Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ohun Tó Jẹ́ Òtítọ́ Nípa Ìjọba Ọlọ́run

Ohun Tó Jẹ́ Òtítọ́ Nípa Ìjọba Ọlọ́run

Jésù kọ́ àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ láti máa gbàdúrà pé: “Baba wa tí ń bẹ ní ọ̀run, kí orúkọ rẹ di mímọ́. Kí Ìjọba rẹ dé. Kí ìfẹ́ rẹ ṣẹ ní ayé, bíi ti ọ̀run.” (Mátíù 6:9, 10) Kí ni Ìjọba Ọlọ́run? Kí ló máa ṣe? Kí nìdí tó fi yẹ ká máa gbàdúrà pé kí Ìjọba náà dé?

Jésù ni Ọba Ìjọba Ọlọ́run.

Lúùkù 1:31-33 sọ pé: “Kí o pe orúkọ rẹ̀ ní Jésù. Ẹni yìí máa jẹ́ ẹni ńlá, wọ́n á máa pè é ní Ọmọ Ẹni Gíga Jù Lọ, Jèhófà Ọlọ́run sì máa fún un ní ìtẹ́ Dáfídì bàbá rẹ̀, ó máa jẹ Ọba lórí ilé Jékọ́bù títí láé, Ìjọba rẹ̀ ò sì ní lópin.”

Ìjọba Ọlọ́run ni ìwàásù Jésù dá lé.

Mátíù 9:35 sọ pé: “Jésù wá bẹ̀rẹ̀ sí í lọ káàkiri gbogbo ìlú àti abúlé, ó ń kọ́ni nínú àwọn sínágọ́gù wọn, ó ń wàásù ìhìn rere Ìjọba náà, ó sì ń wo onírúurú àìsàn àti onírúurú àìlera sàn.”

Jésù fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ ní àmì tó máa jẹ́ kí wọ́n mọ ìgbà tí Ìjọba náà máa dé.

Mátíù 24:7 sọ pé: “Torí orílẹ̀-èdè máa dìde sí orílẹ̀-èdè àti ìjọba sí ìjọba, àìtó oúnjẹ àti ìmìtìtì ilẹ̀ sì máa wà láti ibì kan dé ibòmíì.”

Lónìí, àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù ń wàásù Ìjọba Ọlọ́run kárí ayé.

Mátíù 24:14 sọ pé: “A ó sì wàásù ìhìn rere Ìjọba yìí ní gbogbo ilẹ̀ ayé tí à ń gbé, kó lè jẹ́ ẹ̀rí fún gbogbo orílẹ̀-èdè, nígbà náà ni òpin yóò dé.”