Àjọṣe Rẹ Pẹ̀lú Ọlọ́run
APÁ 9
Àjọṣe Rẹ Pẹ̀lú Ọlọ́run
Èwo ló ṣòro jù fún ẹ lára àwọn gbólóhùn tá a tò sísàlẹ̀ yìí?
□ Kíkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì
□ Gbígbàdúrà déédéé sí Jèhófà Ọlọ́run
□ Sísọ ohun tí mo gbà gbọ́ fáwọn ẹlòmíì (àgàgà àwọn ojúgbà mi)
□ Lílóye ìdí tó fi bọ́gbọ́n mu láti máa fàwọn ìlànà Bíbélì ṣèwà hù
Kọ ohun tó o ní lọ́kàn láti ṣe nípa àwọn ohun tó o fàmì sí pé ó ṣòro fún ẹ jù lọ sórí ìlà yìí.
․․․․․
Orí 34 sí 38 nínú ìwé yìí máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti rí bó o ṣe lè mú kí àjọṣe rẹ pẹ̀lú Ọlọ́run fìdí múlẹ̀, bó o ṣe lè máa fi ìlànà Bíbélì ṣèwà hù àti bó o ṣe lè láwọn àfojúsùn tó máa jẹ́ káyé ẹ lójú kó sì nítumọ̀.
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 280, 281]