Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Àwọn Ìyọnu Tó Wá Sórí Àwọn Oníṣọ́ọ̀ṣì Látọ̀dọ̀ Jèhófà

Àwọn Ìyọnu Tó Wá Sórí Àwọn Oníṣọ́ọ̀ṣì Látọ̀dọ̀ Jèhófà

Orí 21

Àwọn Ìyọnu Tó Wá Sórí Àwọn Oníṣọ́ọ̀ṣì Látọ̀dọ̀ Jèhófà

Ìran 5—Ìṣípayá 8:1–9:21

Ohun tó dá lé: Fífun mẹ́fà nínú àwọn kàkàkí méje náà

Ìgbà tó nímùúṣẹ: Látìgbà tí Jèhófà ti gbé Kristi Jésù gorí ìtẹ́ lọ́dún 1914 títí dìgbà ìpọ́njú ńlá

1. Kí ló ṣẹlẹ̀ nígbà tí Ọ̀dọ́ Àgùntàn ṣí èdìdì keje?

 ÀWỌN áńgẹ́lì ti dá “ẹ̀fúùfù mẹ́rin” náà dúró títí tí a ó fi fi èdìdì di ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì [144,000] àwọn ọmọ Ísírẹ́lì Ọlọ́run tí a ó sì fún ogunlọ́gọ̀ ńlá náà láǹfààní láti là á já. (Ìṣípayá 7:1-4, 9) Ṣùgbọ́n, kí ìjì ẹlẹ́fùúùfù líle yẹn tó rọ́ lu ayé, a gbọ́dọ̀ kéde àwọn ìdájọ́ Jèhófà tó ń bọ̀ lórí ayé Sátánì pẹ̀lú! Bí Ọ̀dọ́ Àgùntàn náà ṣe ń ṣí èdìdì keje tó kẹ́yìn, Jòhánù ti ní láti máa fi gbogbo ọkàn bá ohun tó ń ṣẹlẹ̀ bọ̀ kó lè rí ohun tí a ó fi hàn kedere. Ẹ wo ohun tó lóhun rí wàyí: “Nígbà tí ó [ìyẹn Ọ̀dọ́ Àgùntàn náà] sì ṣí èdìdì keje, kẹ́kẹ́ pa ní ọ̀run fún nǹkan bí ààbọ̀ wákàtí. Mo sì rí àwọn áńgẹ́lì méje tí wọ́n dúró níwájú Ọlọ́run, a sì fún wọn ní kàkàkí méje.”—Ìṣípayá 8:1, 2.

Àkókò Àdúrà Àtọkànwá

2. Kí ló ṣẹlẹ̀ nígbà tí kẹ́kẹ́ pa fún ààbọ̀ wákàtí ìṣàpẹẹrẹ ní ọ̀run?

2 Àkókò pàtàkì làkókò tí kẹ́kẹ́ pa yìí o! Ààbọ̀ wákàtí lè ti gùn jù nígbà tó o bá ń dúró pé kí ohun kan ṣẹlẹ̀. Kódà, Jòhánù ò tiẹ̀ gbúròó orin ìyìn tí wọ́n ń kọ lọ́run mọ́ báyìí. (Ìṣípayá 4:8) Kí ló fà á? Jòhánù rí ohun tó fà á nínú ìran: “Áńgẹ́lì mìíràn sì dé, ó sì dúró nídìí pẹpẹ, ó ní ajere tùràrí oníwúrà lọ́wọ́; a sì fún un ní ìwọ̀n tùràrí púpọ̀ gan-an láti sun ún pẹ̀lú àdúrà gbogbo ẹni mímọ́ lórí pẹpẹ wúrà tí ó wà níwájú ìtẹ́ náà. Èéfín tùràrí náà sì gòkè láti ọwọ́ áńgẹ́lì náà pẹ̀lú àdúrà àwọn ẹni mímọ́ síwájú Ọlọ́run.”—Ìṣípayá 8:3, 4.

3. (a) Kí ni tùràrí tí wọ́n ń sun rán wa létí rẹ̀? (b) Kí nìdí tí kẹ́kẹ́ fi pa fún ààbọ̀ wákàtí lọ́run?

3 Èyí á rán wa létí pé nínú ètò ìjọsìn àwọn Júù, ojoojúmọ́ ni wọ́n máa ń sun tùràrí nínú àgọ́ ìjọsìn, wọ́n sì ń ṣe bẹ́ẹ̀ nínú tẹ́ńpìlì Jerúsálẹ́mù tí wọ́n kọ́ lọ́pọ̀ ọdún lẹ́yìn náà. (Ẹ́kísódù 30:1-8) Lákòókò tí wọ́n bá ń sun tùràrí báyìí, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tí kì í ṣe àlùfáà máa dúró lẹ́yìn òde ibi mímọ́, wọ́n á máa gbàdúrà. Ó dájú pé àdúrà ìdákẹ́jẹ́ẹ́ látinú ọkàn wọn ni wọ́n ń gbà, ẹni tí èéfín tùràrí náà ń gòkè tọ̀ lọ ni wọ́n sì ń gbàdúrà sí. (Lúùkù 1:10) Jòhánù wá rí ohun tó jọ bẹ́ẹ̀ báyìí, tó ń ṣẹlẹ̀ lọ́run. Tùràrí áńgẹ́lì náà ní í ṣe pẹ̀lú “àdúrà àwọn ẹni mímọ́.” Kódà, nínú ìran kan tó ṣáájú èyí, a rí i pé tùràrí náà dúró fún irú àwọn àdúrà bẹ́ẹ̀. (Ìṣípayá 5:8; Sáàmù 141:1, 2) Tó bá rí bẹ́ẹ̀, a wá rí i kedere pé kẹ́kẹ́ tó pa ní ọ̀run yẹn pa láti jẹ́ kí wọ́n máa gbọ́ àdúrà àwọn ẹni mímọ́ orí ilẹ̀ ayé.

4, 5. Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wo tá a rí nínú ìtàn ló jẹ́ ká lè mọ àkókò tó bá àkókò tí kẹ́kẹ́ pa fún ààbọ̀ wákàtí ìṣàpẹẹrẹ mu?

4 Ǹjẹ́ a lè mọ ìgbà tí èyí ṣẹlẹ̀? A kúkú lè mọ̀ ọ́n tá a bá yẹ àwọn ọ̀rọ̀ tó wà ní àyíká ọ̀rọ̀ náà wò, tá a wá fi wé àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tí ìtàn fi hàn pé ó wáyé lápá ìbẹ̀rẹ̀ ọjọ́ Olúwa. (Ìṣípayá 1:10) Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó ṣẹlẹ̀ lórí ilẹ̀ ayé láàárín ọdún 1918 sí ọdún 1919, bá ìran tí Ìṣípayá 8:1-4 ṣàpèjúwe mu rẹ́gí. Láti ogójì [40] ọdún ṣáájú 1914 làwọn Akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ń pe àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà nígbà yẹn, ti ń kéde láìṣojo pé àwọn àkókò Kèfèrí yóò dópin lọdún yẹn. Àwọn àjálù tó wáyé lọ́dún 1914 fi hàn pé òótọ́ ni wọ́n sọ. (Lúùkù 21:24, Bibeli Mimọ; Mátíù 24:3, 7, 8) Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wọn tún gbà gbọ́ pé ọdún 1914 ni a óò mú wọn kúrò lórí ilẹ̀ ayé yìí lọ síbi ogún wọn lọ́run. Ìyẹn ò ṣẹlẹ̀. Kàkà bẹ́ẹ̀, nígbà Ogun Àgbáyé Kìíní, wọ́n fara da àkókò inúnibíni tó gbóná girigiri. Ní October 31, ọdún 1916, ààrẹ àkọ́kọ́ ti Watch Tower Society, Charles T. Russell, kú. Lẹ́yìn náà, ní July 4, ọdún 1918, wọ́n kó ààrẹ tuntun tó tẹ̀ lé e, Joseph F. Rutherford, àtàwọn aṣojú Society méje mìíràn lọ sí ọgbà ẹ̀wọ̀n tó wà nílùú Atlanta, ní ìpínlẹ̀ Georgia, lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà lẹ́yìn tí wọ́n dá wọn lẹ́jọ́ tí ò tọ́ sí wọn pé kí wọ́n lọ fi ẹ̀wọ̀n ọlọ́dún gbọọrọ jura.

5 Jẹbẹtẹ gbọ́mọ lé àwọn Kristẹni olóòótọ́ ẹgbẹ́ Jòhánù lọ́wọ́. Kí wá ni Ọlọ́run fẹ́ kí wọ́n ṣe lẹ́yìn ìyẹn o? Ìgbà wo la máa gbà wọ́n sókè ọ̀run? Àpilẹ̀kọ kan tí àkòrí rẹ̀ jẹ́ “Ìkórè Dópin—Kí Ni Yóò Tẹ̀ Lé E?” jáde nínú Ilé Ìṣọ́ (Gẹ̀ẹ́sì) ìtẹ̀jáde May 1, 1919. Ó fi hàn pé àwọn nǹkan ò dá wọn lójú ó sì rọ àwọn olóòótọ́ láti máa fara dà á nìṣó, ó wá fi kún un pé: “A gbà nísinsìnyí pé tòótọ́ ni pé ìkórè ẹgbẹ́ ìjọba náà jẹ́ ìṣẹ̀lẹ̀ kan tá a ti ṣe láṣeparí àti pé gbogbo àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ti fi èdìdì dì lọ́nà tó tọ́ àti pé ilẹ̀kùn ni a ti tì.” Ní àkókò ìṣòro yìí, àwọn àdúrà àtọkànwá táwọn ẹgbẹ́ Jòhánù ń gbà ń gòkè lọ, bí ẹni pé èéfín tùràrí tó pọ̀ púpọ̀ ló ń gbé e. Ọlọ́run sì ń gbọ́ àdúrà wọn!

Fífi Iná Sọ̀kò sí Ilẹ̀ Ayé

6. Kí ló ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn kẹ́kẹ́ tó pa lọ́run, ìdáhùn kí lèyí sì jẹ́?

6 Jòhánù sọ fún wa pé: “Ṣùgbọ́n lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ áńgẹ́lì náà mú ajere tùràrí náà, ó sì fi díẹ̀ nínú iná pẹpẹ kún inú rẹ̀, ó sì fi í sọ̀kò sí ilẹ̀ ayé. Ààrá àti ohùn àti mànàmáná àti ìsẹ̀lẹ̀ sì sẹ̀.” (Ìṣípayá 8:5) Lẹ́yìn tí kẹ́kẹ́ ti pa, àwọn nǹkan àràmàǹdà bẹ̀rẹ̀ sí í ṣẹlẹ̀ lójijì! Ó hàn gbangba pé ìdáhùn àdúrà àwọn ẹni mímọ́ nìyẹn, torí pé iná tí áńgẹ́lì náà mú látorí pẹpẹ tùràrí ló fà á. Nígbà náà lọ́hùn-ún lọ́dún 1513 ṣááju Sànmánì Kristẹni, lórí Òkè Ńlá Sínáì, ààrá pẹ̀lú mànàmáná, ariwo tó pọ̀, iná, àti ìmìtìtì òkè ńlá náà jẹ́ àmì pé Jèhófà ti yí àfiyèsí rẹ̀ sáwọn èèyàn rẹ̀. (Ẹ́kísódù 19:16-20) Irú àwọn ìran bẹ́ẹ̀, èyí tí Jòhánù ròyìn ẹ̀ yìí, fi hàn pé Jèhófà ti yí àfiyèsí rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lórí ilẹ̀ ayé. Ṣùgbọ́n àmì ni àwọn ohun tí Jòhánù rí. (Ìṣípayá 1:1) Nítorí náà báwo la ṣe lè lóye àwọn nǹkan tí iná, ààrá, ohùn, mànàmáná, àti ìsẹ̀lẹ̀ túmọ̀ sí lónìí?

7. (a) Iná ìṣàpẹẹrẹ wo ni Jésù dá lórí ilẹ̀ ayé lákòókò iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀? (b) Báwo làwọn Kristẹni arákùnrin Jésù ṣe mú kí iná kan ràn níbi tí ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ti gbilẹ̀?

7 Lákòókò kan, Jésù sọ fáwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé: “Èmi wá láti dá iná kan sórí ilẹ̀ ayé.” (Lúùkù 12:49) Lóòótọ́ sì ni, ó dá iná kan. Nípasẹ̀ ìwàásù tí Jésù fi ìtara ṣe, ó sọ Ìjọba Ọlọ́run di ọ̀rọ̀ tó ṣe pàtàkì jù lọ táwọn Júù ní láti gbé yẹ̀ wò, èyí sì tanná ran àríyànjiyàn gbígbóná jákèjádò orílẹ̀-èdè yẹn. (Mátíù 4:17, 25; 10:5-7, 17, 18) Lọ́dún 1919 àwọn Kristẹni arákùnrin Jésù lórí ilẹ̀ ayé, ìyẹn agbo kékeré tàwọn ẹni àmì òróró tí wọ́n ti la àwọn ọjọ́ aládàn-án-wò Ogun Àgbáyé Kìíní já, dá irú iná tó jọ ìyẹn náà níbi tí ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ti gbilẹ̀. Lóṣù September ọdún yẹn, ó hàn gbangba pé ẹ̀mí Jèhófà ń ṣiṣẹ́, báwọn Ẹlẹ́rìí rẹ̀ adúróṣinṣin ṣe pé jọ láti itòsí àti ọ̀nà jíjìn, sí Cedar Point, Ohio, lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà. Joseph F. Rutherford, tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ tú sílẹ̀ lẹ́wọ̀n, tí wọn ò sì ní í pẹ́ sọ pé kò jẹ̀bi àwọn ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn án, fi àìṣojo bá àwọn tó pé jọ náà sọ̀rọ̀ pé: “Gẹ́gẹ́ bí àmì ìgbọràn sí àṣẹ Ọ̀gá wa, tá a sì tún mọ àǹfààní tá a ní àti iṣẹ́ wa, pé a ní láti túdìí àṣírí àwọn ohun tó ti ń kó àwọn èèyàn ṣìnà tipẹ́tipẹ́, iṣẹ́ wa ni láti kéde ìjọba Mèsáyà ológo tó ń bọ̀ wá, bẹ́ẹ̀ ẹnu iṣẹ́ náà la ṣì wà.” Ọ̀ràn pàtàkì tó wà nílẹ̀ nìyẹn, ìyẹn Ìjọba Ọlọ́run!

8, 9. (a) Báwo ni J. F. Rutherford ṣe ṣàlàyé báwọn èèyàn Ọlọ́run ṣe ń ṣe àti ìfẹ́ ọkàn wọn ní gbogbo ọdún tí ìṣòro fi dojú kọ wọ́n? (b) Báwo ló ṣe jẹ́ pé a ju iná sí ilẹ̀ ayé? (d) Báwo ni ààrá, ohùn, mànàmáná, àti ìsẹ̀lẹ̀ ṣe wáyé?

8 Nígbà tí olùbánisọ̀rọ̀ yìí bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ débi àwọn ìnira tó ń kojú èèyàn Ọlọ́run lákòókò yẹn, ó wí pé: “Àwọn ọ̀tá yìí fojú agbo tó jẹ́ ààyò Olúwa rí màbo, débi tó fi ya àwọn tó wà nínú agbo náà lẹ́nu. Wọn ò lè ṣe nǹkan kan, ṣe ló ń ṣe wọ́n ní kàyéfì bí wọ́n ṣe ń gbàdúrà tí wọ́n sì ń fojú sọ́nà sí mímọ ìfẹ́ Olúwa. . . . Àmọ́, láìka ìrẹ̀wẹ̀sì tó bá wọn fúngbà díẹ̀ sí, bí iná ni ìfẹ́ láti wàásù ọ̀rọ̀ Ìjọba náà ṣe ń jó lọ́kàn wọn.”—Wo ìtẹ̀jáde Ilé Ìṣọ́ (Gẹ̀ẹ́sì) ti September 15, 1919, ojú ìwé 280.

9 Lọ́dún 1919, ó ṣeé ṣe fún wọn láti ṣe ìfẹ́ ọkàn wọn. Iná tẹ̀mí ran agbo àwọn Kristẹni tí wọ́n kéré ṣùgbọ́n tí wọ́n jẹ́ akíkanjú yìí, èyí sì mú kí wọ́n máa fi ìtara wàásù káàkiri ayé. (Fi wé 1 Tẹsalóníkà 5:19.) A fi iná sọ̀kò sí ilẹ̀ ayé ní ti pé Ìjọba Ọlọ́run di ọ̀rọ̀ tó ń ràn bí iná, bó sì ṣe ń bá a lọ nìyẹn! Dípò kẹ́kẹ́ tó pa, ohùn alágbára ń dún, ó sì ń gbé ọ̀rọ̀ Ìjọba náà jáde ketekete. Àwọn ọ̀rọ̀ ìkìlọ̀ ń dún gbọnmọgbọnmọ bí ààrá látinú Bíbélì bẹ́ẹ̀ ló ń rọ́ yìì bí ìjì. Àfi bíi mànàmáná tó ń kọ mọ̀nà, Ọ̀rọ̀ alásọtẹ́lẹ̀ Jèhófà ń mú kí òtítọ́ tàn yanran, ṣe làwọn ìsìn lápapọ̀ mì jìgìjìgì dórí ìpìlẹ̀ wọn bíi pé ìsẹ̀lẹ̀ alágbára ńlá ló dé. Ẹgbẹ́ Jòhánù rí i pé iṣẹ́ wà láti ṣe. Títí dòní olónìí, iṣẹ́ náà ń bá a lọ láti gbilẹ̀ tògotògo jákèjádò ilẹ̀ ayé tí a ń gbé!—Róòmù 10:18.

Mímúrasílẹ̀ Láti Fun Kàkàkí

10. Kí làwọn áńgẹ́lì méje náà ṣe tán láti ṣe nísinsìnyí, kí ló sì fà á?

10 Jòhánù tẹ̀ síwájú pé: “Àwọn áńgẹ́lì méje tí wọ́n ní kàkàkí méje lọ́wọ́ sì múra sílẹ̀ láti fun wọ́n.” (Ìṣípayá 8:6) Kí ni fífun àwọn kàkàkí yẹn túmọ̀ sí? Nígbà ayé àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ìró kàkàkí ni wọ́n fi ń sàmì sáwọn ọjọ́ pàtàkì tàbí àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ pàtàkì. (Léfítíkù 23:24; 2 Àwọn Ọba 11:14) Bákan náà, àwọn ìró kàkàkí tí Jòhánù máa tó gbọ́ yóò mú káwọn èèyàn kíyè sí àwọn ọ̀ràn pàtàkì tó lè mú ẹ̀mí lọ́wọ́.

11. Láàárín ọdún 1919 sí 1922 iṣẹ́ ìmúrasílẹ̀ wo ni ẹgbẹ́ Jòhánù dáwọ́ lé lórí ilẹ̀ ayé?

11 Báwọn áńgẹ́lì náà ti ṣe tán láti fun àwọn kàkàkí yẹn, kò sí iyè méjì pé wọ́n tún darí iṣẹ́ ìmúrasílẹ̀ kan lórí ilẹ̀ ayé. Láti ọdún 1919 sí ọdún 1922, ẹgbẹ́ Jòhánù tí wọ́n ti gba agbára kún agbára dáwọ́ lé ṣíṣe àtúntò iṣẹ́ ìwàásù ìta gbangba, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ àwọn ilé tí wọ́n á ti máa tẹ ìwé jáde. Lọ́dún 1919, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í tẹ ìwé ìròyìn náà, The Golden Age, tá a mọ̀ sí Ji! báyìí gẹ́gẹ́ bí “Ìwé Ìròyìn Tó Ń Gbé Ìròyìn Òtítọ́, Ìrètí, àti Ìgbàgbọ́ Tó Dáni Lójú Jáde.” Òun ni irin iṣẹ́ kan tó dà bíi kàkàkí tó máa ṣe bẹbẹ nínú títú àṣírí bí ìsìn èké ṣe ń lọ́wọ́ sí ìṣèlú.

12. Kí ni ìró kàkàkí kọ̀ọ̀kan ń polongo, ó sì rán wa létí ìṣẹ̀lẹ̀ wo nígbà ayé Mósè?

12 Bá a ó ṣe rí i nísinsìnyí, bí ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìró kàkàkí náà ṣe ń dún, ṣe ló ń polongo àgbàyanu ìran nípa báwọn ìyọnu bíbanilẹ́rù ṣe ń dé bá apá kan ilẹ̀ ayé. Díẹ̀ lára ìyọnu wọ̀nyí rán wa létí àwọn ìyọnu tí Jèhófà lò láti fìyà jẹ àwọn ará Íjíbítì nígbà ayé Mósè. (Ẹ́kísódù 7:19–12:32) Wọ́n jẹ́ ìdájọ́ Jèhófà lórí orílẹ̀-èdè yẹn, wọ́n sì jẹ́ káwọn èèyàn Ọlọ́run ráàyè bọ́ lóko ẹrú. Ohun tó jọ èyí làwọn ìyọnu tí Jòhánù rí mú kó ṣeé ṣe. Àmọ́, àwọn ìyọnu yẹn kì í ṣe ìyọnu gidi tó ṣẹlẹ̀. Kàkà bẹ́ẹ̀, àmì tó ń ṣàpẹẹrẹ àwọn ìdájọ́ òdodo Jèhófà ni wọ́n.—Ìṣípayá 1:1.

Ohun Tí “Ìdá Mẹ́ta” Náà Jẹ́

13. Kí ló ṣẹlẹ̀ nígbà táwọn áńgẹ́lì náà fun kàkàkí mẹ́rin àkọ́kọ́, ìbéèrè wo ló sì jẹ yọ látàrí èyí?

13 Gẹ́gẹ́ bá a ṣe máa rí i, nígbà táwọn áńgẹ́lì náà bá fun kàkàkí mẹ́rin àkọ́kọ́, wọ́n á mú ìyọnu wá sórí “ìdá mẹ́ta” ilẹ̀ ayé, òkun, àwọn odò àti àwọn ìsun omi, àti àwọn orísun ìmọ́lẹ̀ ilẹ̀ ayé. (Ìṣípayá 8:7-12) Ìdá mẹ́ta nínú nǹkan kan pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo nǹkan ọ̀hún. (Fi wé Aísáyà 19:24; Ìsíkíẹ́lì 5:2; Sekaráyà 13:8, 9.) “Ìdá mẹ́ta” wo nínú ayé ni ìyọnu yìí tọ́ sí jù lọ? Sátánì àti irú ọmọ rẹ̀ ti fọ́ àwọn tó pọ̀ jù lọ láàárín aráyé lójú ó sì ti sọ wọ́n dìbàjẹ́. (Jẹ́nẹ́sísì 3:15; 2 Kọ́ríńtì 4:4) Ọ̀ràn náà rí bí Dáfídì ti ṣàpèjúwe rẹ̀, pé: “Gbogbo wọn ti yapa, gbogbo wọn pátá jẹ́ ẹni ìbàjẹ́; kò sí ẹni tí ń ṣe rere, kò tilẹ̀ sí ẹyọ kan.” (Sáàmù 14:3) Bẹ́ẹ̀ ni, ewu ìdájọ́ mímúná rọ̀ dẹ̀dẹ̀ sórí gbogbo aráyé. Ṣùgbọ́n apá kan nínú ayé jẹ̀bi ní pàtàkì. Ì bá mà dáa o ká ní apá kan, ìyẹn “ìdá mẹ́ta” náà mọ̀ pé bọ́rọ̀ ṣe máa rí nìyẹn! Kí ni “ìdá mẹ́ta” yẹn?

14. Kí ni ìdá mẹ́ta táwọn ọ̀rọ̀ alágbára, tí ń kó ìyọnu báni látọ̀dọ̀ Jèhófà ń já bọ́ lé lórí dúró fún?

14 Àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ni! Láàárín ọdún 1920 sí ọdún 1929, nǹkan bí ìdá mẹ́ta aráyé ló wà nínú ìsìn èké. Àwọn apẹ̀yìndà láti inú ìsìn Kristẹni tòótọ́ ló dá a sílẹ̀, Jésù àti àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìpẹ̀yìndà ńlá yẹn. (Mátíù 13:24-30; Ìṣe 20:29, 30; 2 Tẹsalóníkà 2:3; 2 Pétérù 2:1-3) Ẹgbẹ́ àlùfáà àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì sọ pé àwọn wà nínú tẹ́ńpìlì Ọlọ́run, wọ́n sì ti sọ pé olùkọ́ni ní ẹ̀kọ́ ìsìn Kristẹni làwọn. Ṣùgbọ́n ẹ̀kọ́ wọn jìnnà pátápátá sí òtítọ́ Bíbélì, nígbà gbogbo ni wọ́n sì ń tàbùkù sí orúkọ Ọlọ́run. Àwọn ọ̀rọ̀ alágbára, tí ń kó ìyọnu báni á máa ti ọ̀dọ̀ Jèhófà bọ́ sórí àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì tó dúró fún ìdá mẹ́ta náà. Ìdá mẹ́ta yẹn láàárín aráyé kò yẹ fún ojú rere Ọlọ́run páàpáà!

15. (a) Ǹjẹ́ fífun ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn kàkàkí náà mọ sí àárín ọdún kan pàtó? Ṣàlàyé. (b) Ohùn àwọn wo ló ti dà pọ̀ mọ́ ti ẹgbẹ́ Jòhánù ní pípòkìkí àwọn ìdájọ́ Jèhófà?

15 Báwọn ìró kàkàkí yìí ṣe ń dún tẹ̀ léra, àwọn ìpinnu pàtàkì pàtàkì làwọn ìránṣẹ́ Jèhófà ń gbé jáde láwọn àpéjọ àgbègbè tó wáyé láàárín ọdún 1922 sí ọdún 1928. Ṣùgbọ́n fífun àwọn kàkàkí náà ò mọ sórí àwọn ọdún yẹn. Wọ́n ṣì ń bá a lọ láìsọsẹ̀ láti máa túdìí àṣírí iṣẹ́ láabi àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì, kódà wọ́n ṣì wà lẹ́nu títú àṣírí ọ̀hún bí ọjọ́ Olúwa ti ń tẹ̀ síwájú. A gbọ́dọ̀ kéde ìdájọ́ Jèhófà káàkiri ayé, fún gbogbo orílẹ̀-èdè, láìka ìkórìíra àti inúnibíni tó wà jákèjádò ayé sí. Ó dìgbà tá a bá tó ṣèyẹn kí òpin ètò Sátánì tó dé. (Máàkù 13:10, 13) Inú wa ń dùn pé ogunlọ́gọ̀ ńlá náà nísinsìnyí ti fi ohùn tiwọn kún ti ẹgbẹ́ Jòhánù láti máa jẹ́ kí ìkéde tó ṣe pàtàkì fún gbogbo àgbáyé náà máa dún bí ààrá.

Ìdá Mẹ́ta Ilẹ̀ Ayé Jóná

16. Kí ló ṣẹlẹ̀ nígbà tí áńgẹ́lì kìíní fun kàkàkí ẹ̀?

16 Nígbà tí Jòhánù tún dẹ́nu lé ìròyìn nípa àwọn áńgẹ́lì náà, ó kọ̀wé pé: “Èyí èkíní sì fun kàkàkí rẹ̀. Yìnyín àti iná tí ó dà pọ̀ mọ́ ẹ̀jẹ̀ sì ṣẹlẹ̀, a sì fi í sọ̀kò sí ilẹ̀ ayé; ìdá mẹ́ta ilẹ̀ ayé sì jóná, ìdá mẹ́ta àwọn igi sì jóná, gbogbo ewéko tútù sì jóná.” (Ìṣípayá 8:7) Eléyìí jọ ìyọnu keje tó wá sórí Íjíbítì, ṣùgbọ́n kí ló túmọ̀ sí lákòókò tiwa yìí?—Ẹ́kísódù 9:24.

17. (a) Kí ni ọ̀rọ̀ náà “ilẹ̀ ayé” tó wà nínú Ìṣípayá 8:7 dúró fún? (b) Báwo ni ìdá mẹ́ta ilẹ̀ ayé tí ó jẹ́ ti ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ṣe jóná?

17 Lọ́pọ̀ ìgbà nínú Bíbélì, ọ̀rọ̀ náà “ilẹ̀ ayé” máa ń tọ́ka sí aráyé. (Jẹ́nẹ́sísì 11:1; Sáàmù 96:1) Níwọ̀n bí ìyọnu kejì ti wá sórí òkun, tí òkun náà sì ní í ṣe pẹ̀lú aráyé, “ilẹ̀ ayé” ní láti tọ́ka sí àgbájọ àwọn èèyàn tí Sátánì gbé kalẹ̀ tó dà bí èyí tó fẹsẹ̀ múlẹ̀, tó sì yẹ fún ìparun. (2 Pétérù 3:7; Ìṣípayá 21:1) Ìran ìyọnu náà fi hàn pé ìdá mẹ́ta ilẹ̀ ayé tó jẹ́ ti ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ni ooru ìbínú Jèhófà tó ń bù yìì jó gbẹ. Àwọn jàǹkàn jàǹkàn tó wà nínú àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì, tí wọ́n dúró bí igi láàárín rẹ̀, ni ìpolongo ìdájọ́ mímúná Jèhófà dáná sun. Bí ẹgbàágbèje àwọn ọmọ ṣọ́ọ̀ṣì wọ̀nyí bá ń bá a lọ láti máa dúró sínú àwọn ìsìn wọn, lójú Ọlọ́run, wọ́n ti rọ dà nù bí ewé koríko tí ooru jó gbẹ.—Fi wé Sáàmù 37:1, 2. a

18. Báwo làwọn ìránṣẹ́ Jèhófà ṣe pòkìkí ìhìn ìdájọ́ Jèhófà ní ìpàdé tó wáyé ní Cedar Point lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà lọ́dún 1922?

18 Báwo ni wọ́n ṣe ń kéde ìdájọ́ yìí? Wọn kì í sábàá lo àwọn ilé iṣẹ́ ìròyìn ayé, tí wọ́n jẹ́ apá kan ayé, tí wọ́n sì sábà máa ń kẹ́gàn “ẹrú” Ọlọ́run. (Mátíù 24:45) Wọ́n pòkìkí rẹ̀ lọ́nà tó gba àfiyèsí ní ìpàdé mánigbàgbé ẹlẹ́ẹ̀kejì táwọn èèyàn Ọlọ́run ṣe ní Cedar Point, Ohio, lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà ní September 10, ọdún 1922. Pẹ̀lú ìfohùnṣọ̀kan àti ìtara, wọ́n tẹ́wọ́ gba ìpinnu kan tí àkòrí rẹ̀ jẹ́: “Ìpèníjà Fáwọn Aṣáájú Ayé.” Láìfọ̀rọ̀ bọpo bọyọ̀, ó fún ilẹ̀ ayé ìṣàpẹẹrẹ ti òde òní ní ìkìlọ̀ àwítẹ́lẹ̀ yìí pé: “Nítorí náà a ké sí àwọn orílẹ̀-èdè tó wà láyé, àwọn alákòóso wọn pẹ̀lú àwọn aṣáájú wọn, a sì ké sí gbogbo ẹgbẹ́ àlùfáà gbogbo àwọn ṣọ́ọ̀ṣì ilẹ̀ ayé ní ẹlẹ́kajẹ̀ka, àwọn ọmọlẹ́yìn wọn àtàwọn alájọṣepọ̀ wọn, tó fi mọ́ àwọn oníṣòwò aládàá ńlá àtàwọn èèkàn nínú òṣèlú, pé kí wọ́n mú ẹ̀rí wá láti sọ ìdí tí wọ́n fi sọ pé àwọn lè mú kí àlàáfíà àti aásìkí rídìí jókòó àti pé àwọn lè mú ayọ̀ wá fáwọn èèyàn; tí wọn ò bá sì lè mú ẹ̀rí wá, a ké sí wọn láti dẹtí wọn sílẹ̀ sí ẹ̀rí tí àwa ń jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́rìí fún Olúwa, kí wọ́n sì wá sọ bóyá ẹ̀rí wa jẹ́ òótọ́ tàbí èké.”

19. Ọ̀rọ̀ ẹ̀rí wo ni àwọn èèyàn Ọlọ́run gbé jáde fáwọn oníṣọ́ọ̀ṣì nípa Ìjọba Ọlọ́run?

19 Ọ̀rọ̀ ẹ̀rí wo ni àwọn Kristẹni wọ̀nyí gbé jáde? Òun rèé: “Àwa gbà gbọ́ a sì polongo pé ìjọba Mèsáyà ni yóò fòpin sí gbogbo ìpọ́njú ìran èèyàn, tí yóò mú àlàáfíà wá sórí ilẹ̀ ayé tí yóò sì fi inú rere bá àwọn èèyàn lò, ohun tí gbogbo orílẹ̀-èdè ń fẹ́ nìyí; a polongo pé àwọn tí wọ́n jọ̀wọ́ ara wọn tinútinú fún ìjọba òdodo rẹ̀ tó ti bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso nísinsìnyí yóò rí àlàáfíà, ìyè, ìtúsílẹ̀ tí yóò wà títí láé àti ayọ̀ aláìlópin gbà gẹ́gẹ́ bí ìbùkún.” Láwọn àkókò ìdíbàjẹ́ wọ̀nyí, nígbà tíjọba táwọn èèyàn gbé kalẹ̀, pàápàá jù lọ àwọn tó wà ní àwọn ibi tí ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ti gbilẹ̀, ń kùnà láti yanjú àwọn ìṣòro ayé tí ẹ̀tẹ́ sì ń bá wọn, ṣe ni ìpèníjà náà ń dún bíi kàkàkí, tí ohùn rẹ̀ sì ròkè ju ti ọdún 1922. Ẹ wo bó ti jẹ́ òótọ́ tó pé Ìjọba Ọlọ́run níkàáwọ́ Kristi aṣẹ́gun rẹ̀ ni ìrètí kan ṣoṣo tó wà fún aráyé!

20. (a) Kí làwọn Kristẹni ẹni àmì òróró lò láti mú àwọn ìhìn ìdájọ́ dún jáde bíi kàkàkí lọ́dún 1922 àti lẹ́yìn náà? (b) Kí ló ṣẹlẹ̀ sí ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì nígbà tí ìró kàkàkí kìíní dún?

20 Nípasẹ̀ àwọn ìpinnu, àwọn àṣàrò kúkúrú, àwọn ìwé pẹlẹbẹ, àwọn ìwé ńlá, àwọn ìwé ìròyìn, àtàwọn àwíyé, ìjọ àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró gbé ìkéde yìí àtàwọn mìíràn lẹ́yìn náà jáde bíi pé nípasẹ̀ kàkàkí ni. Nígbà tí kàkàkí kìíní dún, ṣe ló dà bíi pé ohun tó jọ yìnyín tí ń ya luni ya lu àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì. Àṣírí bí wọ́n ṣe jẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ tú borokoto. Nítorí bí wọ́n sì ṣe nípìn-ín nínú àwọn ogun tó jà ní ọ̀rúndún ogún, ó ti wá hàn pé wọ́n yẹ fún ìbínú amú-bí-iná ti Jèhófà. Ẹgbẹ́ Jòhánù, tí ogunlọ́gọ̀ ńlá wá ń ṣètìlẹ́yìn fún lẹ́yìn náà, ti ń bá a lọ láti mú kí ìró kàkàkí kìíní yìí máa dún gbọnmọ gbọnmọ, èyí sì ń jẹ́ ká rí ojú tí Jèhófà fi ń wo ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì, ó kà á sí ohun tó yẹ fún ìparun.—Ìṣípayá 7:9, 15.

Bí Òkè Ńlá Kan Tí Ń Jó

21. Kí ló ṣẹlẹ̀ nígbà tí áńgẹ́lì kejì fun kàkàkí rẹ̀?

21 “Áńgẹ́lì kejì sì fun kàkàkí rẹ̀. Ohun kan bí òkè ńlá títóbi tí iná ń jó ni a sì fi sọ̀kò sínú òkun. Ìdá mẹ́ta òkun sì di ẹ̀jẹ̀; ìdá mẹ́ta àwọn ẹ̀dá tí ń bẹ nínú òkun tí wọ́n ní ọkàn sì kú, ìdá mẹ́ta àwọn ọkọ̀ ojú omi sì fọ́ bàjẹ́.” (Ìṣípayá 8:8, 9) Kí ni ìran ẹlẹ́rùjẹ̀jẹ̀ yìí ṣàpẹẹrẹ?

22, 23. (a) Ìpinnu wo ló dájú pé ó jáde nígbà tí kàkàkí kejì dún? (b) Kí ni “ìdá mẹ́ta òkun” dúró fún?

22 A lè lóye ìṣẹ̀lẹ̀ yìí dáadáa bá a bá fi wé ohun tó wáyé ní àpéjọ àgbègbè àwọn èèyàn Jèhófà tí wọ́n ṣe ní nílùú Los Angeles, ìpínlẹ̀ California, lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà, ní August 18 sí 26, ọdún 1923. Àkòrí àkànṣe àsọyé ọ̀sán Saturday, látẹnu J. F. Rutherford, ni “Àwọn Àgùntàn àti Ewúrẹ́.” Àsọyé náà fi hàn kedere pé “àwọn àgùntàn” ni àwọn tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ òdodo tí wọn yóò jogún ilẹ̀ ayé nínú Ìjọba Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà làwọn tó wà ní àpéjọ náà wá tẹ́wọ́ gba ìpinnu kan tó jẹ́ ká rí àgàbàgebè “ẹgbẹ́ àlùfáà apẹ̀yìndà àti ‘mọ́gàjí nínú agbo wọn,’ ìyẹn àwọn ẹni ayé tí wọ́n lówó lọ́wọ́ tí wọ́n sì tún lẹ́nu nínú ọ̀rọ̀ ìṣèlú.” Ó ké sí “ògìdìgbó àwọn èèyàn olùfẹ́ àlàáfíà àti ètò, tí wọ́n wà nínú àwọn ṣọ́ọ̀ṣì ní ẹlẹ́kajẹ̀ka . . . pé kí wọ́n dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ètò aláìṣòdodo ti ẹgbẹ́ àlùfáà tí Olúwa pè ní ‘Bábílónì’” kí wọ́n sì múra sílẹ̀ “láti gba àwọn ìbùkún ìjọba Ọlọ́run.”

23 Láìsí àní-àní, kàkàkí kejì tó dún ló mú ìpinnu yìí wá. Àwọn tó máa ṣègbọràn sí ìkéde náà tó bá yá máa ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò láàárín àwọn tí Aísáyà sọ ọ̀rọ̀ wọn báyìí pé: “Ṣùgbọ́n àwọn ẹni burúkú dà bí òkun tí a ń bì síwá bì sẹ́yìn, nígbà tí kò lè rọ̀ wọ̀ọ̀, èyí tí omi rẹ̀ ń sọ èpò òkun àti ẹrẹ̀ sókè.” (Aísáyà 57:20; 17:12, 13) A ti rí i báyìí pé “òkun” ṣàpẹẹrẹ ìran èèyàn oníwọ́nranwọ̀nran, aláraàbalẹ̀, ọlọ̀tẹ̀, tí wọ́n ń rúná sí rògbòdìyàn àti ìyípadà oníjàgídíjàgan. (Fi wé Ìṣípayá 13:1.) Àkókò náà ń bọ̀ tí “òkun” yẹn kì yóò sí mọ́. (Ìṣípayá 21:1) Ṣùgbọ́n ní báyìí ná, Jèhófà fi ìró kàkàkí yẹn kéde ìdájọ́ lòdì sí ìdá mẹ́ta rẹ̀, èyí tí ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì jẹ́ ara rẹ̀.

24. Kí ni nǹkan ràbàtà bí òkè ńlá tó ń jó tá a fi sọ̀kò sínú òkun ṣàpẹẹrẹ?

24 A ju ohun ràbàtà títóbi bí òkè ńlá kan tí iná ń jó sínú “òkun.” Nínú Bíbélì, àwọn òkè ńlá sábà máa ń ṣàpẹẹrẹ àwọn ìjọba. Bí àpẹẹrẹ, Bíbélì fi Ìjọba Ọlọ́run wé òkè ńlá kan. (Dáníẹ́lì 2:35, 44) Bábílónì apanirun di “òkè ńlá jíjóná ráúráú.” (Jeremáyà 51:25) Ṣùgbọ́n ohun ràbàtà bí òkè ńlá tí Jòhánù rí yìí ṣì ń jó síbẹ̀. Jíjù tí wọ́n jù ú sínú òkun ṣàpẹẹrẹ bí ìṣòro àtiyan irú ìjọba tó tọ́ ṣe di àríyànjiyàn tó ń jà ràn-ìn láàárín aráyé ní ìgbà Ogun Àgbáyé Kìíní àti lẹ́yìn náà, pàápàá jù lọ láwọn ilẹ̀ tí ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ti gbilẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, lórílẹ̀-èdè Ítálì, Mussolini dá ètò ìjọba Aláṣẹ Oníkùmọ̀ sílẹ̀. Àwọn ará ilẹ̀ Jámánì fọwọ́ sí ètò ìjọba Násì ti Hitler, àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn sì ń gbìyànjú oríṣiríṣi ètò ìjọba àjùmọ̀ní. Ìyípadà tegbò-tigaga wáyé lórílẹ̀-èdè Rọ́ṣíà, níbi tí àtúntò táwọn Bolshevik ṣe ti mú kí wọ́n gbé ìjọba Kọ́múníìsì àkọ́kọ́ kalẹ̀, èyí sì wá mú kó di pé agbára bọ́ lọ́wọ́ àwọn aṣáájú ìsìn tí wọn ò sì lẹ́nu mọ́ láwọn ibi tó ti fi ìgbà kan rí jẹ́ ibi odi agbára wọn.

25. Báwo ni àríyànjiyàn lórí irú ètò ìjọba tó tọ́ ṣe ń bá a lọ láti dá wàhálà sílẹ̀ lẹ́yìn Ogun Àgbáyé Kejì?

25 Ogun Àgbáyé Kejì fòpin sí ètò ìjọba Aláṣẹ Oníkùmọ̀ àti ìjọba Násì, síbẹ̀ àwọn èèyàn ṣì ń ba ara wọn jiyàn lórí irú ìjọba tó tọ́. Látàrí èyí, ìdàrúdàpọ̀ ṣì ń bá a lọ láàárín aráyé, ìyẹn sì ń mú kí wọ́n gbé oríṣiríṣi ìjọba tó máa ṣàtúntò tipátipá kalẹ̀. Fún ọ̀pọ̀ ọdún lẹ́yìn ọdún 1945, ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè ló ti ṣètò ìjọba oníjàgídíjàgan, lára wọn ni Ṣáínà, Vietnam, Cuba, àti Nicaragua. Wọ́n dán ìjọba ológun abàṣẹwàá wò lórílẹ̀-èdè Gíríìsì, ṣùgbọ́n ó kùnà. Nígbà tí wọ́n gbìyànjú irú ètò ìjọba Kọ́múníìsì kan lórílẹ̀-èdè Kampuchea (ìyẹn Cambodia), ó ju ọgọ́rùn-ún ọ̀kẹ́ èèyàn lọ tó kú látàrí wàhálà tó tẹ̀yìn ẹ̀ wá.

26. Báwo ni “òkè ńlá títóbi tí iná ń jó” ṣe ń bá a lọ láti máa mú kí ìgbì ru nínú òkun aráyé?

26 “Òkè ńlá títóbi tí iná ń jó” yẹn ń bá a lọ láti mú kí ìgbì máa rú nínú òkun aráyé. Ìròyìn fi hàn pé rògbòdìyàn wà lórí irú ìjọba tí wọ́n fẹ́ ní ilẹ̀ Áfíríkà, ilẹ̀ Amẹ́ríkà, ilẹ̀ Éṣíà, àti láwọn erékùṣù òkun Pàsífíìkì. Àwọn ilẹ̀ tí ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ti gbilẹ̀ tàbí níbi táwọn míṣọ́nárì wọn ti di ajàfẹ́tọ̀ọ́ lọ̀pọ̀ rògbòdìyàn yìí ti ṣẹlẹ̀. Kódà, àwọn àlùfáà Ṣọ́ọ̀ṣì Kátólíìkì dara pọ̀ mọ́ àwọn ẹgbẹ́ ọmọ ogun ajàjàgbara ti Kọ́múníìsì tí wọ́n sì jọ ń ja ìjà ọ̀hún. Lákòókò tá à ń sọ yìí, àwọn ajíhìnrere àwọn ṣọ́ọ̀ṣì tó yàtọ̀ sí Kátólíìkì ti ṣakitiyan ní Amẹ́ríkà Àárín láti kojú àwọn Kọ́múníìsì tí wọ́n “forí ṣe fọrùn ṣe láti wá agbára rí ní gbogbo ọ̀nà.” Ṣùgbọ́n kò sí ọ̀kan nínú àwọn ohun tó ń mi òkun aráyé jìgìjìgì yìí tó tíì mú kí ayé wà lálàáfíà àti àìséwu.—Fi wé Aísáyà 25:10-12; 1 Tẹsalóníkà 5:3.

27. (a) Báwo ni “ìdá mẹ́ta òkun” ṣe dà bí ẹ̀jẹ̀? (b) Báwo ni ‘ìdá mẹ́ta àwọn ẹ̀dá nínú òkun’ ṣe kú, báwo ni ó sì ṣe rí fún “ìdá mẹ́ta àwọn ọkọ̀”?

27 Ìrò kàkàkí kejì tó dún fi hàn pé ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wà lọ́rùn àwọn ọmọ aráyé, tí wọ́n lọ́wọ́ nínú rògbòdìyàn àti ìdàrúdàpọ̀ torí àtigbé ìjọba tó máa tẹ́ aráyé lọ́rùn kalẹ̀, dípò kí wọ́n juwọ́ sílẹ̀ fún Ìjọba Ọlọ́run. “Ìdá mẹ́ta òkun,” ní pàtàkì jù lọ, àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ti dà bí ẹ̀jẹ̀. Gbogbo àwọn ohun alààyè inú ẹ̀ ti kú lójú Ọlọ́run. Kò sí èyíkéyìí nínú àwọn àjọ tó wà nídìí àwọn àtúntò yẹn, tí wọ́n lé téńté bí ọkọ̀ sójú ìdá mẹ́ta agbami òkun yẹn, tí ò ní rì nígbẹ̀yìngbẹ́yín. Inú wa mà dùn o, pé ọ̀kẹ́ àìmọye àwọn èèyàn ẹni bí àgùntàn ń ṣègbọràn báyìí sí ìkìlọ̀ náà tó ń dún bí ìró kàkàkí. Ìró kàkàkí náà ń rọ̀ wọ́n pé kí wọ́n jáde kúrò láàárín àwọn tí wọ́n ṣì ń ri ara wọn bọ inú ìfẹ́ orílẹ̀-èdè ẹni tí wọ́n sì lẹ́jẹ̀ lọ́rùn nínú òkun yẹn!

Ìràwọ̀ Kan Jábọ́ Láti Ọ̀run

28. Kí ló ṣẹlẹ̀ nígbà tí áńgẹ́lì kẹta fun kàkàkí tirẹ̀?

28 “Áńgẹ́lì kẹta sì fun kàkàkí rẹ̀. Ìràwọ̀ ńlá tí ń jó bí fìtílà sì jábọ́ láti ọ̀run, ó sì jábọ́ sórí ìdá mẹ́ta àwọn odò àti sórí àwọn ìsun omi. A sì ń pe orúkọ ìràwọ̀ náà ní Iwọ. Ìdá mẹ́ta àwọn omi sì di iwọ, ọ̀pọ̀ nínú àwọn ènìyàn sì kú láti ọwọ́ àwọn omi náà, nítorí a ti sọ ìwọ̀nyí di kíkorò.” (Ìṣípayá 8:10, 11) Lẹ́ẹ̀kan sí i, àwọn apá mìíràn nínú Bíbélì ràn wá lọ́wọ́ láti rí bí ẹsẹ Ìwé Mímọ́ yìí ṣe kan ọjọ́ Olúwa.

29. Kí ni àpẹẹrẹ “ìràwọ̀ ńlá tí ń jó bí fìtílà” dúró fún, kí sì nìdí?

29 Ṣáájú, nínú àwọn iṣẹ́ tí Jésù rán sáwọn ìjọ méje, a kà nípa bí ìràwọ̀ ṣe jẹ́ àpẹẹrẹ, a rí i pé àwọn ìràwọ̀ méje náà ṣàpẹẹrẹ àwọn alàgbà nínú àwọn ìjọ. b (Ìṣípayá 1:20) Tá a bá fojú tẹ̀mí wò ó lọ́nà àpẹẹrẹ, “àwọn ìràwọ̀” tí wọ́n jẹ́ ẹni àmì òróró pa pọ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn ẹni àmì òróró yòókù, ti bẹ̀rẹ̀ sí í gbé lọ́run látìgbà tá a ti fi èdìdì dì wọ́n pẹ̀lú ẹ̀mí mímọ́ gẹ́gẹ́ bí àmì ogún wọn tọ̀run. (Éfésù 2:6, 7) Síbẹ̀, àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kìlọ̀ pé àwọn kan látinú irú àwọn ẹni bí ìràwọ̀ bẹ́ẹ̀ máa di apẹ̀yìndà, olùdá-ìyapa-sílẹ̀, wọn sì máa ṣi agbo lọ́nà. (Ìṣe 20:29, 30) Irú àìṣòtítọ́ bẹ́ẹ̀ yóò yọrí sí ìpẹ̀yìndà ńlá, àwọn alàgbà tí wọ́n ṣubú wọ̀nyẹn á sì wá para pọ̀ di ọkùnrin àìlófin kan tó máa gbé ara rẹ̀ ga débi táá fi sọ ara ẹ̀ di ọlọ́run láàárín aráyé. (2 Tẹsalóníkà 2:3, 4) Àwọn ohun tí Pọ́ọ̀lù kìlọ̀ nípa rẹ̀ yìí ní ìmúṣẹ nígbà táwọn àlùfáà ṣọ́ọ̀ṣì bẹ̀rẹ̀ sí í lọ́wọ́ sọ́ràn aráyé. Àbí ẹ ò rí i pé ó bá a mu gẹ́ẹ́, pé àwọn wọ̀nyí ni àpẹẹrẹ “ìràwọ̀ ńlá tí ń jó bí fìtílà” dúró fún.

30. (a) Nígbà tí Aísáyà sọ pé ọba Bábílónì á ṣubú látọ̀run, kí ló ní lọ́kàn? (b) Kí ni ìṣubú láti ọ̀run lè tọ́ka sí?

30 Ìràwọ̀ yìí gan-an ni Jòhánù rí tó já bọ́ látọ̀run. Lọ́nà wo? Ohun tó ṣẹlẹ̀ sí ọba ìgbà àtijọ́ kan á ràn wá lọ́wọ́ láti lóye rẹ̀. Nígbà tí wòlíì Aísáyà ń bá ọba Bábílónì sọ̀rọ̀, ó wí pé: “Wo bí o ti já bọ́ láti ọ̀run, ìwọ ẹni tí ń tàn, ọmọ ọ̀yẹ̀! Wo bí a ti ké ọ lulẹ̀, ìwọ tí ń sọ àwọn orílẹ̀-èdè di aláìlágbára!” (Aísáyà 14:12) Àsọtẹ́lẹ̀ yìí nímùúṣẹ nígbà tí ẹgbẹ́ ọmọ ogun Kírúsì bi Bábílónì ṣubú, tí ọba rẹ̀ sì ré bọ́ lójijì pẹ̀lú ìtìjú látorí ipò tó wà gẹ́gẹ́ bí alákòóso ayé. A lè rí i báyìí pé ìṣubú látọ̀run lè tọ́ka sí ìgbà tí ipò gíga kan bá bọ́ lọ́wọ́ èèyàn tónítọ̀hún sì dẹni ìtìjú tó tẹ́ pátápátá.

31. (a) Nígbà wo ni àwùjọ àlùfáà àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ṣubú láti ipò ti “ọ̀run?” (b) Báwo ni omi táwọn àlùfáà gbé kalẹ̀ ṣe yí padà di “iwọ,” kí nìyẹn sì fà fún ọ̀pọ̀lọpọ̀?

31 Nígbà tí ẹgbẹ́ àlùfáà àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì pẹ̀yìn dà kúrò nínú ìsìn Kristẹni tòótọ́, wọ́n ṣubú láti ipò gíga fíofío ti “ọ̀run” tí Pọ́ọ̀lù ṣàpèjúwe nínú Éfésù 2:6, 7. Kàkà kí wọ́n fáwọn èèyàn ní omi òtítọ́ títunilára mu, wọ́n gbé “iwọ” kalẹ̀, ìyẹn àwọn irọ́ kíkorò bí ẹ̀kọ́ ọ̀run àpáàdì, pọ́gátórì, Mẹ́talọ́kan, àti àyànmọ́; bákan náà, wọ́n ti kó àwọn orílẹ̀-èdè lọ sógun, nípa kíkùnà láti mú kí wọ́n di ìránṣẹ́ Ọlọ́run tó níwà ọmọlúwàbí. Kí ló tẹ̀yìn ẹ̀ wá? Wọ́n ń fún àwọn tó gba ẹ̀kọ́ èké wọn gbọ́ ní májèlé tẹ̀mí jẹ. Ọ̀ràn wọn jọ tàwọn ọmọ Ísírẹ́lì aláìṣòótọ́ nígbà ayé Jeremáyà, àwọn ẹni tí Jèhófà wí fún pé: “Kíyè sí i, èmi yóò mú, èyíinì ni, àwọn èèyàn yìí, jẹ iwọ, dájúdájú, èmi yóò sì mú wọn mu omi onímájèlé. Nítorí láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì Jerúsálẹ́mù ni ìpẹ̀yìndà ti jáde lọ sí gbogbo ilẹ̀.”—Jeremáyà 9:15; 23:15.

32. Nígbà wo ni ìṣubú àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì kúrò ní ọ̀run tẹ̀mí hàn kedere, kí ló sì fi í hàn?

32 Ọdún 1919 ló hàn gbangba pé àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ti ṣubú látọ̀run tẹ̀mí nígbà tí Jésù yan ìwọ̀nba kéréje ìyókù àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró sórí gbogbo ohun tó jẹ́ mọ́ ọ̀ràn Ìjọba náà, dípò ẹgbẹ́ àlùfáà àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì. (Mátíù 24:45-47) Àwọn Kristẹni yìí sì fi ìṣubú àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì hàn kedere láti 1922 nígbà tí wọ́n ń polongo lákọ̀tun nípa títú àṣírí ibi táwọn àlùfáà àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ti kùnà láìfi ọ̀rọ̀ sábẹ́ ahọ́n sọ.

33. Báwo làwọn akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ṣe tú àwùjọ àlùfáà àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì fó ní àpéjọ àgbègbè ọdún 1924 tí wọ́n ṣe nílùú Columbus, ní ìpínlẹ̀ Ohio, lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà?

33 Èyí tó ta yọ nínú pípòkìkí ìṣubú yìí ni ìpolongo táwọn akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ṣe ní àpéjọ kan tí ìwé ìròyìn The Golden Age pè ní “àpéjọ àgbègbè gíga jù lọ táwọn Akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì tíì ṣe rí.” Ìlú Columbus ní ìpínlẹ̀ Ohio, lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà ni wọ́n ti ṣe àpéjọ yìí ní July 20 sí 27, ọdún 1924. Kò síyè méjì pé áńgẹ́lì tó fun kàkàkí kẹta ń darí wọn, torí wọ́n fọwọ́ sí ìpinnu lílágbára kan níbẹ̀ wọ́n sì pín àádọ́ta mílíọ̀nù ẹ̀dà ìpinnu náà kiri nígbà tí wọ́n sọ ọ́ di ìwé àṣàrò kúkúrú. Wọ́n tẹ̀ ẹ́ jáde wọ́n sì pe àkọlé rẹ̀ ní Ecclesiastics Indicted (Ẹ̀sùn Tó Wà Lọ́rùn Ẹgbẹ́ Àwọn Àlùfáà). Ìsọ̀rí ọ̀rọ̀ kan gbé àríyànjiyàn náà kalẹ̀, ó sọ pé: “Irú-Ọmọ Ìlérí Ní Ìdojúùjà Kọ Irú-Ọmọ Ejò.” Ẹ̀sùn náà tú ẹgbẹ́ àlùfáà àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì fó ní gbogbo ọ̀nà, irú bí wọ́n ṣe ń fi ara wọn jẹ oyè ìsìn kàǹkà-kàǹkà, bí wọ́n ṣe ń fàwọn oníṣòwò tó rọ́wọ́ mú àtàwọn ògbóǹtarìgì olóṣèlú ṣe àwọn ògúnná gbòǹgbò nínú agbo wọn, bí wọ́n ṣe ń fẹ́ láti máa fẹlá níwájú àwọn èèyàn, àti kíkọ̀ tí wọ́n kọ̀ láti wàásù ìhìn rere Ìjọba Mèsáyà fáwọn èèyàn. Ó tẹnu mọ́ ọn pé olúkúlùkù Kristẹni olùṣèyàsímímọ́ ni Ọlọ́run fún níṣẹ́ láti máa pòkìkí “ọjọ́ ẹ̀san níhà ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wa; láti tu gbogbo àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú.”—Aísáyà 61:2.

34, 35. (a) Látìgbà tí áńgẹ́lì kẹta ti bẹ̀rẹ̀ sí í fun kàkàkí rẹ̀, kí ló ṣẹlẹ̀ sí àṣẹ àti agbára àwùjọ àwọn àlùfáà? (b) Kí ló máa ṣẹlẹ̀ sí àwùjọ àlùfáà àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì lọ́jọ́ iwájú?

34 Láti ìgbà tí áńgẹ́lì kẹta ti bẹ̀rẹ̀ sí í fun kàkàkí rẹ̀ lagbára ti ń bọ́ lọ́wọ́ àwọn àlùfáà, wọn ò sì lè fi bẹ́ẹ̀ jẹ gàba láàárín aráyé mọ́. Ó burú fún wọn débi pé, lóde òní yìí, ìwọ̀nba kéréje nínú wọn ló ṣì ń rí agbára tí wọ́n fi sọ ara wọn di ọlọ́run lò, bẹ́ẹ̀ sì rèé wọ́n nírú agbára bẹ́ẹ̀ láwọn ọ̀rúndún tó kọjá. Nítorí ìwàásù àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà, ọ̀pọ̀ èèyàn ló ti wá mọ̀ pé májèlé tẹ̀mí, tàbí “iwọ” ni ọ̀pọ̀ ẹ̀kọ́ táwọn ẹgbẹ́ àlùfáà fi ń kọ́ni. Síwájú sí i, láwọn orílẹ̀-èdè tó wà ní àríwá ilẹ̀ Yúróòpù, agbára ti fẹ́rẹ̀ẹ́ tán lọ́wọ́ àwọn àlùfáà, nígbà tó jẹ́ pé ní àwọn ilẹ̀ kan ìjọba ká wọn lọ́wọ́ kò gan-an. Láwọn apá ibi tí ẹ̀sìn Kátólíìkì pọ̀ sí nílẹ̀ Yúróòpù àti nílẹ̀ Amẹ́ríkà, orúkọ ẹgbẹ́ àwọn àlùfáà ti bà jẹ́ nítorí mọ́namọ̀na tí wọ́n ń ṣe nínú ọ̀ràn owó, ìṣèlú, àti nítorí ìwà pálapàla wọn. Láti ìsinsìnyí lọ, ṣe ni wọ́n á kàn máa tẹ́ sí i torí pé àgbákò tó máa bá gbogbo àwọn onísìn èké yòókù láìpẹ́ máa kan àwọn náà.—Ìṣípayá 18:21; 19:2.

35 Ìyọnu tí Jèhófà ń mú wá sórí àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì kò tíì tán o. Ìwọ wo ohun tó ṣẹlẹ̀ nígbà tí kàkàkí kẹrin dún.

Òkùnkùn!

36. Kí ló ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn tí áńgẹ́lì kẹrin fun kàkàkí rẹ̀?

36 “Áńgẹ́lì kẹrin sì fun kàkàkí rẹ̀. A sì fi agbára lu ìdá mẹ́ta oòrùn àti ìdá mẹ́ta òṣùpá àti ìdá mẹ́ta àwọn ìràwọ̀, kí ìdá mẹ́ta wọn bàa lè ṣókùnkùn, kí ọ̀sán má sì ní ìmọ́lẹ̀ títàn fún ìdá mẹ́ta rẹ̀, àti òru bákan náà.” (Ìṣípayá 8:12) Òkùnkùn gidi ni ìyọnu kẹsàn-án tó wá sórí ilẹ̀ Íjíbítì. (Ẹ́kísódù 10:21-29) Ṣùgbọ́n, kí ni òkùnkùn ìṣàpẹẹrẹ yìí tó mú ìyọnu wá sórí àwọn èèyàn?

37. Báwo ni àpọ́sítélì Pétérù àti Pọ́ọ̀lù ṣe ṣàpèjúwe ipò tẹ̀mí àwọn tí ń bẹ lẹ́yìn òde ìjọ Kristẹni?

37 Àpọ́sítélì Pétérù sọ fáwọn tí wọ́n jọ jẹ́ onígbàgbọ́ pé inú òkùnkùn tẹ̀mí ni wọ́n wà, kí wọ́n tó di Kristẹni. (1 Pétérù 2:9) Pọ́ọ̀lù pẹ̀lú lo ọ̀rọ̀ náà “òkùnkùn” láti ṣàpèjúwe ipò táwọn tó wà lẹ́yìn òde ìjọ Kristẹni wà. (Éfésù 5:8; 6:12; Kólósè 1:13; 1 Tẹsalóníkà 5:4, 5) Ṣùgbọ́n àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ńkọ́, ìyẹn àwọn tí wọ́n sọ pé àwọ́n ní ìgbàgbọ́ nínú Ọlọ́run tí wọ́n sì sọ pé àwọ́n gba Jésù gẹ́gẹ́ bí Olùgbàlà àwọn?

38. Òtítọ́ wo ni áńgẹ́lì kẹrin fi kàkàkí ẹ̀ fun jáde nípa “ìmọ́lẹ̀” àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì?

38 Jésù sọ pé èso àwọn Kristẹni tòótọ́ la ó fi mọ̀ wọ́n àti pé ọ̀pọ̀ àwọn tó sọ pé ọmọlẹ́yìn òun làwọn ló máa jẹ́ àwọn “oníṣẹ́ ìwà àìlófin.” (Mátíù 7:15-23) Kò sẹ́nì kankan tó lè máa wo àwọn èso ìdá mẹ́ta ayé tí ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì gba inú ẹ̀ kan yìí tí ò ní í gbà pé inú òkùnkùn biribiri nípa tẹ̀mí ló ti ń tá ràrà. (2 Kọ́ríńtì 4:4) Ẹ̀bi tiẹ̀ ló pọ̀ jù lọ, torí ó sọ pé Kristẹni lòun. Torí náà, kò sí ṣíṣe kò sí àìṣe, áńgẹ́lì kẹrin ní láti fun kàkàkí ẹ̀ kó lè fi gbé òtítọ́ náà jáde pé òkùnkùn biribiri ni “ìmọ́lẹ̀” àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì, ìmọ́lẹ̀ Bábílónì làwọn orísun “ìmọ́lẹ̀” wọn, kì í ṣe ti Kristẹni.—Máàkù 13:22, 23; 2 Tímótì 4:3, 4.

39. (a) Báwo ni ìpinnu táwọn èèyàn Jèhófà tẹ́wọ́ gbà ní àpéjọ àgbègbè ní 1925 ṣe ṣàpèjúwe ìmọ́lẹ̀ èké àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì? (b) Ìtúfó síwájú sí i wo ni a ṣe ní 1955?

39 Ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí áńgẹ́lì yẹn pòkìkí láti ọ̀run, ogunlọ́gọ̀ àwọn èèyàn Ọlọ́run pé jọ sí àpéjọ àgbègbè kan nílùú Indianapolis, ní ìpínlẹ̀ Indiana, lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà, ní August 29, ọdún 1925, wọ́n sì tẹ́wọ́ gba ìpinnu kan tó sojú abẹ níkòó, tí àkòrí rẹ̀ jẹ́ “Ìhìn Ìrètí,” èyí tí wọ́n tẹ̀ jáde lẹ́yìn náà. Wọ́n pín nǹkan bí àádọ́ta [50] mílíọ̀nù ẹ̀dà rẹ̀ kiri láwọn èdè mélòó kan. Ó sọ̀rọ̀ nípa ìmọ́lẹ̀ èké tí àpapọ̀ àwọn oníṣòwò elérè àjẹpajúdé, àwọn aṣíwájú òṣèlú, àti àwùjọ àwọn àlùfáà ìsìn ń tàn, èyí tó fi jẹ́ pé “àwọn ènìyàn ti ṣubú sínú òkùnkùn.” Ó sì fi hàn pé Ìjọba Ọlọ́run ni ìrètí tòótọ́ fún rírí “ìbùkún àlàáfíà, aásìkí, ìlera, ìyè, òmìnira àti ayọ̀ ayérayé” gbà. Ó gba ìgboyà kí agbo kékeré àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró náà tó lè polongo irú àwọn ìkéde bẹ́ẹ̀ lòdì sí ètò ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì tó tóbi gbàràmù gbaramu. Ṣùgbọ́n láti bí ọdún mélòó kan lẹ́yìn ọdún 1920, wọ́n ti ń bá ìkéde náà bọ̀ láìdáwọ́ dúró títí di ìsinsìnyí. Kódà lákòókò tí kò tíì pẹ́ tóyẹn, ìyẹn lọ́dún 1955, ìwé pẹlẹbẹ kan táwọn èèyàn Ọlọ́run pín káàkiri àgbáyé ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ èdè tú ẹgbẹ́ àlùfáà fó síwájú sí i. Àkòrí ìwé náà ni Kristẹndọm Tabi Jijẹ-Kristian—Ewo Ni “Imọlẹ Aiye”? Lónìí, àgàbàgebè àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ti wá hàn gbangba débi pé ọ̀pọ̀ nínú ayé ti ń rí i fúnra wọn. Ṣùgbọ́n àwọn èèyàn Jèhófà ò tíì dẹ́kun títú u fó nípa jíjẹ́ káwọn èèyàn mọ ohun tó jẹ́ gan-an: ìyẹn ìjọba òkùnkùn.

Idì Tí Ń Fò

40. Kí ni àwọn ìró kàkàkí mẹ́rin náà fi hàn pé ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì jẹ́?

40 Lóòótọ́, àwọn ìró kàkàkí mẹ́rin àkọ́kọ́ wọ̀nyí jẹ́ ká mọ ipò ahoro tó sì ń ṣekú pani tí ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì wà. Ó hàn gbangba pé apá tó jẹ́ ti ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì lórí “ilẹ̀ ayé” yẹ fún ìdájọ́ Jèhófà. A ti rí i kedere pé àwọn ìjọba oníyìípadà jàgídíjàgan tó ń rú yọ láwọn ilẹ̀ rẹ̀ àti ní ibòmíràn léwu nípa tẹ̀mí. Àṣírí bí ẹgbẹ́ àlùfáà rẹ̀ ṣe ṣubú ti tú pátápátá, ó sì ti ṣeé ṣe fún gbogbo èèyàn láti rí i kedere pé inú òkùnkùn tẹ̀mí ló wà. Ní tòótọ́, ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ló jẹ̀bi jù lọ nínú ètò àwọn nǹkan Sátánì.

41. Nígbà táwọn ìró kàkàkí náà dáwọ́ dúró díẹ̀, kí ni Jòhánù rí tó sì gbọ́?

41 Kí ló tún kù ńbẹ̀ láti ṣí payá? Ká tó rí ìdáhùn sí ìbéèrè yí, àwọn ìró kàkàkí dáwọ́ dúró díẹ̀ ná. Ohun tí Jòhánù lóun rí nísinsìnyí rèé: “Mo sì rí, mo sì gbọ́ tí idì kan tí ń fò ní agbedeméjì ọ̀run wí pẹ̀lú ohùn rara pé: ‘Ègbé, ègbé, ègbé ni fún àwọn tí ń gbé lórí ilẹ̀ ayé nítorí ìyókù ìró ìpè kàkàkí àwọn áńgẹ́lì mẹ́ta tí wọ́n máa tó fun kàkàkí wọn!’”—Ìṣípayá 8:13.

42. Kí ni idì tí ń fò náà dúró fún, kí ló sì ń polongo?

42 Idì a máa fò lókèlókè lójú sánmà, tó fi jẹ́ pé àwọn èèyàn púpọ̀ lórí ilẹ̀ lè rí i. Ojú ẹ̀ ríran ketekete ó sì lè rí nǹkan tó bá wà lọ́nà jíjìn. (Jóòbù 39:29) A fi ẹyẹ idì tí ń fò ṣàpẹẹrẹ ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin tí wọ́n jẹ́ kérúbù, tí wọ́n yí ìtẹ́ Ọlọ́run ká. (Ìṣípayá 4:6, 7) Bóyá kérúbù yẹn ni o, tàbí ìránṣẹ́ Ọlọ́run míì tójú ẹ̀ lè rína jìnnà mìíràn ni o, ó ń fi ohùn rara polongo ìkéde alágbára kan pé: “Ègbé, ègbé, ègbé”! Káwọn tó ń gbé ilẹ̀ ayé kíyè sí i, bí wọ́n bá ti ń gbọ́ àwọn ìró kàkàkí mẹ́ta tó kù wọ̀nyẹn, ègbé kọ̀ọ̀kan ń bá ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn rìn ni.

[Àwọ̀n Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]

a Ìṣípayá 7:16 fi ìyàtọ̀ hàn pé ti ogunlọ́gọ̀ ńlá náà máa yàtọ̀, wọn ò ní rí ooru tó ń jó nǹkan gbẹ, èyí tí í ṣe ìbínú Jèhófà.

b Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ìràwọ̀ méje náà tó wà ní ọwọ́ ọ̀tún Jésù dúró fún àwọn alábòójútó ẹni àmì òróró nínú ìjọ Kristẹni, àwọn alàgbà inú èyí tó pọ̀ jù lọ lára iye tó lé ní ọ̀kẹ́ márùn-ún [100,000] ìjọ tó wà láyé báyìí jẹ́ ara ogunlọ́gọ̀ ńlá náà. (Ìṣípayá 1:16; 7:9) Ipò wo ni wọ́n wà? Níwọ̀n bó ti jẹ́ pé ẹ̀mí mímọ́ la fi yàn wọ́n sípò nípasẹ̀ ẹgbẹ́ ẹrú olóòótọ́ àti olóye tí wọ́n jẹ́ ẹni àmì òróró, a lè sọ pé àwọn wọ̀nyí wà ní ọwọ́ ọ̀tun Jésù níbi tó ti ń ṣàkóso wọn, nítorí olùṣọ́ àgùntàn tó ń sìn lábẹ́ rẹ̀ làwọn náà. (Aísáyà 61:5, 6; Ìṣe 20:28) Wọ́n ń ṣètìlẹ́yìn fún “àwọn ìràwọ̀ méje” ní ti pé wọ́n ń sìn níbi táwọn arákùnrin ẹni àmì òróró tó kúnjú ìwọ̀n ò bá ti sí.

[Ìbéèrè fún Ìkẹ́kọ̀ọ́]

[Àtẹ Ìsọfúnnni tó wà ní ojú ìwé 139]

Iwọ Ni Omi Ìsìn Àwọn Oníṣọ́ọ̀ṣì

Ìgbàgbọ́ àti Àṣà Àwọn Oníṣọ́ọ̀ṣì Ohun Tí Bíbélì Wí Gan-an

Orúkọ Ọlọ́run kò ṣe pàtàkì: “Lílo Jésù gbàdúrà pé kí a sọ orúkọ

orúkọ èyíkéyìí kan pàtó fún Ọlọ́run di mímọ́. Pétérù wí pé:

Ọlọ́run tó wà . . . kò bójú mu “Olúkúlùkù ẹni tí ó bá sì ń ké

rárá àti rárá fáwọn Ṣọ́ọ̀ṣì pe orúkọ Jèhófà ni a ó gbà

Kristẹni ní gbogbo àgbáyé.” là.” (Ìṣe 2:21; Jóẹ́lì 2:32;

(Ọ̀rọ̀ Ìṣáájú nínú ìtumọ̀ Bíbélì Ìṣípayá 4:11; 15:3; 19:6)

Revised Standard Version)

Mẹ́talọ́kan ni Ọlọ́run: “Baba jẹ́ Bíbélì sọ pé Jèhófà tóbi ju

Ọlọ́run, Ọmọ jẹ́ Ọlọ́run, Ẹ̀mí Jésù lọ àti pé òun ni Ọlọ́run

Mímọ́ sì jẹ́ Ọlọ́run, síbẹ̀ Ọlọ́run àti orí fún Kristi.

mẹ́ta kọ́ ló wà bí kò ṣe (Jòhánù 14:28; 20:17;

Ọlọ́run kan.” (Ìwé gbédègbẹ́yọ̀ 1 Kọ́ríńtì 11:3) Ipá ìṣiṣẹ́

The Catholic Encyclopedia, Ọlọ́run ni ẹ̀mí mímọ́ jẹ́.

ìtẹ̀jáde ti 1912) (Mátíù 3:11; Lúùkù 1:41;

Ìṣe 2:4)

Ọkàn ẹ̀dá èèyàn jẹ́ aláìleèkú: Èèyàn jẹ́ ọkàn. Nígbà ikú, ọkàn

“Nígbà tí èèyàn bá kú ọkàn àti ò lè ronú mọ́ bẹ́ẹ̀ ni kò lè mòye

ara rẹ̀ ni a pín níyà. Ara ohunkóhun mọ́, yóò padà sí

rẹ̀ . . . máa jẹrà . . . Ṣùgbọ́n, erùpẹ̀ láti inú èyí tí a ti

ọkàn ẹ̀dá èèyàn kì í kú.” dá a. (Jẹ́nẹ́sísì 2:7; 3:19;

(Ìtẹ̀jáde Roman Kátólíìkì kan Sáàmù 146:3, 4;

tí wọ́n pe àkọlé rẹ̀ ní What Oníwàásù 3:19, 20; 9:5, 10;

Happens After Death) Ìsíkíẹ́lì 18:4, 20)

Àwọn èèyàn burúkú máa ń jìyà Ikú ni èrè ẹ̀ṣẹ̀, kì í ṣe

lẹ́yìn ikú ní hẹ́ẹ̀lì: “Gẹ́gẹ́ bó ìdálóró ayérayé. (Róòmù 6:23)

ṣe wà nínú ìgbàgbọ́ Kristẹni Àwọn òkú ń sinmi láìmọ

látọjọ́ pípẹ́, hẹ́ẹ̀lì jẹ́ ibi ohunkóhun nínú hẹ́ẹ̀lì

làásìgbò àti ìrora tí kì í (Hédíìsì, Ṣìọ́ọ̀lù), wọ́n

dópin.” (Ìwé gbédègbẹ́yọ̀ ń dúró de àjíǹde.

The World Book Encyclopedia, (Sáàmù 89:48; Jòhánù 5:28, 29;

ìtẹ̀jáde ti 1987) 11:24, 25; Ìṣípayá 20:13, 14)

“Orúkọ oyè náà Midiatrix Alárinà kan ṣoṣo láàárín

[alárinà obìnrin] la fi ń pe Ọlọ́run àti èèyàn ni Jésù.

Ìyálóde Wa.” (Ìwé gbédègbẹ́yọ̀ (Jòhánù 14:6; 1 Tímótì 2:5;

New Catholic Encyclopedia, Hébérù 9:15; 12:24)

ìtẹ̀jáde 1967)

Àwọn ọmọ ọwọ́ la ní láti batisí: Ìrìbọmi wà fún àwọn tá a ti sọ

“Láti ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ni Ṣọ́ọ̀ṣì ti ń pín di ọmọ ẹ̀yìn tá a sì ti kọ́ láti

Sákírámẹ́ǹtì Ìbatisí fáwọn ọmọ ọwọ́. máa ṣègbọràn sáwọn àṣẹ Jésù.

Kì í ṣe kìkì pé a ka àṣà yìí sí Láti kúnjú ìwọ̀n láti ṣe

èyí tó bófin mu nìkan ni, ṣùgbọ́n a ìrìbọmi, èèyàn gbọ́dọ̀ lóye Ọ̀rọ̀

tún fi kọ́ni pé ó pọn dandan fún Ọlọ́run kó sì lo ìgbàgbọ́.

ìgbàlà.” (Ìwé gbédègbẹ́yọ̀ (Mátíù 28:19, 20;

New Catholic Encyclopedia, Lúùkù 3:21-23; Ìṣe 8:35, 36)

ìtẹ̀jáde 1967)

Ṣọ́ọ̀ṣì tó pọ̀ jù ni wọ́n pín sí ẹgbẹ́ Gbogbo àwọn Kristẹni ọ̀rúndún

ọmọ ìjọ àti ẹgbẹ́ àwọn àlùfáà, tí kìíní ló jẹ́ òjíṣẹ́ tí wọ́n sì ń

wọ́n ń ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ fáwọn ọmọ ìjọ. kópa nínú wíwàásù ìhìn rere.

Wọ́n sábà máa ń fún ẹgbẹ́ àlùfáà (Ìṣe 2:17, 18; Róòmù 10:10-13;

lówó oṣù fún iṣẹ́ òjíṣẹ́ wọn, wọ́n sì 16:1) Kristẹni kan ní láti

máa ń fi oyè bí “Ẹni Ọ̀wọ̀,” “Fadá,” ‘fúnni lọ́fẹ̀ẹ́,’ kò gbọ́dọ̀ máa

“Ẹni Ọ̀wọ̀ Jù Lọ” dá wọn lọ́lá. retí owó oṣù kankan.

(Mátíù 10:7, 8) Jésù ka lílo

àwọn orúkọ oyè ìsìn léèwọ̀.

(Mátíù 6:2; 23:2-12;

1 Pétérù 5:1-3)

Àwọn ère, àwòrán ìjọsìn, àtàwọn Àwọn Kristẹni gbọ́dọ̀ sá fún

àgbélébùú ni wọ́n máa ń lò nínú oríṣiríṣi ìbọ̀rìṣà gbogbo,

ìjọsìn: “Àwọn ère . . . Kristi, títí kan àwọn ìjọsìn míì bẹ́ẹ̀.

ti Wúńdíá Ìyá Ọlọ́run, àti tàwọn (Ẹ́kísódù 20:4, 5;

ẹni mímọ́ mìíràn, la ní láti . . . 1 Kọ́ríńtì 10:14;

fi sínú àwọn ṣọ́ọ̀ṣì ká sì máa fún 1 Jòhánù 5:21) Kì í ṣe ohun tí

wọn ní ọ̀wọ̀ àti ọlá tó yẹ wọ́n.” wọ́n ń fojú rí ni wọ́n fi ń jọ́sìn

(Ìpolongo Ìgbìmọ̀ Trent Ọlọ́run bí kò ṣe ní ẹ̀mí àti ní

[1545 sí 1563]) òtítọ́. (Jòhánù 4:23, 24;

2 Kọ́ríńtì 5:7)

Àwọn olùre ṣọ́ọ̀ṣì ni wọ́n kọ́ pé Jésù wàásù Ìjọba Ọlọ́run gẹ́gẹ́

ìṣèlú ayé ni Ọlọ́run á lò láti mú bí ìrètí tí aráyé ní, kò sọ pé

àwọn ohun tó ní lọ́kàn ṣẹ. Olóògbé ètò ìṣèlú ni ìrètí ayé.

Kádínà Spellman sọ pé: “Kìkì ọ̀nà (Mátíù 4:23; 6:9, 10)

kan ṣoṣo ló wà sí àlàáfíà . . . , Jésù kọ̀ láti lọ́wọ́ nínú ìṣèlú.

ọ̀nà márosẹ̀ ti ìjọba tiwa-n-tiwa.” (Jòhánù 6:14, 15) Ìjọba ẹ̀ kì

Àwọn kókó inú ìròyìn ń fi bí ìsìn í ṣe apá kan ayé yìí; fún ìdí

ti ń lọ́wọ́ sí ìṣèlú ayé hàn (kódà yìí, àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ ò ní

nínú àwọn ìdìtẹ̀ sí ìjọba) àti láti jẹ́ apá kan ayé.

ìtìlẹyìn rẹ̀ fún àjọ Ìparapọ̀ Àwọn (Jòhánù 18:36; 17:16) Jákọ́bù

Orílẹ̀-Èdè gẹ́gẹ́ bí “ìrètí ìkẹyìn kìlọ̀ lòdì sí bíbá ayé dọ́rẹ̀ẹ́.

fún ìrẹ́pọ̀ àti àlàáfíà.” (Jákọ́bù 4:4)

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 132]

Ṣíṣí èdìdì méje náà ló ṣáájú fífun àwọn kàkàkí méje

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 140]

“Ìpèníjà Fáwọn Aṣáájú Ayé” (1922)

Ìpinnu yìí ṣèrànwọ́ láti polongo ìyọnu látọ̀dọ̀ Jèhófà lòdì sí “ilẹ̀ ayé”

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 140]

“Ìkìlọ̀ fún Gbogbo Kristẹni” (1923)

Ìpinnu yìí la fi pòkìkí ìdájọ́ mímúná Jèhófà lórí “ìdá mẹ́ta òkun”

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 141]

“Ẹ̀sùn Tó Wà Lọ́rùn Ẹgbẹ́ Àwọn Àlùfáà” (1924)

Pínpín tá a pín ìwé àṣàrò kúkúrú yìí délé dóko jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé “ìràwọ̀” tó jẹ́ ẹgbẹ́ àlùfáà àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ti já bọ́

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 141]

“Ìhìn Ìrètí” (1925)

Ìpinnu tó ṣe tààràtà yìí la fi tú àṣírí àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì pé ohun tí wọ́n pè ní orísun ìmọ́lẹ̀ wọn jẹ́ orísun òkùnkùn