Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn Òǹkàwé
Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn Òǹkàwé
Kí nìdí tí Aísáyà 30:21 fi sọ pé wàá gbọ́ ọ̀rọ̀ Jèhófà “lẹ́yìn rẹ,” níwọ̀n bí ẹsẹ tó ṣáájú rẹ̀ ti jẹ́ ká gbà pé iwájú ni Jèhófà wà nítorí ó sọ pé, “ojú rẹ yóò sì di ojú tí ń rí Olùkọ́ni rẹ Atóbilọ́lá”?
Aísáyà 30:20, 21 kà pé: “Olùkọ́ni rẹ Atóbilọ́lá kì yóò tún fi ara rẹ̀ pa mọ́, ojú rẹ yóò sì di ojú tí ń rí Olùkọ́ni rẹ Atóbilọ́lá. Etí rẹ yóò sì gbọ́ ọ̀rọ̀ kan lẹ́yìn rẹ tí ń sọ pé: ‘Èyí ni ọ̀nà. Ẹ máa rìn nínú rẹ̀,’ bí ó bá ṣẹlẹ̀ pé ẹ lọ sí apá ọ̀tún tàbí bí ó bá ṣẹlẹ̀ pé ẹ lọ sí apá òsì.”
Bí òǹkàwé bá gba ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ ẹsẹ yẹn sí bó ṣe fara hàn níbẹ̀ gẹ́lẹ́, a jẹ́ pé á máa wo Jèhófà níwájú rẹ̀ ṣùgbọ́n á máa gbóhùn Rẹ̀ látẹ̀yìn. Ṣùgbọ́n o, èdè ìṣàpẹẹrẹ ni ẹsẹ yìí lò, kò sì yẹ ká gbà á sí pé bó ṣe sọ ọ́ gẹ́lẹ́ yẹn náà ló ṣe jẹ́.
Èdè ìṣàpẹẹrẹ tó wà ní ẹsẹ ogún múni ronú lọ sọ́dọ̀ ìránṣẹ́ kan tó ń ṣiṣẹ́ fún ọ̀gá, tó sì ṣe tán nígbà gbogbo láti tẹ̀ lé ìtọ́ni ọ̀gá rẹ̀. Gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ kan tó ń fara balẹ̀ kíyè sí ọwọ́ tí ọ̀gá rẹ̀ fi ń júwe láti lè fòye mọ ohun tí ọ̀gá rẹ̀ ń fẹ́ kó ṣe, bẹ́ẹ̀ làwọn èèyàn Jèhófà ń fara balẹ̀ kíyè sí ìtọ́ni tá a gbé karí Bíbélì tí Jèhófà ń tipa ètò àjọ rẹ̀ orí ilẹ̀ ayé pèsè ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé. (Sáàmù 123:1, 2) Wọ́n ń tẹ̀ lé ìtọ́ni rẹ̀ dájúdájú, wọ́n sì ń wà lójúfò nígbà gbogbo sí ohunkóhun tí Jèhófà bá tipasẹ̀ “ẹrú olóòótọ́ àti olóye” tọ́ka wọn sí.—Mátíù 24:45-47.
Ọ̀rọ̀ táwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wá ń gbọ́ látẹ̀yìn ńkọ́? Ó bọ́gbọ́n mu láti sọ pé ohùn tó ń wá látẹ̀yìn jẹ́ ohùn ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run ti sọ sẹ́yìn, tí à ń gbọ́ látinú àkọsílẹ̀ Ọ̀rọ̀ rẹ̀ bí “ìríjú” rẹ̀ “olóòótọ́” ṣe ń ṣàlàyé wọn fún wa. (Lúùkù 12:42) Àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run òde òní ń gbọ́ ohùn rẹ̀ bí wọ́n ṣe ń ṣakitiyan láti kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, tí wọ́n sì ń jẹ́ kí àwọn ìtẹ̀jáde látọ̀dọ̀ “ẹrú olóòótọ́ àti olóye” tí í ṣe “ìríjú olóòótọ́” náà kọ́ wọn bí wọ́n ṣe máa fi àwọn ìlànà rẹ̀ sílò nígbèésí ayé wọn. Àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run ń rí i níwájú wọn lọ́nà ìṣàpẹẹrẹ, wọ́n sì ń gbóhùn rẹ̀ lẹ́yìn wọn lọ́nà ìṣàpẹẹrẹ nígbà tí wọ́n bá ń kíyè sí ìtọ́sọ́nà tó bá àkókò mu tí Olùkọ́ni wọn Atóbilọ́lá ń pèsè, tí wọ́n ń gbára lé e, tí wọ́n sì tún ń kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tá a ti kọ láti ọ̀pọ̀ ọ̀rúndún sẹ́yìn.—Róòmù 15:4.