Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ìyanu Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Pẹ́ńtíkọ́sì!

Ìyanu Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Pẹ́ńtíkọ́sì!

Abala Àwọn Ọ̀dọ́

Ìyanu Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Pẹ́ńtíkọ́sì!

Ohun tó o máa ṣe: Ibi tí kò sáriwo ni kó o ti ṣe ìdánrawò yìí. Bó o bá ṣe ń ka àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó wà nísàlẹ̀ yìí, máa fojú inú wò ó bíi pé o wà níbi tọ́rọ̀ náà ti ń ṣẹlẹ̀, jẹ́ kó dà bíi pé ò ń gbọ́ báwọn èèyàn náà ṣe ń sọ̀rọ̀. Ronú nípa bóhun tó ò ń kà yẹn ṣe máa rí lára àwọn èèyàn wọ̀nyẹn. Kó o sì máa fojú inú wò ó bí ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lọ́wọ́lọ́wọ́.

KA ÌTÀN NÁÀ DÁADÁA.—KA ÌṢE 2:1-21, 38-41.

Kí ló wá sí ẹ lọ́kàn bó o ṣe ń kà nípa “atẹ́gùn líle tí ń rọ́ yìì,” àti “ahọ́n bí ti iná”?

․․․․․

Kí lo rò pé àwọn èèyàn náà sọ nígbà tí wọ́n gbọ́ táwọn ọmọ ẹ̀yìn ń sọ̀rọ̀ ní ahọ́n àjèjì?

․․․․․

Báwo lo ṣe rò pé ohun tó ń ṣẹlẹ̀ yìí ṣe rí lára àwọn tó ń fi wọ́n ṣẹlẹ́yà gẹ́gẹ́ bí ẹsẹ 13 ti ṣàlàyé?

․․․․․

ṢÈWÁDÌÍ KÓ O SÌ RONÚ JINLẸ̀.

Àjọyọ̀ wo ni wọ́n ń pè ní Pẹ́ńtíkọ́sì, báwo nìyẹn sì ṣe lè nípa lórí ọ̀pọ̀ èèyàn tó wá sí Jerúsálẹ́mù? (Diutarónómì 16:10-12)

․․․․․

Báwo ni Pétérù ṣe bọ̀wọ̀ fáwọn tó ń bá sọ̀rọ̀, báwo ló sì ṣe bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ́nà tí wọ́n á fi nífẹ̀ẹ́ sóhun tó fẹ́ sọ? (Ìṣe 2:29)

․․․․․

Báwo ni ìgboyà tí Pétérù ní lọ́jọ́ Pẹ́ńtíkọ́sì ṣe yàtọ̀ gédégbé sóhun tó ṣe nínú àgbàlá àlùfáà àgbà nígbà kan sẹ́yìn? (Mátíù 26:69-75)

․․․․․

MÁA FOHUN TÓ O KỌ́ ṢÈWÀ HÙ. KỌ Ẹ̀KỌ́ TÓ O KỌ́ NÍPA . . .

Ìdí tó fi yẹ ká máa sọ̀rọ̀ lọ́nà táwọn èèyàn á fi nífẹ̀ẹ́ sóhun tá a fẹ́ sọ àti ìdí tó fi yẹ ká máa bọ̀wọ̀ fáwọn èèyàn nígbà tá a bá ń sọ àwọn nǹkan tá a gbà gbọ́ nínú Bíbélì fún wọn.

․․․․․

Bó o ṣe lè fìgboyà jẹ́rìí nípá Jèhófà, ká tiẹ̀ sọ pé ẹ̀rù ṣì ń bà ẹ́ báyìí.

․․․․․

KÍ LÓ WÚ Ẹ LÓRÍ JÙ LỌ NÍNÚ ÌTÀN YÌÍ, KÍ SÌ NÌDÍ?

․․․․․

Tó o bá fẹ́ mọ púpọ̀ sí i, ka Ilé Ìṣọ́ September 15, 1996, ojú ìwé 8 àti 9.