Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ọ̀rọ̀ Bẹ́yìn Yọ!

Ọ̀rọ̀ Bẹ́yìn Yọ!

Abala Àwọn Ọ̀dọ́

Ọ̀rọ̀ Bẹ́yìn Yọ!

Ohun tó o máa ṣe: Ibi tí kò sáriwo ni kó o ti ṣe ìdánrawò yìí. Bó o bá ṣe ń ka àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó wà nísàlẹ̀ yìí, máa fojú inú wò ó bíi pé o wà níbi tọ́rọ̀ náà ti ń ṣẹlẹ̀, jẹ́ kó dà bíi pé ò ń gbọ́ báwọn èèyàn náà ṣe ń sọ̀rọ̀. Ronú nípa bóhun tó ò ń kà yẹn ṣe máa rí lára àwọn èèyàn wọ̀nyẹn. Kó o sì máa fojú inú wò ó bí ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lọ́wọ́lọ́wọ́.

KA ÌTÀN NÁÀ DÁADÁA.KA DÁNÍẸ́LÌ 6:1-28.

Kí lèrò ẹ? Irú ọkùnrin wo ni Dáríúsì? Ṣàpèjúwe bó o ṣe rò pé ó máa rí? Báwo lo ṣe rò pé ohùn rẹ̀ ṣe máa rí nígbà tó bá ń sọ̀rọ̀? (Tún ka ẹsẹ 14, 16 àti 18 sí 20.)

․․․․․

Báwo ni ihò yẹn ṣe rí, báwo lo sì ṣe máa ṣàpèjúwe àwọn kìnnìún wọ̀nyẹn?

․․․․․

Ṣàpèjúwe ohun tó o rò pé ó ṣẹlẹ̀ láàárín ìṣẹ́jú mélòó kan lẹ́yìn tí wọ́n ju Dáníẹ́lì sínú ihò náà tí wọ́n sì dé e pa.

․․․․․

ṢÈWÁDÌÍ KÓ O SÌ RONÚ JINLẸ̀.

Kí nìdí táwọn ìjòyè ọba Dáríúsì fi ń jowú Dáníẹ́lì? (Tún ka ẹsẹ 3.)

․․․․․

Kí nìdí tí Dáníẹ́lì fi gbàdúrà níbi táwọn èèyàn ti lè rí i dípò kó gbà á ní kọ̀rọ̀? (Tún ka ẹsẹ 10, 11.)

․․․․․

Kí nìdí tí òfin táwọn kan ṣe nípa àdúrà fi dùn mọ́ Dáríúsì nínú? (Tún ka ẹsẹ 7.)

․․․․․

MÁA FOHUN TÓ O KỌ́ ṢÈWÀ HÙ. ṢÀKỌSÍLẸ̀ Ẹ̀KỌ́ TÓ O KỌ́ NÍPA . . .

Béèyàn ṣe lè jẹ́ onígboyà nígbà táwọn ẹlòmíì bá ń ta kò ó.

․․․․․

Bí àdúrà ti ṣe pàtàkì tó.

․․․․․

Bí Jèhófà ṣe máa ń bójú tó àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tó ń fi tọkàntọkàn sìn ín.

․․․․․

KÍ LÓ WÚ Ẹ LÓRÍ JÙ LỌ NÍNÚ ÌTÀN INÚ BÍBÉLÌ YÌÍ, KÍ SÌ NÌDÍ?

․․․․․