Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Jésù “Kó Ẹ̀ṣẹ̀ Ayé Lọ”

Jésù “Kó Ẹ̀ṣẹ̀ Ayé Lọ”

Jésù “Kó Ẹ̀ṣẹ̀ Ayé Lọ”

Jòhánù Oníbatisí sọ pé Jésù “kó ẹ̀ṣẹ̀ ayé lọ.” (Jòhánù 1:29) Èyí jẹ́ ká mọ ipa tí Jésù kó nínú gbígba aráyé onígbọràn là.

Àmọ́, kí nìdí tí Jésù fi ní láti kú kó lè gba àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ là?

Kí ni Jésù mú kó ṣeé ṣe nígbà tó fínnúfíndọ̀ yọ̀ǹda ẹ̀mí rẹ̀?

Àwọn wo ló jàǹfààní látinú ikú rẹ̀?

Àǹfààní wo ni ikú rẹ̀ máa ṣe ọ́?

Ọdọọdún làwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa ń ṣe Ìrántí Ikú Jésù ní àyájọ́ ọjọ́ tó kú. Lọ́dún yìí, ọjọ́ náà bọ́Sunday, April 17, lẹ́yìn tí oòrùn bá ti wọ̀.

Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà fi tayọ̀tayọ̀ pè ọ́, pé kó o wá síbi tá a ti fẹ́ ṣe Ìrántí Ikú Jésù. A óò dáhùn àwọn ìbéèrè tó wà lókè yìí nínú Bíbélì.

A rọ̀ ẹ́ pé kó o lọ sí ibi tó sún mọ́ ọ jù lọ tí wọ́n ti fẹ́ ṣe ìrántí náà. Béèrè ibi tí wọ́n ti fẹ́ ṣe é àti àkókò tí wọ́n máa ṣe é lọ́wọ́ àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó wà ládùúgbò rẹ.