Kí Lèrò Rẹ?
Tí Ọlọ́run bá nífẹ̀ẹ́ wa lóòótọ́, kí nìdí tó fi jẹ́ kí ìwà ibi àti ìyà máa bá a lọ?
Kí nìdí tó fi dá wa lójú pé àwọn ọjọ́ ìkẹyìn ayé là ń gbé yìí?
Báwo la ṣe mọ̀ pé àwọn nǹkan tí Bíbélì sọ nípa Ìjọba Ọlọ́run máa ṣẹ?
Ṣé Bíbélì lè ràn wá lọ́wọ́ láti ṣe àwọn ìpinnu tó bọ́gbọ́n mu lóde òní?
Torí pé Ẹlẹ́dàá wa nífẹ̀ẹ́ wa, ó pèsè ìdáhùn sí àwọn ìbéèrè yìí àtàwọn míì. Lọ sí ìkànnì wa, www.pr418.com/yo, tá a fi ń kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, kó o ba lè rí àwọn ìdáhùn náà.
Tó o bá lọ sórí ìkànnì wa, wàá rí eré ìkẹ́kọ̀ọ́, àwọn àpilẹ̀kọ, ohùn tá a gbà sílẹ̀ àti fídíò, àwọn ìfòrọ̀wánilẹ́nuwò, àti ọ̀pọ̀ àwọn ìwé lóríṣiríṣi, títí kan Bíbélì. Ọ̀fẹ́ sì ni gbogbo wọn.