29.

Ṣé ọ̀rọ̀ tí Sátánì sọ fún Éfà nínú ọgbà Édẹ́nì ló bí ẹ̀kọ́ èké nípa àìleèkú ọkàn?

Ọ̀rọ̀ ò rí bẹ́ẹ̀. Èṣù ò sọ fún Éfà pé tó bá jẹ èso tí Ọlọ́run ní kí wọ́n má jẹ, ó kàn máa dà bíi pé ó kú ni àmọ́ kò kú. Ó ṣe kedere nígbà náà pé ẹ̀yìn Ìkún Omi ni ẹ̀kọ́ àìleèkú ọkàn táwọn èèyàn fi ń kọ́ni lónìí bẹ̀rẹ̀. Kò sí àní-àní pé ìgbà tí Ọlọ́run da èdè àwọn èèyàn rú ní Bábélì tí wọ́n sì tú ká “sí gbogbo ayé” ni wọ́n tan ẹ̀kọ́ èké nípa àìleèkú ọkàn kálẹ̀.​—w19.12, ojú ìwé 15.