Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ríran Onírúurú Ènìyàn Lọ́wọ́ Nílẹ̀ Netherlands

Ríran Onírúurú Ènìyàn Lọ́wọ́ Nílẹ̀ Netherlands

Àwọn Olùpòkìkí Ìjọba Ròyìn

Ríran Onírúurú Ènìyàn Lọ́wọ́ Nílẹ̀ Netherlands

ÁBÚRÁHÁMÙ jẹ́ ọkùnrin kan tí ìgbàgbọ́ rẹ̀ ò lẹ́gbẹ́. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ pé: “Nígbà tí a pè é,” Ábúráhámù ṣègbọràn sí ohùn Ọlọ́run, ó sì “jáde lọ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò mọ ibi tí òun ń lọ.” Lẹ́yìn tí Ábúráhámù kó gbogbo ìdílé rẹ̀, ó “ṣe àtìpó ní ilẹ̀ ìlérí” fún ọgọ́rùn-ún ọdún tó kù fún un nínú ìgbésí ayé rẹ̀.—Hébérù 11:8, 9.

Bákan náà ni lónìí, ọ̀pọ̀ àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ló ti tẹ́wọ́ gba ìpèníjà kíkó lọ sí orílẹ̀-èdè mìíràn kí wọ́n lè sìn ní ibi tí àìní ti pọ̀. Àwọn mìíràn ti kọ́ èdè mìíràn kí wọ́n lè jẹ́rìí fún àwọn àjèjì tó ń ya wọ orílẹ̀-èdè wọn. Gẹ́gẹ́ bí àwọn ìrírí tó tẹ̀ lé e wọ̀nyí ti fi hàn, ẹ̀mí tó dára tí wọ́n ní yìí ti ṣí “ilẹ̀kùn ńlá tí ń ṣamọ̀nà sí ìgbòkègbodò” sílẹ̀ ní Netherlands, níbi tó jẹ́ pé mílíọ̀nù kan lára mílíọ̀nù mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ènìyàn tó ń gbébẹ̀ ló wá láti orílẹ̀-èdè mìíràn.—1 Kọ́ríńtì 16:9.

◻ Orílẹ̀-èdè kan ní Àárín Gbùngbùn Ìlà Oòrùn ayé ni Bahram, tó fìgbà kan jẹ́ ẹni tí ń dá àwọn tó ń ja ìjà Kung Fu lẹ́kọ̀ọ́, ti wá. Ó gba ẹ̀dà Bíbélì kan àti àwọn ìtẹ̀jáde Watch Tower Society bíi mélòó kan. Láàárín oṣù kan, Bahram wá mọ̀ pé òun ti rí òtítọ́. Bí wọ́n ṣe bẹ̀rẹ̀ sí í bá òun àti ìyàwó rẹ̀ kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì nìyẹn, àmọ́ ìṣòro kan wá wà níbẹ̀—ẹni tí ń kọ́ wọn lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ò gbọ́ èdè wọn. Wọ́n rántí pé àpèjúwe làwọn fi ń bá ara wọn sọ̀rọ̀, “tọwọ́ tẹsẹ̀” ni wọ́n fi ń sọ̀rọ̀. Nígbà tó yá, ó ṣeé ṣe fún Bahram àti ìyàwó rẹ̀ láti rí ìjọ tí wọ́n ti ń sọ èdè àbínibí wọn, kíá ni wọ́n sì tẹ̀ síwájú lọ́nà tó yá kánkán. Bahram ti di Ẹlẹ́rìí tó ṣèrìbọmi báyìí.

◻ Àwọn tọkọtaya ọmọ ilẹ̀ Netherlands, tí wọ́n jẹ́ aṣáájú ọ̀nà, lọ bá ọkùnrin ará Indonesia tó dúró síwájú ilé ìtajà ńlá kan. Ó yà á lẹ́nu gan-an nígbà tí tọkọtaya náà bá a sọ̀rọ̀ ní èdè tirẹ̀. Wọ́n wá ṣètò bí wọn ó ṣe wá bá a nílé tó ń gbé. Wọ́n wá rí i pé ó ti lé lógún ọdún tó fi gbé ní Rọ́ṣíà, láàárín àkókò yẹn ló sì di oníṣègùn tí ń tọ́jú àwọn obìnrin. Ó ní òun ò gba pé Ọlọ́run wà o, àmọ́ ó sọ pé gbogbo ìgbà tí òun bá ti gbẹ̀bí ọmọ kan lòun máa ń ṣe kàyéfì pé, “Áá àá, ara ènìyàn mà pé o! Ìyanu ńlá ni!” Ó gbà láti kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, kò sì pẹ́ tó fi gbà gbọ́ pé Ẹlẹ́dàá kan wà tó bìkítà nípa ìran ènìyàn. (1 Pétérù 5:6, 7) Ó ti di arákùnrin tó ti ṣèrìbọmi báyìí, ó sì ń sìn pẹ̀lú ìjọ Indonesia tó wà ní Amsterdam.

◻ Àwùjọ àwọn aṣáájú ọ̀nà kan ti pegedé nínú wíwàásù fún àwọn ènìyàn tó ń sọ onírúurú èdè, tí wọ́n ń gúnlẹ̀ sí Rotterdam, tó jẹ́ ọ̀kan lára èbúté ọkọ̀ òkun tó tóbi jù lọ lágbàáyé. Ìyọrísí ìgbòkègbodò àwùjọ àwọn oníwàásù tí wọ́n jẹ́ onítara wọ̀nyí ni pé, ọ̀pọ̀ àwọn tó ń wa ọkọ̀ òkun, títí kan ọ̀gákọ̀ kan, alábòójútó kan, àti ẹnì kan tí ó jẹ́ ẹ̀ṣọ́ nígbà kan rí, ti gba òtítọ́. Àwọn náà ti ń ṣèrànwọ́ láti sọ ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run fún gbogbo ayé báyìí.—Mátíù 24:14.

Bí ó ti rí ní àwọn apá ibòmíràn lágbàáyé, àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó wà ní Netherlands ti pinnu láti ṣe ipa tiwọn ní kíkéde ìhìn rere àìnípẹ̀kun fún gbogbo orílẹ̀-èdè, ẹ̀yà, ahọ́n, àti ènìyàn.—Ìṣípayá 14:6.