Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ṣé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ni Bíbélì?

Ṣé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ni Bíbélì?

Ṣé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ni Bíbélì?

“Gbogbo Ìwé Mímọ́ ni Ọlọ́run mí sí, ó sì ṣàǹfààní fún kíkọ́ni, fún fífi ìbáwí tọ́ni sọ́nà, fún mímú àwọn nǹkan tọ́, fún bíbániwí nínú òdodo, kí ènìyàn Ọlọ́run lè pegedé ní kíkún, tí a mú gbára dì pátápátá fún iṣẹ́ rere gbogbo.”—2 TÍMÓTÌ 3:16, 17.

Ọ̀RỌ̀ tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ nípa bí Bíbélì ṣe níye lórí tó yìí mà lágbára gan-an o! Ó dájú pé àwọn ìwé Bíbélì tó wà lárọ̀ọ́wọ́tó rẹ̀ nígbà yẹn ló ń sọ, ìyẹn àwọn ìwé táwọn èèyàn sábà máa ń pè ní Májẹ̀mú Láéláé. Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ tó sọ yẹn kan gbogbo ìwé mẹ́rìndínláàádọ́rin [66] tó wà nínú Bíbélì, títí kan èyí táwọn olóòótọ́ ọmọ ẹ̀yìn Jésù kọ ní ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní Sànmánì Kristẹni.

Bíi ti Pọ́ọ̀lù, ǹjẹ́ ìwọ náà ń fojú iyebíye wo Bíbélì? Ǹjẹ́ o rò pé Ọlọ́run mí sí àwọn tó kọ Bíbélì lóòótọ́? Àwọn Kristẹni ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní gbà pé ó rí bẹ́ẹ̀. Ìgbàgbọ́ yẹn kò mì fún ọgọ́rọ̀ọ̀rún ọdún tó tẹ̀ lé e. Bí àpẹẹrẹ, ní ọgọ́rùn-ún ọdún kẹrìnlá, òǹkọ̀wé ọmọ ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì kan tó ń jẹ́ John Wycliffe sọ pé Bíbélì jẹ́ “ìlànà òtítọ́ tí kò láṣìṣe.” Ìwé atúmọ̀ ọ̀rọ̀ inú Bíbélì, ìyẹn The New Bible Dictionary, sọ nípa ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù tá a fàyọ níbẹ̀rẹ̀ pé, “ìmísí [Ọlọ́run] ló fìdí gbogbo ohun tí Bíbélì sọ múlẹ̀ pé ó jóòótọ́.”

Àwọn Èèyàn Ti Ń Kẹ̀yìn sí Bíbélì

Lẹ́nu àìpẹ́ yìí, àwọn èèyàn ò fi bẹ́ẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé mọ́ nínú àṣẹ Bíbélì. Ìwé àmọ̀ràn kan nípa ẹ̀sìn, ìyẹn The World’s Religions, sọ pé, “Gbogbo Kristẹni [ṣì] máa ń sọ ọ́ lẹ́nu pé àwọn gbà pé Bíbélì ní àṣẹ lórí ìwà àti ẹ̀kọ́ ìgbàgbọ́ àwọn.” Àmọ́ nínú ìwà wọn, èyí kò rí bẹ́ẹ̀ mọ́. Ọ̀pọ̀ èèyàn nísinsìnyí ló ń wo Bíbélì pé ó jẹ́ “ẹ̀kọ́ èèyàn tí kò ṣeé gbára lé.” Bí wọ́n tilẹ̀ gbà pé àwọn tó kọ Bíbélì ní ìgbàgbọ́ gan-an, wọ́n kà wọ́n sí aláìpé tó ń sapá láti ṣàlàyé òtítọ́ tó jinlẹ̀ àmọ́ tí wọn kò ní ìmọ̀ àti ìlàlóye tá a ní lónìí.

Ká sòótọ́, àwọn èèyàn díẹ̀ ló gbà pé kí ìlànà Bíbélì máa darí èrò àti ìṣe wọn lónìí. Bí àpẹẹrẹ, ṣó o máa ń gbọ́ lọ́pọ̀ ìgbà táwọn èèyàn máa ń sọ pé ìlànà Bíbélì nípa ìbálòpọ̀ kò bóde mu mọ́ àti pé kò wúlò mọ́? Ó yá ọ̀pọ̀ èèyàn lára láti bẹnu àtẹ́ lu òfin àti ìlànà inú Bíbélì tàbí kí wọ́n tiẹ̀ pa wọ́n tì pátápátá nígbà tí wọ́n bá rò pé ó fẹ́ dí àwọn lọ́wọ́. Àwọn kan tí wọ́n pe ara wọn ní Kristẹni máa ń mọ̀ọ́mọ̀ ṣàìgbọràn sí ohun tí Bíbélì sọ nípa àgbèrè, panṣágà, àìṣòótọ́ àti ìmutíyó kẹ́ri.—1 Kọ́ríńtì 6:9, 10.

Kí nìdí tó fi rí bẹ́ẹ̀? Ní nǹkan tó lé lọ́gọ́rùn-ún ọdún sẹ́yìn, Alàgbà Charles Marston tó jẹ́ awalẹ̀pìtàn sọ ìdí kan ṣoṣo tó fà á nínú ìwé rẹ̀ The Bible Is True. Ó sọ pé àwọn èèyàn tètè máa ń “gba èrò àwọn òǹkọ̀wé òde òní láìjanpata,” ìyẹn àwọn tó ń ṣàtakò pé ọ̀rọ̀ Bíbélì kò jóòótọ́. Ṣé irú ìyẹn náà ń ṣẹlẹ̀ lónìí? Ojú wo ló yẹ kó o máa fi wo èrò àti àbá àwọn ọ̀mọ̀wé tí wọn ò jẹ́ káwọn èèyàn fọkàn tán Bíbélì mọ́? Wo ohun tí àpilẹ̀kọ tó kàn máa sọ nípa èyí.