Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ṣé Ìwà Àpọ́nlé Ò Ti Dàwátì Báyìí?

Ṣé Ìwà Àpọ́nlé Ò Ti Dàwátì Báyìí?

ÌDÍ TÓ FI YẸ KÁ MÁA PỌ́N ÀWỌN ÈÈYÀN LÉ

Tá a bá ń pọ́n àwọn èèyàn lé, inú wọn á máa dùn sí wa, ọ̀rọ̀ tí kò tó nǹkan ò sì ní máa di wàhálà láàárín wa.

  • Òwe Bíbélì kan sọ pé: “Ìdáhùn pẹ̀lẹ́ máa ń mú kí ìbínú rọlẹ̀, àmọ́ ọ̀rọ̀ líle ń ru ìbínú sókè.” (Òwe 15:1) Tá a bá ń hùwà àfojúdi sáwọn èèyàn, tá a sì ń sọ̀rọ̀ lọ́nà tó fi hàn pé a ò pọ́n wọn lé, ìyẹn lè múnú bí wọn, ó sì lè jẹ́ kí nǹkan bà jẹ́ kọjá àtúnṣe.

  • Jésù sọ pé: “Lára ọ̀pọ̀ nǹkan tó wà nínú ọkàn ni ẹnu ń sọ.” (Mátíù 12:34) Ọ̀rọ̀ kòbákùngbé tá a bá sọ sẹ́nì kan sábà máa ń fi ohun tó wà lọ́kàn wa hàn. Ó lè fi hàn pé a ò gba tẹni náà torí pé ẹ̀yà ẹ̀, èdè tó ń sọ, orílẹ̀-èdè tó ti wá tàbí ipò tó wà láwùjọ yàtọ̀ sí tiwa.

    Lẹ́nu àìpẹ́ yìí, nínú ìwádìí kan tí wọ́n ṣe lọ́dọ̀ ẹgbẹ̀rún méjìlélọ́gbọ̀n (32,000) èèyàn ní orílẹ̀-èdè méjìdínlọ́gbọ̀n (28), ó ju ìdajì lára wọn tó sọ pé kò tíì sígbà táwọn èèyàn ń hùwà àfojúdi bíi ti àsìkò wa yìí.

OHUN TÓ O LÈ ṢE

Tó o bá wà nílé ìwé tàbí níbi iṣẹ́, ó yẹ kó o máa bọ̀wọ̀ fún gbogbo èèyàn, tó ò bá tiẹ̀ fara mọ́ èrò wọn. Ronú jinlẹ̀ kó o lè ríbi tí èrò ìwọ àti tàwọn èèyàn ti jọra. Ìyẹn ò ní jẹ́ kó o máa ṣàríwísí wọn tàbí kó o máa dá wọn lẹ́jọ́.

“Ẹ yéé dáni lẹ́jọ́, kí a má bàa dá yín lẹ́jọ.”—Mátíù 7:1.

Ohun tó o bá fẹ́ káwọn èèyàn máa ṣe sí ẹ ni kó o máa ṣe sí wọn. Tó o bá ń ṣoore fáwọn èèyàn, tó ò sì ṣojúsàájú, ó máa wu àwọn náà kí wọ́n ṣe dáadáa sí ẹ.

“Bí ẹ ṣe fẹ́ kí àwọn èèyàn ṣe sí yín gẹ́lẹ́ ni kí ẹ máa ṣe sí wọn.”—Lúùkù 6:31.

Máa dárí jini. Tẹ́nì kan bá sọ̀rọ̀ tàbí ṣe ohun tó dùn ẹ́, má ronú pé ńṣe ló mọ̀ọ́mọ̀ fẹ́ múnú bí ẹ.

“Ìjìnlẹ̀ òye tí èèyàn ní ló máa ń dẹwọ́ ìbínú rẹ̀, ẹwà ló sì jẹ́ fún un pé kó gbójú fo àṣìṣe.”—Òwe 19:11.

OHUN TÍ ÀWA ẸLẸ́RÌÍ JÈHÓFÀ Ń ṢE

Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa ń bọ̀wọ̀ fáwọn èèyàn ládùúgbò wa àti níbi tá a ti ń ṣiṣẹ́, a sì ń rọ àwọn èèyàn pé káwọn náà máa ṣe bẹ́ẹ̀.

À ń kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, gbogbo èèyàn ló láǹfààní láti kọ́ ẹ̀kọ́ yìí, àmọ́ a kì í fipá mú ẹnikẹ́ni láti fara mọ́ èrò wa. Kàkà bẹ́ẹ̀, tá a bá ń wàásù fáwọn èèyàn a máa ń gbìyànjú láti fi ìmọ̀ràn Bíbélì sílò pé ká bá wọn sọ̀rọ̀ pẹ̀lú “ìwà tútù àti ọ̀wọ̀ tó jinlẹ̀.”—1 Pétérù 3:15; 2 Tímótì 2:24.

A kì í ṣojúsàájú, gbogbo èèyàn tó bá fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ló lè wá sáwọn ìpàdé wa. A máa gbà wọ́n tọwọ́tẹsẹ̀, láìka bí wọ́n ṣe rí tàbí irú ẹni tí wọ́n jẹ́. A máa ń gbìyànjú láti “bọ̀wọ̀ fún gbogbo enìyàn” tá ò bá tiẹ̀ fara mọ́ èrò wọn.—1 Pétérù 2:17, Bíbélì Yorùbá.

A máa ń bọ̀wọ̀ fáwọn aláṣẹ orílẹ̀-èdè tá à ń gbé. (Róòmù 13:1) A máa ń pa òfin mọ́, a sì ń san owó orí. Òótọ́ ni pé a kì í dá sí ọ̀rọ̀ ogun tàbí ọ̀rọ̀ òṣèlú, síbẹ̀ a mọ̀ pé ẹnì kọ̀ọ̀kan ló lómìnira láti pinnu ohun tó máa ṣe lórí ọ̀rọ̀ yìí.