Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ògo Ìtẹ́ Jèhófà ní Ọ̀run

Ògo Ìtẹ́ Jèhófà ní Ọ̀run

Orí 14

Ògo Ìtẹ́ Jèhófà ní Ọ̀run

Ìran 2—Ìṣípayá 4:1–5:14

Ohun tó dá lé: Àwọn ohun àgbàyanu tó ń ṣẹlẹ̀ níwájú ìtẹ́ ìdájọ́ Ọlọ́run

Ìgbà tó nímùúṣẹ: Ìran yìí gbé àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tí ń ṣẹlẹ̀ láti 1914 títí lọ dé òpin ẹgbẹ̀rún ọdún ìjọba Kristi àti ré kọjá rẹ̀ jáde lọ́nà àkànṣe, nígbà tí gbogbo ẹ̀dá tó wà ní ọ̀run àti lórí ilẹ̀ ayé pátá yóò máa yin Jèhófà.—Ìṣípayá 5:13

1. Kí nìdí tí a fi ní láti fọkàn sí àwọn ìran tó tani jí tí Jòhánù ń sọ fún wa yìí gidigidi?

 JÒHÁNÙ ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ nípa àwọn ìran tó tani jí tó ń sọ fún wa. Nípa ìmísí, ó ṣì wà ní ọjọ́ Olúwa. Nítorí náà, ohun tó ṣàpèjúwe ní ìtumọ̀ pàtàkì fún àwa tá à ń gbé ní ọjọ́ Olúwa yìí ní tòótọ́. Ńṣe ni Jèhófà ń lo àwọn ìran wọ̀nyí láti fi ṣí ìbòjú kúrò lórí àwọn ohun gidi ti ọ̀run tí a kò lè fojú rí, ó sì jẹ́ ká mọ èrò rẹ̀ nípa àwọn ìdájọ́ rẹ̀ tí ń bọ̀ wá sórí ayé. Síwájú sí i, ìṣípayá wọ̀nyí ń jẹ́ ká lè mọ ipò tí a wà nínú àwọn ohun tí Jèhófà pinnu láti ṣe, yálà a ní ìrètí ti ọ̀run tàbí ti orí ilẹ̀ ayé. Nítorí náà, gbogbo wa ní láti máa bá a lọ láti fọkàn sí ọ̀rọ̀ tí Jòhánù sọ yìí gidigidi, ìyẹn: “Aláyọ̀ ni ẹni tí ń ka àwọn ọ̀rọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ yìí sókè àti àwọn tí ń gbọ́, tí wọ́n sì ń pa àwọn ohun tí a kọ sínú rẹ̀ mọ́.”—Ìṣípayá 1:3.

2. Ìrírí wo ni Jòhánù ní nísinsìnyí?

2 Ohun tí Jòhánù wá rí báyìí kọjá ohunkóhun táwọn èèyàn òde òní tíì rí nínú fídíò! Ó kọ̀wé pé: “Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí mo rí, sì wò ó! ilẹ̀kùn kan tí ó ṣí sílẹ̀ ní ọ̀run, ohùn àkọ́kọ́ tí mo sì gbọ́ dà bí ti kàkàkí, ó ń bá mi sọ̀rọ̀, pé: ‘Máa bọ̀ lókè níhìn-ín, èmi yóò sì fi àwọn ohun tí ó gbọ́dọ̀ ṣẹlẹ̀ hàn ọ́.’” (Ìṣípayá 4:1) Nínú ìran, Jòhánù wọnú ọ̀run tí a kò lè fojú rí, ó wá sí iwájú Jèhófà, ẹni tó wà níbi tó ga fíofío kọjá gbalasa òfuurufú tó ṣeé fojú rí táwọn tó ń rìnrìn àjò ní gbalasa òfuurufú tíì mọ̀, àní ó kọjá ibi tàwọn ìṣùpọ̀ ìràwọ̀ ojú ọ̀run wà pàápàá. Bí ẹní wọlé sínú ilẹ̀kùn ṣíṣí sílẹ̀ kan ni a ṣe ní kí Jòhánù wọlé wá wo ìran àgbàyanu kan nípa inú òkè ọ̀run pátápátá lọ́hùn-ún táwọn ẹni ẹ̀mí ń gbé, níbi tí Jèhófà fúnra rẹ̀ ti gúnwà sórí ìtẹ́. (Sáàmù 11:4; Aísáyà 66:1) Àǹfààní yìí mà ga o!

3. Kí ni ohùn tó “dà bí ti kàkàkí” mú wá sọ́kàn wa, láìsí iyè méjì, ta sì ni Orísun rẹ̀?

3 Bíbélì kò sọ ohun tí “ohùn àkọ́kọ́” yìí jẹ́. Àmọ́ ó ní ìró àṣẹ bíi ti kàkàkí tí ohùn alágbára ti Jésù tí a gbọ́ ní ìṣáájú ní. (Ìṣípayá 1:10, 11) Ó mú wa rántí ìró ìwo tí ń wọni létí tó jẹ́ àmì wíwà tí Jèhófà wà ní Òkè Sínáì. (Ẹ́kísódù 19:18-20) Láìsí iyè méjì, Jèhófà tó tóbi lọ́ba ni Orísun ohùn tó ń pa àṣẹ náà. (Ìṣípayá 1:1) Ńṣe ló ṣí ilẹ̀kùn kí Jòhánù lè tipa ìran wọ ibi tó jẹ́ ibi mímọ́ jù lọ láàárín ibi tó lọ salalu tí Jèhófà Ọba Aláṣẹ ayé àtọ̀run ń ṣàkóso.

Ìrísí Ológo Jèhófà

4. (a) Ìtumọ̀ wo ni ìran Jòhánù ní fún àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró? (b) Ìtumọ̀ wo ni ó ní fún àwọn tó ní ìrètí ìwàláàyè títí láé lórí ilẹ̀ ayé?

4 Kí ni Jòhánù rí? Fetí sílẹ̀, kó o gbọ́ bó ṣe ń sọ ohun àgbàyanu tó rí. Ó ní: “Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, mo wá wà nínú agbára ẹ̀mí lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀: sì wò ó! ìtẹ́ kan wà ní ipò rẹ̀ ní ọ̀run, ẹni kan sì wà tí ó jókòó lórí ìtẹ́ náà.” (Ìṣípayá 4:2) Ní ìṣẹ́jú akàn, ipá ìṣiṣẹ́ Ọlọ́run gbé Jòhánù lọ nínú ẹ̀mí, síbi ìtẹ́ Jèhófà gan-an. Èyí mára Jòhánù yá gágá gan-an! Níhìn-ín, a jẹ́ kó rí àkọ́wò ìran kan tó jẹ́ àrímáleèlọ nípa ọ̀run, níbi tí a ti tọ́jú “ogún tí ó jẹ́ aláìlè-díbàjẹ́ àti aláìlẹ́gbin àti aláìlèṣá” pa mọ́ sí de òun àti àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró yòókù. (1 Pétérù 1:3-5; Fílípì 3:20) Ìran Jòhánù tún ní ìtumọ̀ pàtàkì pẹ̀lú fún àwọn tó ní ìrètí pé wọn á wà láàyè títí láé lórí ilẹ̀ ayé. Ó jẹ́ kí wọ́n lè róye ìrísí ológo tó wà níbi tí Jèhófà wà kí wọ́n sì mọ̀ nípa ètò tí Jèhófà ń lò lọ́run láti fi ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, tó sì jẹ́ èyí tí yóò tún lò nígbà tó bá yá láti fi darí ìgbésí ayé àwọn èèyàn lórí ilẹ̀ ayé. Ọlọ́run ètò tí ó ga lọ́lá ni Jèhófà lóòótọ́!

5. Ohun gidi wo ni Jòhánù rí èyí ti ìdérí àpótí májẹ̀mú náà ṣàpẹẹrẹ rẹ̀?

5 Púpọ̀ lára ohun tí Jòhánù rí lókè ọ̀run lọ́hùn-ún jọ àwọn apá tó ṣe pàtàkì nínú àgọ́ ìjọsìn tí ń bẹ ní aginjù. Wọ́n kọ́ àgọ́ ìjọsìn yẹn ní nǹkan bí ẹgbẹ̀jọ [1,600] ọdún ṣáájú ìgbà ayé Jòhánù gẹ́gẹ́ bí ibi táwọn ọmọ Ísírẹ́lì á ti máa ṣe ìjọsìn tòótọ́. Nínú ibi Mímọ́ Jù Lọ àgọ́ ìjọsìn yẹn ni àpótí májẹ̀mú wà, orí ìdérí oníwúrà líle koránkorán Àpótí yẹn ni Jèhófà sì ti sọ̀rọ̀. (Ẹ́kísódù 25:17-22; Hébérù 9:5) Fún ìdí yìí, ìdérí Àpótí náà jẹ́ àpẹẹrẹ ìtẹ́ Jèhófà. Nísinsìnyí Jòhánù wá rí ohun gidi tí èyí jẹ́ àpẹẹrẹ rẹ̀, ìyẹn: Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ fúnra rẹ̀ tó gúnwà sórí ìtẹ́ rẹ̀ gíga fíofío ní ọ̀run tòun ti ògo tó kọyọyọ!

6. Kí ni Jòhánù sọ fún wa nípa Jèhófà, kí sì nìdí tí èyí fi bá a mu wẹ́kú?

6 Jòhánù kò ṣe kúlẹ̀kúlẹ̀ àpèjúwe nípa Ẹni Mímọ́ tó jókòó sórí rẹ̀ bí àwọn wòlíì ìṣáájú tí wọ́n ti rí àwọn ìran ìtẹ́ Jèhófà ti ṣe. (Ìsíkíẹ́lì 1:26, 27; Dáníẹ́lì 7:9, 10) Ṣùgbọ́n bí Jòhánù ṣe sọ ohun tó rí nípa Ẹni tó jókòó lórí ìtẹ́ náà nìyí: “Ẹni tí ó jókòó, ní ìrísí, sì dà bí òkúta jásípérì àti òkúta aláwọ̀ pupa tí ó ṣeyebíye, àti yí ká ìtẹ́ náà òṣùmàrè kan wà tí ó dà bí òkúta émírádì ní ìrísí.” (Ìṣípayá 4:3) Áà, ògo tí kò láfiwé yìí kọyọyọ! Ohun tí Jòhánù rí ni ẹwà tó wà nípò tó tòrò mini, tó ń dán tó sì ń kọ mànà bí àwọn òkúta iyebíye dídán gbinrin, tí ń kọ yẹ̀rì. Ẹ sì wo bí èyí ti bá àpèjúwe tí Jákọ́bù ọmọ ẹ̀yìn ṣe nípa Jèhófà pé ó jẹ́ “Baba àwọn ìmọ́lẹ̀ àtọ̀runwá” mu wẹ́kú tó! (Jákọ́bù 1:17) Ní gẹ́rẹ́ lẹ́yìn tí Jòhánù gan-an kọ Ìṣípayá, ló sọ pé: “Ọlọ́run jẹ́ ìmọ́lẹ̀, kò sì sí òkùnkùn kankan rárá ní ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.” (1 Jòhánù 1:5) Ẹni ológo tó ga lọ́lá jù lọ ni Jèhófà jẹ́ ní tòótọ́!

7. Kí ni ẹ̀kọ́ tá a lè rí kọ́ nínú wíwà tí òṣùmàrè wà yí ká ìtẹ́ Jèhófà?

7 Kíyè sí i pé Jòhánù rí òṣùmàrè kan, tí àwọ̀ rẹ̀ jẹ́ àwọ̀ émírádì aláwọ̀ ewé yí ká ìtẹ́ náà. Ọ̀rọ̀ Gíríìkì náà tí a túmọ̀ níhìn-ín sí òṣùmàrè (irʹis) fi hàn pé ńṣe ló rí bìrìkìtì ní ìrísí. Ìgbà tí Bíbélì kọ́kọ́ mẹ́nu kan òṣùmàrè ni ìgbà tó ń sọ̀rọ̀ nípa ọjọ́ Nóà. Lẹ́yìn tí Ìkún-omi gbẹ, Jèhófà mú kí òṣùmàrè kan fara hàn ní àwọsánmà, ó sì ṣàlàyé ohun tó ṣàpẹẹrẹ, ó ní: “Òṣùmàrè mi ni mo fi sí àwọsánmà, yóò sì jẹ́ àmì májẹ̀mú láàárín èmi àti ilẹ̀ ayé. Èmi yóò sì rántí májẹ̀mú mi dájúdájú, èyí tí ń bẹ láàárín èmi àti ẹ̀yin àti gbogbo alààyè ọkàn láàárín gbogbo ẹran ara; omi kì yóò sì di àkúnya omi mọ́ láti run gbogbo ẹran ara.” (Jẹ́nẹ́sísì 9:13, 15) Nígbà náà, kí ni ìran tí Jòhánù wá rí ni ọ̀run yóò mú wá sọ́kàn Jòhánù? Ó yẹ kí òṣùmàrè tó rí yẹn rán an létí pé ó yẹ kó ní àjọṣe alálàáfíà pẹ̀lú Jèhófà, irú èyí tí ẹgbẹ́ Jòhánù ń gbádùn lónìí. Yóò tún jẹ́ kó mọ irú ìtòròmini àti àlàáfíà tó wà níbi tí Jèhófà wà pẹ̀lú, ìtòròmini kan tí gbogbo èèyàn onígbọràn yóò ní nígbà tí Jèhófà bá ta àgọ́ rẹ̀ bo aráyé nínú ayé tuntun.—Sáàmù 119:165; Fílípì 4:7; Ìṣípayá 21:1-4.

Dídá Àwọn Alàgbà Mẹ́rìnlélógún Náà Mọ̀

8. Àwọn wo ni Jòhánù rí yí ká ìtẹ́ náà, ta ni àwọn wọ̀nyí sì dúró fún?

8 Jòhánù mọ̀ pé a yan àwọn àlùfáà kí wọ́n máa sìn nínú àgọ́ ìjọsìn ìgbàanì. Nítorí náà, ó ṣeé ṣe kó yà á lẹ́nu láti rí ohun tó ṣàpèjúwe tẹ̀ lé e yìí: “Àti yí ká ìtẹ́ náà ni ìtẹ́ mẹ́rìnlélógún wà, mo sì rí àwọn alàgbà mẹ́rìnlélógún tí wọ́n wọ ẹ̀wù àwọ̀lékè funfun, tí wọ́n jókòó sórí ìtẹ́ wọ̀nyí, adé wúrà sì ń bẹ ní orí wọn.” (Ìṣípayá 4:4) Bẹ́ẹ̀ ni, kàkà kó rí àwọn àlùfáà, alàgbà mẹ́rìnlélógún ló rí, tí wọ́n wà lórí ìtẹ́ tí wọ́n sì dé adé bí ọba. Àwọn wo ni alàgbà wọ̀nyí? Àwọn ẹni àmì òróró inú ìjọ Kristẹni ni, tó jẹ́ pé wọ́n ti jíǹde tí wọ́n sì wà ní ipò tí Jèhófà ṣèlérí fún wọn lọ́run. Báwo la ṣe mọ èyí?

9, 10. Báwo ni a ṣe mọ̀ pé alàgbà mẹ́rìnlélógún náà dúró fún ìjọ Kristẹni ẹni àmì òróró tí wọ́n wà nínú ipò ológo wọn ní ọ̀run?

9 Lákọ̀ọ́kọ́ ná, wọ́n dé adé. Bíbélì sọ̀rọ̀ nípa àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró pé wọ́n gba ‘adé kan tí kò lè díbàjẹ́’ wọ́n sì tún gba ìwàláàyè àìlópin, ìyẹn àìleèkú. (1 Kọ́ríńtì 9:25; 15:53, 54) Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí alàgbà mẹ́rìnlélógún wọ̀nyí ti jókòó lórí ìtẹ́, adé wúrà tí wọ́n dé níbí yìí dúró fún níní tí wọ́n ní ọlá àṣẹ bí ọba. (Fi wé Ìṣípayá 6:2; 14:14.) Èyí wà níbàámu pẹ̀lú àlàyé tá a ti ṣe pé alàgbà mẹ́rìnlélógún náà dúró fún àwọn ẹni àmì òróró ọmọlẹ́yìn Jésù bí wọ́n ṣe wà ní ipò wọn ní ọ̀run, torí Jésù bá wọn dá májẹ̀mú pé wọ́n máa jókòó sórí ìtẹ́ nínú Ìjọba òun. (Lúùkù 22:28-30) Jésù àti alàgbà mẹ́rìnlélógún wọ̀nyí nìkan ni a ṣàpèjúwe pé wọ́n ń ṣàkóso ní ọ̀run ní iwájú Jèhófà, kódà Bíbélì ò sọ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ nípa àwọn áńgẹ́lì.

10 Èyí bá ìlérí tí Jésù ṣe fún ìjọ Laodíkíà mu pé: “Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun ni èmi yóò yọ̀ǹda fún láti jókòó pẹ̀lú mi lórí ìtẹ́ mi.” (Ìṣípayá 3:21) Ṣùgbọ́n iṣẹ́ tí a yàn fún àwọn alàgbà mẹ́rìnlélógún náà ní ọ̀run kò mọ sí ṣíṣe ìjọba. Nígbà tí Jòhánù ń nasẹ̀ ìwé Ìṣípayá, ó sọ nípa Jésù pé: “Ó sì mú kí a jẹ́ ìjọba kan, àlùfáà fún Ọlọ́run àti Baba rẹ̀.” (Ìṣípayá 1:5, 6) Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọba àti àlùfáà bákan náà. “Wọn yóò jẹ́ àlùfáà Ọlọ́run àti ti Kristi, wọn yóò sì ṣàkóso gẹ́gẹ́ bí ọba pẹ̀lú rẹ̀ fún ẹgbẹ̀rún ọdún náà.”—Ìṣípayá 20:6.

11. Èé ṣe tó fi bá a mu wẹ́kú pé iye àwọn alàgbà wọnnì jẹ́ mẹ́rìnlélógún, kí sì ni iye yẹn túmọ̀ sí?

11 Kí ni ó ṣe pàtàkì nípa iye náà mẹ́rìnlélógún, tó fi jẹ́ pé alàgbà mẹ́rìnlélógún ni Jòhánù rí yí ká ìtẹ́ náà? Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀nà làwọn olóòótọ́ nínú àlùfáà Ísírẹ́lì ìgbàanì gbà jẹ́ àpẹẹrẹ ìṣáájú fún àwọn alàgbà wọ̀nyí. Àpọ́sítélì Pétérù kọ̀wé sí àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró pé: “Ẹ̀yin jẹ́ ‘ẹ̀yà àyànfẹ́, ẹgbẹ́ àlùfáà aládé, orílẹ̀-èdè mímọ́, àwọn ènìyàn fún àkànṣe ìní.’” (1 Pétérù 2:9) Ẹ sì wá wò ó o, ẹgbẹ́ mẹ́rìnlélógún ni wọ́n pín ẹgbẹ́ àlùfáà àwọn Júù ìgbàanì sí. Ìpín kọ̀ọ̀kan ni a pín àwọn ọ̀sẹ̀ tirẹ̀ fún lọ́dún kí wọ́n máa wá sìn níwájú Jèhófà, tó fi jẹ́ pé iṣẹ́ ìsìn ọlọ́wọ̀ ń bá a lọ láìsí ìdádúró. (1 Kíróníkà 24:5-19) Ó bá a mu wẹ́kú, nígbà náà, pé alàgbà mẹ́rìnlélógún ni Jòhánù rí nínú ìran nípa ẹgbẹ́ àlùfáà ti ọ̀run nítorí ńṣe ni ẹgbẹ́ àlùfáà yìí ń sin Jèhófà nígbà gbogbo, láìdáwọ́dúró. Nígbà tí wọ́n bá pé, ìpín mẹ́rìnlélógún ni yóò wà, ọ̀kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ẹgbàáta [6,000] aṣẹ́gun, nítorí Ìṣípayá 14:1-4 sọ fún wa pé ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì [144,000], (ìyẹn, mẹ́rìnlélógún lọ́nà ẹgbàáta [24 x 6,000]), ni a “rà láti ilẹ̀ ayé wá” láti dúró ní Òkè Síónì ti ọ̀run pẹ̀lú Ọ̀dọ́ Àgùntàn náà, Jésù Kristi. Níwọ̀n bí iye náà méjìlá ti túmọ̀ sí ètò tí Ọlọ́run mú kó fìdí múlẹ̀ gbọn-in, mẹ́rìnlélógún jẹ́ ìlọ́po méjì, tàbí èyí tó túbọ̀ fún irú ìṣètò bẹ́ẹ̀ lókun.

Mànàmáná, Ohùn, àti Ààrá

12. Kí ni Jòhánù rí tó sì gbọ́ lẹ́yìn èyí, kí sì ni “mànàmáná àti ohùn àti ààrá” mú wa rántí?

12 Kí ni Jòhánù rí tí ó sì gbọ́ lẹ́yìn èyí? Ó ní: “Mànàmáná àti ohùn àti ààrá sì ń jáde wá láti inú ìtẹ́ náà.” (Ìṣípayá 4:5a) Èyí múni rántí àwọn ọ̀nà àgbàyanu míì tí Jèhófà ti gbà fi agbára rẹ̀ hàn gan-an ni! Bí àpẹẹrẹ, nígbà tí Jèhófà “sọ̀ kalẹ̀” sórí Òkè Sínáì, Mósè ròyìn pé: “Ní ọjọ́ kẹta, nígbà tí ó di òwúrọ̀, ó sì ṣẹlẹ̀ pé ààrá sán, mànàmáná sì bẹ̀rẹ̀ sí kọ, àti àwọsánmà ṣíṣú dùdù lórí òkè ńlá náà àti ìró ìwo adúnròkè lálá. . . . Nígbà tí ìró ìwo náà túbọ̀ ń dún kíkankíkan láìdáwọ́ dúró, Mósè bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀, Ọlọ́run tòótọ́ sì bẹ̀rẹ̀ sí fi ohùn dá a lóhùn.”—Ẹ́kísódù 19:16-19.

13. Kí ni mànàmáná tí ń ti ibi ìtẹ́ Jèhófà jáde dúró fún?

13 Ní ọjọ́ Olúwa, Jèhófà ń fi agbára rẹ̀ àti wíwà tó wà nítòsí hàn lọ́nà ológo tó ga lọ́lá. Àmọ́ kì í ṣe nípa lílo mànàmáná gidi, nítorí àmì làwọn ohun tí Jòhánù rí jẹ́. Kí wá ni mànàmáná náà dúró fún? Ó dára, ìbùyẹ̀rì mànàmáná lè fúnni ní ìmọ́lẹ̀, ó sì tún lè pani. Fún ìdí yìí, mànàmáná tí ń bù yẹ̀rì jáde láti ibi ìtẹ́ Jèhófà jẹ́ àpẹẹrẹ àwọn ìbùyẹ̀rì ìlàlóye àti ní pàtàkì jù lọ, àwọn ìhìn nípa ìdájọ́ amú-bí-iná tí Ọlọ́run ń bá a lọ láti fún àwọn èèyàn rẹ̀ láìdáwọ́dúró.—Fi wé Sáàmù 18:14; 144:5, 6; Mátíù 4:14-17; 24:27.

14. Báwo ni ohùn ṣe ń dún jáde lónìí?

14 Àwọn ohùn náà ńkọ́? Lákòókò tí Jèhófà sọ̀ kalẹ̀ sórí Òkè Sínáì, ohùn kan bá Mósè sọ̀rọ̀. (Ẹ́kísódù 19:19) Àwọn ohùn láti ọ̀run ló sọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun tó jẹ́ àṣẹ àti ìpòkìkí inú ìwé Ìṣípayá. (Ìṣípayá 4:1; 10:4, 8; 11:12; 12:10; 14:13; 16:1, 17; 18:4; 19:5; 21:3) Lónìí Jèhófà pẹ̀lú ti sọ àwọn ohun tó jẹ́ àṣẹ àti àwọn ìpòkìkí kan fáwọn èèyàn rẹ̀, ní títan ìmọ́lẹ̀ sí òye wọn nípa àwọn àsọtẹ́lẹ̀ àti àwọn ìlànà Bíbélì. A sábà máa ń gbọ́ àwọn ìsọfúnni tó ń lani lóye láwọn àpéjọ àgbègbè, irú àwọn òtítọ́ Bíbélì bẹ́ẹ̀ ni a sì ti pòkìkí kárí ayé lẹ́yìn náà. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ nípa àwọn olóòótọ́ oníwàásù ìhìn rere pé: “Họ́wù, ní ti tòótọ́, ‘ìró wọ́n jáde lọ sí gbogbo ilẹ̀ ayé, àsọjáde wọn sì jáde lọ sí àwọn ìkángun ilẹ̀ ayé tí a ń gbé.’”—Róòmù 10:18.

15. Ààrá wo ló ti sán jáde láti orí ìtẹ́ náà ní apá tá a wà yìí nínú ọjọ́ Olúwa?

15 Ààrá sábà máa ń tẹ̀ lé mànàmáná. Dáfídì tọ́ka sí ààrá gidi gẹ́gẹ́ bí “ohùn Jèhófà.” (Sáàmù 29:3, 4) Nígbà tí Jèhófà bá àwọn ọ̀tá jà fún Dáfídì, ààrá ni Bíbélì sọ pe Ó rán sí wọn. (2 Sámúẹ́lì 22:14; Sáàmù 18:13) Élíhù sọ fún Jóòbù pé ohùn Jèhófà dún bí ààrá, bí Ó ti ń ṣe “àwọn ohun ńlá ti a kò lè mọ̀.” (Jóòbù 37:4, 5) Ní apá tá a wà yìí nínú ọjọ́ Olúwa, Jèhófà ti ‘sán ààrá,’ ní kíkìlọ̀ nípa àwọn ohun ńláǹlà tí òun yóò ṣe sí àwọn ọ̀tá rẹ̀. Ìró àwọn ààrá ìṣàpẹẹrẹ wọ̀nyí ti dún àdúntúndún jákèjádò ilẹ̀ ayé. Ayọ̀ ńbẹ fún ọ o, tó o bá ń fiyè sí ìpòkìkí adún-bí-ààrá wọ̀nyí tó o sì ń lo ahọ́n rẹ lọ́nà tó bọ́gbọ́n mu láti fi kún ìró wọn!—Aísáyà 50:4, 5; 61:1, 2.

Àwọn Fìtílà Iná àti Òkun Bí Gíláàsì

16. Kí ni “fìtílà iná méje” náà túmọ̀ sí?

16 Kí ni Jòhánù rí síwájú sí i? Ohun tí ó rí nìyí: “Fìtílà iná méje sì wà tí ń jó níwájú ìtẹ́ náà, ìwọ̀nyí sì túmọ̀ sí ẹ̀mí méje ti Ọlọ́run. Àti níwájú ìtẹ́ náà ni ohun tí a lè pè ní òkun bí gíláàsì, tí ó dà bí kírísítálì wà.” (Ìṣípayá 4:5b, 6a) Jòhánù fúnra rẹ̀ sọ ohun tí fìtílà méje náà dúró fún pé: “Ìwọ̀nyí sì túmọ̀ sí ẹ̀mí méje ti Ọlọ́run.” Iye náà, méje, ṣàpẹẹrẹ ìpépérépéré nínú àwọn ohun ti Ọlọ́run; fún ìdí yìí, fìtílà méje náà ní láti dúró fún ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ agbára ìlanilóye ti ẹ̀mí mímọ́. Ẹ wo bí ẹgbẹ́ Jòhánù náà ti kún fún ìmoore tó lónìí pé a ti fi ìlàlóye yìí sí ìkáwọ́ rẹ̀, tó sì tún jẹ́ ojúṣe rẹ̀ láti rí i dájú pé ìlàlóye yìí dé ọ̀dọ̀ àwọn tí ebi ń pa nípa tẹ̀mí nínú ayé! Inú wa sì dùn gan-an ni pé lọ́dọọdún ọgọ́rọ̀ọ̀rún mílíọ̀nù ẹ̀dà ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́ ń bá a lọ láti máa tan ìmọ́lẹ̀ yìí jáde ní nǹkan bí igba [200] èdè!—Sáàmù 43:3.

17. Kí ni “òkun bí gíláàsì tí ó dà bí òkúta kírísítálì” náà ṣàpẹẹrẹ?

17 Pẹ̀lúpẹ̀lù Jòhánù rí “òkun bí gíláàsì tí ó dà bí kírísítálì.” Kí ni èyí yóò ṣàpẹẹrẹ nínú ọ̀ràn àwọn tí Jèhófà pè wá sínú ààfin rẹ̀ lọ́run? Pọ́ọ̀lù sọ̀rọ̀ nípa ọ̀nà tí Jésù gbà sọ ìjọ Ọlọ́run di mímọ́, pé ó ‘wẹ̀ ẹ́ mọ́ pẹ̀lú ìwẹ̀ omi nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ náà.’ (Éfésù 5:26) Ṣáájú ikú rẹ̀, Jésù sọ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé: “Ẹ ti mọ́ nísinsìnyí nítorí ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ fún yín.” (Jòhánù 15:3) Nítorí bẹ́ẹ̀, òkun bí gíláàsì tó dà bíi kírísítálì yìí ní láti dúró fún àkọsílẹ̀ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tí ń wẹni mọ́. Àwọn ẹgbẹ́ àlùfáà tó jẹ́ ọba tí wọ́n wá síwájú Jèhófà ní láti jẹ́ àwọn tí a fi Ọ̀rọ̀ rẹ̀ wẹ̀ mọ́ tónítóní.

Wò Ó—“Ẹ̀dá Alààyè Mẹ́rin”!

18. Kí ni Jòhánù rí láàárín ìtẹ́ náà àti yí ká rẹ̀?

18 Jòhánù tún kíyè sí nǹkan mìíràn wàyí. Ó kọ̀wé pé: “Àti ní àárín ìtẹ́ náà àti yí ká ìtẹ́ náà ni àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin wà tí wọ́n kún fún ojú níwájú àti lẹ́yìn.”—Ìṣípayá 4:6b.

19. Kí ni àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọnnì dúró fún, báwo la sì ṣe mọ èyí?

19 Kí ni àwọn ẹ̀dá wọ̀nyí dúró fún? Ìran kan tí wòlíì mìíràn, ìyẹn Ìsíkíẹ́lì, ròyìn jẹ́ ká rí ìdáhùn rẹ̀. Ìsíkíẹ́lì rí Jèhófà lórí ìtẹ́ kan tó wà lórí kẹ̀kẹ́ ẹṣin ọ̀run tó láwọn ẹ̀dá alààyè kan, àwọn ẹ̀dá alààyè yìí sì fàwọn nǹkan kan jọ àwọn tí Jòhánù ṣàpèjúwe. (Ìsíkíẹ́lì 1:5-11, 22-28) Lẹ́yìn èyí, Ìsíkíẹ́lì tún rí kẹ̀kẹ́ ẹṣin tí ìtẹ́ wà lórí rẹ̀ yìí kan náà tòun tàwọn ẹ̀dá alààyè náà. Ṣùgbọ́n, lọ́tẹ̀ yí, kérúbù ló pe àwọn ẹ̀dá alààyè náà. (Ìsíkíẹ́lì 10:9-15) Nígbà náà, ẹ̀dá alààyè mẹ́rin tí Jòhánù rí ní láti dúró fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn kérúbù Ọlọ́run, ìyẹn àwọn ẹ̀dá tó wà nípò gíga nínú ètò Rẹ̀ tó jẹ́ tàwọn ẹ̀dá ẹ̀mí. Kò ní ṣàjèjì sí Jòhánù láti rí àwọn kérúbù pé wọ́n wà ní ipò tó sún mọ́ ibi tí Jèhófà wà pẹ́kípẹ́kí, nítorí pé nínú ìṣètò àgọ́ ìjọsìn ìgbàanì, àwọn kérúbù oníwúrà méjì wà lórí ọmọrí àpótí májẹ̀mú, èyí tó dúró fún ìtẹ́ Jèhófà. Ohùn Jèhófà sì máa ń sọ àwọn òfin fún orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì láti àárín àwọn kérúbù wọ̀nyí.—Ẹ́kísódù 25:22; Sáàmù 80:1.

20. Ọ̀nà wo la lè gbà sọ pé ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọnnì wà ní “àárín ìtẹ́ náà àti yí ká ìtẹ́ náà”?

20 Ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí wà “ní àárín ìtẹ́ náà àti yí ká ìtẹ́ náà.” Kí ni èyí túmọ̀ sí gan-an? Ó lè túmọ̀ sí pé wọ́n wà yí ká ìtẹ́ náà lọ́nà tó fi jẹ́ pé ọ̀kan dúró ní agbedeméjì ìhà kọ̀ọ̀kan. Nípa báyìí, àwọn tí wọ́n túmọ̀ Bíbélì Today’s English Version tún ọ̀rọ̀ Gíríìkì ìpilẹ̀ṣẹ̀ náà sọ lọ́rọ̀ mìíràn, wọ́n ní: “yí ìtẹ́ náà ká ní àwọn ìhà rẹ̀ kọ̀ọ̀kan.” Gbólóhùn náà sì tún lè túmọ̀ sí pé ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà wà ní àárín gbùngbùn ọ̀run níbi tí ìtẹ́ náà wà. Ó ṣeé ṣe kí èyí jẹ́ ìdí tí Bíbélì The Jerusalem Bible fi túmọ̀ gbólóhùn ọ̀rọ̀ náà lọ́nà yìí: “ní àárín gbùngbùn, a pín wọn sí ẹgbẹẹgbẹ́ yí ká ìtẹ́ náà.” Ohun tó ṣáà ṣe pàtàkì ni bí àwọn kérúbù náà ṣe sún mọ́ ìtẹ́ Jèhófà pẹ́kípẹ́kí, lọ́nà tó jọ tàwọn kérúbù tí Ìsíkíẹ́lì rí ní igun kọ̀ọ̀kan kẹ̀kẹ́ ẹṣin tó dúró fún ètò Jèhófà. (Ìsíkíẹ́lì 1:15-22) Gbogbo èyí bá àwọn ọ̀rọ̀ Sáàmù 99:1 mu pé: “Jèhófà fúnra rẹ̀ ti di ọba. . . . Ó jókòó lórí àwọn kérúbù.”

21, 22. (a) Báwo ni Jòhánù ṣe ṣàpèjúwe ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọnnì? (b) Kí ni ìrísí ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà dúró fún?

21 Jòhánù ń bá a lọ pé: “Ẹ̀dá alààyè kìíní sì dà bí kìnnìún, ẹ̀dá alààyè kejì sì dà bí ẹgbọrọ akọ màlúù, ẹ̀dá alààyè kẹta sì ní ojú bí ti ènìyàn, ẹ̀dá alààyè kẹrin sì dà bí idì tí ń fò.” (Ìṣípayá 4:7) Èé ṣe tí ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí fi ní ìrísí tó yàtọ̀ síra wọn? Ó hàn gbangba pé ńṣe làwọn ẹ̀dá alààyè tó dá yàtọ̀ wọ̀nyí ń fi apá pàtó kan lára àwọn ànímọ́ Ọlọ́run hàn. Àkọ́kọ́ níbẹ̀ ni kìnnìún. Nínú Bíbélì, a máa ń fi kìnnìún ṣàpẹẹrẹ ìgboyà, pàápàá tá a bá ń sọ̀rọ̀ nípa ṣíṣe ẹ̀tọ́ àti òdodo. (2 Sámúẹ́lì 17:10; Òwe 28:1) Nípa báyìí, kìnnìún dúró fún ànímọ́ Ọlọ́run tí í ṣe ìdájọ́ òdodo onígboyà. (Diutarónómì 32:4; Sáàmù 89:14) Ẹ̀dá alààyè kejì jọ ẹgbọrọ akọ màlúù. Ànímọ́ wo ni akọ màlúù mú wá sọ́kàn rẹ? Lójú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, akọ màlúù jẹ́ ohun ìní kan tó ṣeyebíye nítorí agbára rẹ̀. (Òwe 14:4; tún wo Jóòbù 39:9-11.) Ẹgbọrọ akọ màlúù, nígbà náà, dúró fún agbára, okun inú gẹ́gẹ́ bí Jèhófà ti pèsè rẹ̀.—Sáàmù 62:11; Aísáyà 40:26.

22 Ẹ̀dá alààyè kẹta ní ojú bíi tèèyàn. Èyí ní láti dúró fún ìfẹ́ lọ́nà ti Ọlọ́run, nítorí pé lórí ilẹ̀ ayé, èèyàn nìkan ni Ọlọ́run dá ní àwòrán ara rẹ̀, tó sì dá ànímọ́ aláìlẹ́gbẹ́ náà, ìfẹ́, mọ́. (Jẹ́nẹ́sísì 1:26-28; Mátíù 22:36-40; 1 Jòhánù 4:8, 16) Láìsí iyè méjì, àwọn kérúbù ń fi ànímọ́ yìí hàn bí wọ́n ti ń sìn ní àyíká ìtẹ́ Jèhófà. Wàyí o, ẹ̀dá alààyè kẹrin ńkọ́? Èyí ní ìrísí idì tí ń fò. Jèhófà fúnra rẹ̀ pe àfiyèsí sí agbára ìríran ńláǹlà idì, ó ní: “Ojú rẹ̀ ń wo ọ̀nà jíjìn.” (Jóòbù 39:29) Fún ìdí yìí, idì dúró fún ọgbọ́n tí ń ríran jìnnà. Jèhófà ni Orísun ọgbọ́n. Àwọn kérúbù rẹ̀ ń lo ọgbọ́n àtọ̀runwá bí wọ́n ti ń ṣègbọràn sí àwọn àṣẹ rẹ̀.—Òwe 2:6; Jákọ́bù 3:17.

Ìyìn Jèhófà Ró Gbọnmọgbọnmọ

23. Kí ni kíkún tí ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọnnì “kún fún ojú” ṣàpẹẹrẹ, kí sì ni níní tí wọ́n ní ìyẹ́ apá méjì méjì lọ́nà mẹ́ta ń fi hàn?

23 Jòhánù ń bá àpèjúwe rẹ̀ lọ pé: “Àti ní ti àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà, olúkúlùkù wọn lọ́tọ̀ọ̀tọ̀ ní ìyẹ́ apá mẹ́fà; yí ká àti lábẹ́, wọ́n kún fún ojú. Wọn kò sì ní ìsinmi rárá lọ́sàn-án àti lóru bí wọ́n ti ń wí pé: ‘Mímọ́, mímọ́, mímọ́ ni Jèhófà Ọlọ́run, Olódùmarè, tí ó ti wà, tí ń bẹ, tí ó sì ń bọ̀.’” (Ìṣípayá 4:8) Kíkún tí wọ́n kún fún ojú yìí ń fi hàn pé wọ́n ní agbára ìríran tó pé pérépéré tó sì ríran jìnnà. Ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọnnì ń lò wọ́n láìdáwọ́dúró, torí pé wọn kì í sùn ní tiwọn. Wọ́n tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Ẹni tí Bíbélì sọ nípa rẹ̀ pé: “Ní ti Jèhófà, ojú rẹ̀ ń lọ káàkiri ní gbogbo ilẹ̀ ayé láti fi okun rẹ̀ hàn nítorí àwọn tí ọkàn-àyà wọn pé pérépéré síhà ọ̀dọ̀ rẹ̀.” (2 Kíróníkà 16:9) Níwọ̀n bí àwọn kérúbù yìí ti ní ojú tó pọ̀ tó bẹ́ẹ̀, wọ́n lè rí ibi gbogbo. Kò sí ohunkóhun tó ń fo àfiyèsí wọn. Nípa báyìí, wọ́n ti gbára dì ní kíkún láti ṣe iṣẹ́ tí Ọlọ́run bá yàn fún wọ́n nínú iṣẹ́ ìdájọ́ rẹ̀. Bíbélì sọ nípa Ọlọ́run pé: “Ojú Jèhófà ń bẹ ní ibi gbogbo, ó ń ṣọ́ àwọn ẹni búburú àti àwọn ẹni rere.” (Òwe 15:3) Bákan náà, bí àwọn kérúbù náà ṣe ní ìyẹ́ apá méjì méjì lọ́nà mẹ́ta, wọ́n lè gbéra lọ fàì bíi ti mànàmáná lọ síbikíbi láti polongo àwọn ìdájọ́ Jèhófà kí wọ́n sì mú wọn ṣẹ, nítorí pé iye tàbí nọ́ńbà náà, mẹ́ta là ń lò nínú Bíbélì fún ìtẹnumọ́.

24. Báwo ni àwọn kérúbù ṣe ń yin Jèhófà, kí nìyẹn sì tún mọ̀ sí?

24 Fetí sílẹ̀! Orin ìyìn tí àwọn kérúbù ń kọ sí Jèhófà jẹ́ orin adùnyùngbà tó ń mórí ẹni wú gidigidi. Wọ́n ní: “Mímọ́, mímọ́, mímọ́ ni Jèhófà Ọlọ́run, Olódùmarè, tí ó ti wà, tí ń bẹ, tí ó sì ń bọ̀.” Lẹ́ẹ̀kan sí i, ńṣe ni jíjẹ́ tí ìpolongo wọn jẹ́ mẹ́ta ń fi hàn pé ó gbóná janjan. Àwọn kérúbù náà ń tẹnu mọ́ ọn gidigidi pé Jèhófà Ọlọ́run jẹ́ mímọ́. Òun ni Orísun ìjẹ́mímọ́, òun gan-an sì ni Ìdiwọ̀n ìjẹ́mímọ́. Òun pẹ̀lú tún ni “Ọba ayérayé,” ìgbà gbogbo ni òun sì jẹ́ “Ááfà àti Ómégà, ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìkẹyìn, ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ àti òpin.” (1 Tímótì 1:17; Ìṣípayá 22:13) Àwọn kérúbù kì í fìgbà kankan sinmi rárá o bí wọ́n ti ń pòkìkí àwọn ànímọ́ Jèhófà aláìlẹ́gbẹ́ níwájú gbogbo ẹ̀dá.

25. Báwo ni àwọn ẹ̀dá alààyè àti alàgbà mẹ́rìnlélógún wọnnì ṣe ń fi ìṣọ̀kan júbà Jèhófà?

25 Ìyìn Jèhófà wá ń dún lọ réré ní gbogbo inú ìsálú ọ̀run! Jòhánù ń bá ohun tó ń sọ lọ pé: “Àti nígbàkigbà tí àwọn ẹ̀dá alààyè náà bá fi ògo àti ọlá àti ìdúpẹ́ fún Ẹni tí ó jókòó lórí ìtẹ́, Ẹni tí ó wà láàyè títí láé àti láéláé, àwọn alàgbà mẹ́rìnlélógún náà a wólẹ̀ níwájú Ẹni tí ó jókòó lórí ìtẹ́, wọn a jọ́sìn Ẹni tí ó wà láàyè títí láé àti láéláé, wọn a sì ju adé wọn síwájú ìtẹ́ náà, wọn a sọ pé: ‘Jèhófà, àní Ọlọ́run wa, ìwọ ni ó yẹ láti gba ògo àti ọlá àti agbára, nítorí pé ìwọ ni ó dá ohun gbogbo, àti nítorí ìfẹ́ rẹ ni wọ́n ṣe wà, tí a sì dá wọn.’” (Ìṣípayá 4:9-11) Nínú gbogbo Ìwé Mímọ́, èyí jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọ̀nà tó ga lọ́lá jù lọ tí wọ́n gbà júbà Jèhófà, Ọlọ́run wa àti Olúwa Ọba Aláṣẹ!

26. Kí nìdí tí alàgbà mẹ́rìnlélógún wọnnì fi ju adé wọn sílẹ̀ níwájú Jèhófà?

26 Alàgbà mẹ́rìnlélógún wọnnì ní irú ẹ̀mí kan náà tí Jésù ní, àní débi pé wọ́n ju adé wọn sílẹ̀ níwájú Jèhófà. Kò sóhun tó jọ èrò gbígbé ara ẹni ga níwájú Ọlọ́run lọ́kàn wọn rárá. Tìrẹ̀lẹ̀tìrẹ̀lẹ̀ ni wọ́n fi mọ̀ dájú pé ìdí kan ṣoṣo tí wọ́n fi wà nípò ọba ni láti máa fi ọlá àti ògo fún Ọlọ́run àní bí Jésù ti ń ṣe nígbà gbogbo. (Fílípì 2:5, 6, 9-11) Pẹ̀lú ìtẹríba ni wọ́n fi fi hàn pé ipò rírẹlẹ̀ làwọn wà, tí wọ́n sì tún fi hàn pé ọlá Jèhófà tó jẹ́ Ọba Aláṣẹ làwọn fi ń ṣàkóso. Nípa báyìí, wọ́n wà ní ìṣọ̀kan látọkànwá pẹ̀lú àwọn kérúbù àti ìyókù ìṣẹ̀dá olóòótọ́ ní fífi ìyìn àti ògo fún Ọlọ́run tí ó dá ohun gbogbo.—Sáàmù 150:1-6.

27, 28. (a) Ipa wo ló yẹ kí àpèjúwe Jòhánù nípa ìran yìí ní lórí wa? (b) Àwọn ìbéèrè wo ló jẹ yọ nípa ohun tí Jòhánù rí tó sì gbọ́ tẹ̀ lé èyí?

27 Ta ní lè ka ohun tí Jòhánù kọ nípa ìran yìí tí orí rẹ̀ ò ní wú? Ó kàmàmà, àní àgbàyanu ni! Ṣùgbọ́n báwo ni gbogbo èyí ṣe kàn wá? Ẹnikẹ́ni tó bá lẹ́mìí ìmọrírì ní láti jẹ́ kí ọlá ńlá Jèhófà mú kí òun dara pọ̀ mọ́ ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọnnì àti alàgbà mẹ́rìnlélógún náà láti máa yin Jèhófà, nínú àdúrà gbígbà àti nípa pípòkìkí orúkọ rẹ̀ fáwọn èèyàn. Èyí ni Ọlọ́run tí àwa Kristẹni ní àǹfààní láti jẹ́ ẹlẹ́rìí rẹ̀ lónìí. (Aísáyà 43:10) Rántí pé ìran Jòhánù kan ọjọ́ Olúwa, èyí tá a wà lónìí. “Ẹ̀mí méje” yẹn wà lárọ̀ọ́wọ́tó nígbà gbogbo láti ṣamọ̀nà wa kó sì fún wa lókun. (Gálátíà 5:16-18) A ní Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lónìí, tó lè ràn wá lọ́wọ́ ká lè jẹ́ mímọ́ bá a ṣe ń sin Ọlọ́run mímọ́. (1 Pétérù 1:14-16) Dájúdájú, a láyọ̀ láti ka àwọn ọ̀rọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ yìí sókè. (Ìṣípayá 1:3) Ẹ wo bí wọ́n ṣe ń ràn wá lọ́wọ́ tó ká lè jẹ́ olóòótọ́ sí Jèhófà ká má sì jẹ́ kí ayé pín ọkàn wa níyà nínú kíkọrin ìyìn rẹ̀ déédéé!—1 Jòhánù 2:15-17.

28 Jòhánù ti ṣàpèjúwe ohun tó rí nígbà tí a ké sí i láti gba ẹnu ilẹ̀kùn ṣíṣí sílẹ̀ yẹn ní ọ̀run wọlé wá. Ní pàtàkì jù lọ, ó ròyìn pé Jèhófà, Ọ̀gá Ògo, gúnwà sórí ìtẹ́ Rẹ̀ lókè ọ̀run nínú ọlá ńlá àti gbogbo ògo Rẹ̀. Ètò tó lágbára jù lọ láyé àtọ̀run sì wà yí i ká, ìyẹn ètò tó jẹ́ pé ògo ẹwà rẹ̀ àti ìdúróṣinṣin rẹ̀ kọyọyọ. Bẹ́ẹ̀ ni, Kóòtù ọ̀run wà lẹ́nu iṣẹ́. (Dáníẹ́lì 7:9, 10, 18) Ohun àrà ọ̀tọ̀ kan máa tó ṣẹlẹ̀ wàyí. Kí ni ohun náà, báwo ló sì ṣe kàn wá lónìí? Ẹ jẹ́ ká máa wo bí ìran náà yóò ṣe máa ṣẹlẹ̀!

[Ìbéèrè fún Ìkẹ́kọ̀ọ́]

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 75]

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 78]