Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ọmọdébìnrin Tó Jẹ́ Ọ̀làwọ́

Ọmọdébìnrin Tó Jẹ́ Ọ̀làwọ́

Ọmọdébìnrin Tó Jẹ́ Ọ̀làwọ́

LẸ́NU àìpẹ́ yìí, ọmọdébìnrin kan tó jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́sàn-án lórílẹ̀-èdè Brazil pín owó tó ti tọ́jú pa mọ́ sọ́nà méjì, láìsẹ́ni tó kọ́ ọ. Apá kan jẹ́ dọ́là méjìdínlógún, apá kejì sì jẹ́ dọ́là mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n. Ó fi dọ́là méjìdínlógún sínú àpótí ọrẹ fún ìnáwó ìjọ nínú Gbọ̀ngàn Ìjọba wọn. Ó wá fi dọ́là mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ránṣẹ́ sí ẹ̀ka ọ́fíìsì àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà, ó sì kọ lẹ́tà kékeré kan mọ́ ọn. Ohun tó wà nínú lẹ́tà náà rèé: “Mo fẹ́ fi owó yìí ṣètọrẹ fún iṣẹ́ ìwàásù kárí ayé. Ó wù mí láti ran ọ̀pọ̀ àwọn arákùnrin àti arábìnrin kárí ayé lọ́wọ́ láti máa wàásù ìhìn rere. Ìfẹ́ ńlá tí mo ní fún Jèhófà ló mú kí n fowó yìí ṣètọrẹ.”

Àwọn òbí ọmọdébìnrin yìí ti kọ́ ọ pé ó ṣe pàtàkì kóun náà máa lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ ìwàásù Ìjọba Ọlọ́run. Wọ́n sì tún ti gbìn ín sí i lọ́kàn pé ó gbọ́dọ̀ máa ‘fi àwọn ohun ìní rẹ̀ tí ó níye lórí bọlá fún Jèhófà.’ (Òwe 3:9) Bíi ti ọmọdébìnrin yẹn, ẹ jẹ́ kí gbogbo wa máa fi ìtara lọ́wọ́ nínú ìtẹ̀síwájú gbogbo ohun tó jẹ́ mọ́ Ìjọba Ọlọ́run lágbègbè wa àti kárí ayé!