Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Àwọn Àkòrí Ọ̀rọ̀ Bíbélì fún Ìjíròrò

Àwọn Àkòrí Ọ̀rọ̀ Bíbélì fún Ìjíròrò

Àwọn Àkòrí Ọ̀rọ̀ Bíbélì fún Ìjíròrò

(látinú Ìtumọ̀ Ayé Tuntun)

1. Àdúrà

  A. Àwọn àdúrà tí Ọlọ́run máa ń gbọ́

Lóòótọ́ ni Ọlọ́run máa ń fetí sí àdúrà àwọn ènìyàn.  Sm 145:18; 1Pe 3:12

Kì í gbọ́ ti aláìṣòdodo àyàfi bí ó bá yí padà. Ais 1:15-17

A gbọ́dọ̀ gbàdúrà ní orúkọ Jésù. Joh 14:13, 14; 2Kọ 1:20

A gbọ́dọ̀ gbàdúrà ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run. 1Jo 5:14, 15

Ìgbàgbọ́ ṣe pàtàkì. Jak 1:6-8

 B. Àtúnwí asán, àdúrà sí Màríà tàbí àwọn “ẹni mímọ́” kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀

A gbọ́dọ̀ gbàdúrà sí Ọlọ́run ní orúkọ Jésù. Joh 14:6, 14; 16:23, 24

Àtúnwí ọ̀rọ̀ ni a kò ní gbọ́. Mt 6:7

2. Àgbélébùú

  A. A gbé Jésù kọ́ sórí òpó igi ìfikúpani gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gàn

A gbé Jésù kọ́ sórí òpó igi ìfikúpani tàbí igi. Iṣe 5:30; 10:39; Ga 3:13

Àwọn Kristẹni gbọ́dọ̀ gbé òpó igi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gàn. Mt 10:38; Lk 9:23

 B. A kò gbọ́dọ̀ jọ́sìn rẹ̀

Fífi òpó igi Jésù hàn káàkiri jẹ́ ẹ̀gàn. Heb 6:6; Mt 27:41, 42

Lílo àgbélébùú nínú ìjọsìn jẹ́ ìbọ̀rìṣà. Ẹk 20:4, 5; Jer 10:3-5

Jésù jẹ́ ẹ̀mí, kò sí lórí òpó igi mọ́. 1Ti 3:16; 1Pe 3:18

3. Àjíǹde

  A. Ìrètí fún àwọn òkú

Gbogbo àwọn tí ń bẹ nínú ibojì ni a óò gbé dìde. Joh 5:28, 29

Àjíǹde Jésù jẹ́ ẹ̀rí ìfọwọ́sọ̀yà. 1Kọ 15:20-22; Iṣe 17:31

Àwọn tí ó ṣẹ̀ sí ẹ̀mí kì yóò jíǹde. Mt 12:31, 32

A mú un dájú fún àwọn tí ń fi ìgbàgbọ́ hàn. Joh 11:25

 B. Àjíǹde sí ìyè ní ọ̀run tàbí lórí ilẹ̀ ayé

Gbogbo ènìyàn ń kú nínú Ádámù; ń rí ìyè nínú Jésù. 1Kọ 15:20-22; Ro 5:19

Ìyàtọ̀ nínú irú ẹ̀dá àwọn tí a gbé dìde. 1Kọ 15:40, 42, 44

Àwọn tí yóò wà lọ́dọ̀ Jésù yóò dà bí rẹ̀. 1Kọ 15:49; Flp 3:20, 21

Àwọn tí kò ní ṣàkóso yóò wà lórí ilẹ̀ ayé. Iṣi 20:4b, 5, 13; 21:3, 4

4. Amágẹ́dónì

  A. Ogun Ọlọ́run láti fi òpin sí ìwà burúkú

Àwọn orílẹ̀-èdè ń gbárajọ sí Amágẹ́dónì. Iṣi 16:14, 16

Ọlọ́run yóò jà, yóò lo Ọmọ àti àwọn áńgẹ́lì. 2Tẹ 1:6-9; Iṣi 19:11-16

Bí a ṣe lè là á já. Se 2:2, 3; Iṣi 7:14

 B. Kò rú òfin ìfẹ́ Ọlọ́run

Ayé ti bàjẹ́ pátápátá. 2Ti 3:1-5

Ọlọ́run ní sùúrù, ṣùgbọ́n ìdájọ́ òdodo béèrè ìgbésẹ̀. 2Pe 3:9, 15; Lk 18:7, 8

Ẹni burúkú gbọ́dọ̀ kọjá lọ kí olódodo lè láásìkí. Owe 21:18; Iṣi 11:18

5. Àmúlùmálà Ìgbàgbọ́

  A. Dídarapọ̀ mọ́ àwọn ìsìn mìíràn kì í ṣe ọ̀nà Ọlọ́run

Ọ̀nà kan ṣoṣo, tóóró ni, díẹ̀ ni ó ń rí i. Ef 4:4-6; Mt 7:13, 14

A kìlọ̀ fúnni pé ẹ̀kọ́ èké ń sọni di eléèérí. Mt 16:6, 12; Ga 5:9

A pàṣẹ fún wa láti ta kété. 2Ti 3:5; 2Kọ 6:14-17; Iṣi 18:4

 B. “Gbogbo ìsìn ni ó ní rere tirẹ̀” kì í ṣe òtítọ́

Àwọn kan ní ìtara ṣùgbọ́n kì í ṣe ní ìbámu pẹ̀lú ti Ọlọ́run. Ro 10:2, 3

Búburú a máa ba rere yòówù tí ó bá wà jẹ́. 1Kọ 5:6; Mt 7:15-17

Àwọn olùkọ́ èké a máa mú ìparun wá. 2Pe 2:1; Mt 12:30; 15:14

Ìjọsìn tí ó mọ́ ń béèrè fún ìfọkànsìn pátápátá. Di 6:5, 14, 15

6. Àtakò, Inúnibíni

  A. Ìdí fún àtakò sí àwọn Kristẹni

A kórìíra Jésù, ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ àtakò. Joh 15:18-20; Mt 10:22

Rírọ̀mọ́ àwọn ìlànà títọ́ ń dá ayé lẹ́bi. 1Pe 4:1, 4, 12, 13

Sátánì, ọlọ́run ètò yìí, ń tako Ìjọba náà. 2Kọ 4:4; 1Pe 5:8

Kristẹni kì í bẹ̀rù, Ọlọ́run ń tini lẹ́yìn. Ro 8:38, 39; Jak 4:8

 B. Aya kò gbọ́dọ̀ gba ọkọ láyè láti ya òun nípa sí Ọlọ́run

A kìlọ̀ tẹ́lẹ̀; ẹlòmíràn lè fún ọkọ ní ìsọfúnni èké. Mt 10:34-38; Iṣe 28:22

Òun gbọ́dọ̀ máa wo ọ̀dọ̀ Ọlọ́run àti Kristi. Joh 6:68; 17:3

Nípa ìṣòtítọ́, ó lè gbà á là pẹ̀lú. 1Kọ 7:16; 1Pe 3:1-6

Ọkọ ni orí, ṣùgbọ́n kì í ṣe láti pàṣẹ ìjọsìn. 1Kọ 11:3; Iṣe 5:29

 D. Ọkọ kò gbọ́dọ̀ jẹ́ kí aya dí òun lọ́wọ́ sísin Ọlọ́run

Ó gbọ́dọ̀ nífẹ̀ẹ́ aya àti ìdílé, kí ó fẹ́ ìyè fún wọn. 1Kọ 7:16

Òun ló ni ẹrù iṣẹ́ láti pinnu, láti pèsè. 1Kọ 11:3; 1Ti 5:8

Ọlọ́run nífẹ̀ẹ́ ọkùnrin tí ó bá dúró fún òtítọ́. Jak 1:12; 5:10, 11

Jíjuwọ́sílẹ̀ nítorí àlàáfíà ń mú ìbínú Ọlọ́run wá. Heb 10:38

Ṣamọ̀nà ìdílé sí ayọ̀ nínú Ayé Tuntun. Iṣi 21:3, 4

7. Àyànmọ́

  A. A kò yan àyànmọ́ kankan fún ènìyàn

Ète Ọlọ́run dájú. Ais 55:11; Jẹ 1:28

Olúkúlùkù ni a fún ní òmìnira yíyàn láti sin Ọlọ́run. Joh 3:16; Flp 2:12

8. Bíbélì

  A. Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ní ìmísí

Ẹ̀mí Ọlọ́run ni ó sún àwọn ènìyàn láti kọ̀wé. 2Pe 1:20, 21

Ó ní àsọtẹ́lẹ̀ nínú: Da 8:5, 6, 20-22; Lk 21:5, 6, 20-22; Ais 45:1-4

Gbogbo Bíbélì ní ìmísí ó sì ṣàǹfààní. 2Ti 3:16, 17; Ro 15:4

 B. Ó jẹ́ amọ̀nà wíwúlò fún ọjọ́ wa

Ṣíṣàìka ìlànà Bíbélì sí lè ṣekú pani. Ro 1:28-32

Ọgbọ́n ènìyàn kì í ṣe arọ́pò. 1Kọ 1:21, 25; 1Ti 6:20

Ààbò kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá lílágbára jù lọ. Ef 6:11, 12, 17

Ó ń ṣamọ̀nà ènìyàn ní ọ̀nà títọ́. Sm 119:105; 2Pe 1:19; Owe 3:5, 6

 D. A kọ ọ́ fún ènìyàn orílẹ̀-èdè àti ẹ̀yà ìran gbogbo

A bẹ̀rẹ̀ kíkọ Bíbélì ní Ìlà-Oòrùn. Ẹk 17:14; 24:12, 16; 34:27

Ìpèsè Ọlọ́run kì í ṣe fún àwọn ará Yúróòpù nìkan. Ro 10:11-13; Ga 3:28

Ọlọ́run tẹ́wọ́ gba gbogbo onírúurú ènìyàn. Iṣe 10:34, 35; Ro 5:18; Iṣi 7:9, 10

9. Ère

  A. Lílo àwọn ère, ère ìrántí, nínú ìjọsìn jẹ́ ẹ̀gàn sí Ọlọ́run

Ère Ọlọ́run kò ṣeé yà. 1Jo 4:12; Ais 40:18; 46:5; Iṣe 17:29

A kìlọ̀ fún àwọn Kristẹni lòdì sí ère. 1Kọ 10:14; 1Jo 5:21

Ọlọ́run ni a ní láti sìn ní ẹ̀mí, òtítọ́. Joh 4:24

 B. Ìjọsìn ère yọrí sí ikú fún orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì

A ka ìjọsìn ère léèwọ̀ fún àwọn Júù. Ẹk 20:4, 5

Kò lè gbọ́ràn, sọ̀rọ̀; àwọn tí ń ṣe wọ́n dà bí wọn. Sm 115:4-8

Ó mú ìdẹkùn, ìparun wá. Sm 106:36, 40-42; Jer 22:8, 9

 D. Ìjọsìn “aláàlà” ni a kò pa láṣẹ

Ọlọ́run kò fàyè gba ìjọsìn “aláàlà” fún ara rẹ̀. Ais 42:8

Ọlọ́run nìkan ṣoṣo ni “Olùgbọ́ àdúrà.” Sm 65:1, 2

10. Èṣù, Àwọn Ẹ̀mí Èṣù

  A. Èṣù jẹ́ ẹ̀dá ẹ̀mí kan

Kì í ṣe ìwà ibi nínú ènìyàn bí kò ṣe ẹ̀dá ẹ̀mí kan. 2Ti 2:26

Èṣù jẹ́ ẹ̀dá kan gẹ́gẹ́ bí àwọn áńgẹ́lì. Mt 4:1, 11; Job 1:6

Ó sọ ara rẹ̀ di Èṣù nípasẹ̀ ìfẹ́-ọkàn àìtọ́. Jak 1:13-15

 B. Èṣù ni ẹni tí a kò lè rí tí ń ṣàkóso ayé

Ayé wà lábẹ́ àkóso rẹ̀ bí ọlọ́run. 2Kọ 4:4; 1Jo 5:19; Iṣi 12:9

A fi í sílẹ̀ títí a ó fi yanjú àríyànjiyàn. Ẹk 9:16; Joh 12:31

A ó sọ ọ́ sínú ọ̀gbun, lẹ́yìn náà, a ó pa á run. Iṣi 20:2, 3, 10

 D. Àwọn áńgẹ́lì tí ó ṣọ̀tẹ̀ ni àwọn ẹ̀mí èṣù

Wọ́n dara pọ̀ mọ́ Sátánì ṣáájú Ìkún Omi. Jẹ 6:1, 2; 1Pe 3:19, 20

A rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, a ké wọn kúrò nínú gbogbo ìlàlóye. 2Pe 2:4; Jud 6

Wọ́n ń bá Ọlọ́run jà, wọn ń ni aráyé lára. Lk 8:27-29; Iṣi 16:13, 14

A ó pa wọ́n run pẹ̀lú Sátánì. Mt 25:41; Lk 8:31; Iṣi 20:2, 3, 10

11. Ẹ̀jẹ̀

  A. Gbígba ẹ̀jẹ̀ sára rú òfin ìjẹ́mímọ́ ẹ̀jẹ̀

A sọ fún Nóà pé ẹ̀jẹ̀ jẹ́ mímọ́, òun ni ìwàláàyè. Jẹ 9:4, 16

Májẹ̀mú Òfin ka jíjẹ ẹ̀jẹ̀ léèwọ̀. Le 17:14; 7:26, 27

A tún ìkàléèwọ̀ rẹ̀ sọ fún àwọn Kristẹni. Iṣe 15:28, 29; 21:25

 B. Ọ̀ràn gbígba ẹ̀mí là kò dáni láre láti rú òfin Ọlọ́run

Ìgbọràn sàn ju ẹbọ lọ. 1Sa 15:22; Mk 12:33

Fífi ẹ̀mí ẹni ṣáájú òfin Ọlọ́run ń ṣe ikú pani. Mk 8:35, 36

12. Ẹlẹ́rìí Jèhófà

  A. Ìpilẹ̀ṣẹ̀ Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà

Jèhófà fi àwọn ẹlẹ́rìí tirẹ̀ hàn. Ais 43:10-12; Jer 15:16

Ìlà àwọn ẹlẹ́rìí olùṣòtítọ́ bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú Ébẹ́lì. Heb 11:4, 39; 12:1

Jésù jẹ́ ẹlẹ́rìí aṣeégbíyèlé àti olóòótọ́. Joh 18:37; Iṣi 1:5; 3:14

13. Ẹ̀mí, Ìbẹ́mìílò

  A. Ohun tí ẹ̀mí mímọ́ jẹ́

Ipá agbéṣẹ́ṣe Ọlọ́run, kì í ṣe ẹnì kan. Iṣe 2:2, 3, 33; Joh 14:17

A lò ó nínú ìṣẹ̀dá, ìmísí Bíbélì, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Jẹ 1:2; Isk 11:5

A fi bí, a fi yan, ẹ̀yà ara Kristi. Joh 3:5-8; 2Kọ 1:21, 22

Ó ń fi agbára fún, ń ṣamọ̀nà ènìyàn Ọlọ́run lónìí. Ga 5:16, 18

 B. Ipá ìwàláàyè ni a ń pè ní ẹ̀mí

Ìlànà ìwàláàyè, a mú un dúró nípasẹ̀ èémí. Jak 2:26; Job 27:3

Agbára lórí ipá ìwàláàyè wà lọ́wọ́ Ọlọ́run. Sek 12:1; Onw 8:8

Ti Ọlọ́run ni ipá ìwàláàyè ẹ̀dá ènìyàn, ẹranko. Onw 3:19-21

A fi ẹ̀mí lé Ọlọ́run lọ́wọ́ pẹ̀lú ìrètí àjíǹde. Lk 23:46

 D. A gbọ́dọ̀ kọ ìbẹ́mìílò sílẹ̀ bí iṣẹ́ àwọn ẹ̀mí èṣù

Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run kà á léèwọ̀. Ais 8:19, 20; Le 19:31; 20:6, 27

Àfọ̀ṣẹ jẹ́ bíbá ẹ̀mí èṣù lò; a dá a lẹ́bi. Iṣe 16:16-18

Ó ń yọrí sí ìparun. Ga 5:19-21; Iṣi 21:8; 22:15

A ka wíwo ìràwọ̀ léèwọ̀. Di 18:10-12; Jer 10:2

14. Ẹ̀sìn

  A. Ẹ̀sìn tòótọ́ kan ṣoṣo ni ó wà

Ìrètí kan, ìgbàgbọ́ kan, ìbatisí kan. Ef 4:5, 13

A pa á láṣẹ láti sọni di ọmọ ẹ̀yìn. Mt 28:19; Iṣe 8:12; 14:21

Èso rẹ̀ ni a ó fi mọ̀ ọ́n. Mt 7:19, 20; Lk 6:43, 44; Joh 15:8

Ìfẹ́, ìfohùnṣọ̀kan láàárín àwọn mẹ́ńbà. Joh 13:35; 1Kọ 1:10; 1Jo 4:20

 B. A wọ́gi lé ẹ̀kọ́ èké lọ́nà tí ó tọ́

Jésù wọ́gi lé ẹ̀kọ́ èké. Mt 23:15, 23, 24; 15:4-9

Ó ṣe bẹ́ẹ̀ fún ààbò àwọn tí a ti fọ́ lójú. Mt 15:14

Òtítọ́ sọ wọ́n di òmìnira láti di ọmọ ẹ̀yìn Jésù. Joh 8:31, 32

 D. Yíyí ẹ̀sìn ẹni padà ṣe kókó bí a bá fi hàn pé kò tọ̀nà

Òtítọ́ ń sọni di òmìnira; ń fi hàn pé ọ̀pọ̀ ti kùnà. Joh 8:31, 32

Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, àwọn mìíràn, fi ìjọsìn ìṣáájú sílẹ̀. Joṣ 24:15; 2 Ọba 5:17

Kristẹni ìjímìjí yí ojú ìwòye padà. Ga 1:13, 14; Iṣe 3:17, 19

Pọ́ọ̀lù yí ẹ̀sìn rẹ̀ padà. Iṣe 26:4-6

Gbogbo ayé ni a tàn jẹ; a gbọ́dọ̀ yí èrò padà. Iṣi 12:9; Ro 12:2

 E. “Rere ń bẹ nínú gbogbo ẹ̀sìn” tí a ń wí kò mú ojú rere Ọlọ́run dájú

Ọlọ́run gbé ọ̀pá ìdiwọ̀n kalẹ̀ fún ìjọsìn. Joh 4:23, 24; Jak 1:27

Kò dára bí kì í bá ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run. Ro 10:2, 3

A lè kọ “àwọn iṣẹ́ rere” tì. Mt 7:21-23

Èso ni a fi ń mọ̀ ọ́n. Mt 7:20

15. Ẹ̀ṣẹ̀

  A. Ohun tí ẹ̀ṣẹ̀ jẹ́

Rírú òfin Ọlọ́run, ọ̀pá ìdiwọ̀n rẹ̀ pípé. 1Jo 3:4; 5:17

Ènìyàn, bí ìṣẹ̀dá Ọlọ́run, ní láti jíhìn fún un. Ro 14:12; 2:12-15

Òfin fi ẹ̀ṣẹ̀ hàn, ó jẹ́ kí ènìyàn mọ̀ ọ́n. Ga 3:19; Ro 3:20

Aráyé wà nínú ẹ̀ṣẹ̀, wọ́n kùnà ọ̀pá ìdiwọ̀n pípé Ọlọ́run. Ro 3:23; Sm 51:5

 B. Ìdí tí gbogbo ènìyàn fi ń jìyà nípa ẹ̀ṣẹ̀ Ádámù

Ádámù mú àìpé, ikú kọjá sórí gbogbo ènìyàn. Ro 5:12, 18

Ọlọ́run jẹ́ aláàánú ní fífaradà á fún aráyé. Sm 103:8, 10, 14, 17

Ìrúbọ Jésù ni ó ń wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ nù. 1Jo 2:2

Ẹ̀ṣẹ̀ àti gbogbo iṣẹ́ Èṣù mìíràn ni a ó nù kúrò. 1Jo 3:8

 D. Èso tí a kàléèwọ̀ jẹ́ àìgbọràn, kì í ṣe ìbálòpọ̀ takọtabo

Ìkàléèwọ̀ igi ni a ti ṣe kí a tó dá Éfà. Jẹ 2:17, 18

A sọ fún Ádámù àti Éfà pé kí wọ́n ní àwọn ọmọ. Jẹ 1:28

Ọmọ kì í ṣe ìyọrísí ẹ̀ṣẹ̀, bí kò ṣe ìbùkún Ọlọ́run. Sm 127:3-5

Éfà ṣẹ̀ nígbà tí ọkọ̀ rẹ̀ kò sí níbẹ̀, ó kánjú. Jẹ 3:6; 1Ti 2:11-14

Ádámù, gẹ́gẹ́ bí orí, ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Ọlọ́run. Ro 5:12, 19

 E. Ohun tí ẹ̀ṣẹ̀ sí ẹ̀mí mímọ́ jẹ́ (Mt 12:32; Mk 3:28, 29)

Ẹ̀ṣẹ̀ àjogúnbá kì í ṣe irúfẹ́ èyíinì. Ro 5:8, 12, 18; 1Jo 5:17

Ẹnì kan lè mú ẹ̀mí bínú, síbẹ̀ kí ó padà bọ̀ sípò. Ef 4:30; Jak 5:19, 20

Mímọ̀ọ́mọ̀ sọ ẹ̀ṣẹ̀ dàṣà a máa yọrí sí ikú. 1Jo 3:6-9

Ọlọ́run a máa dá irúfẹ́ ẹni bẹ́ẹ̀ lẹ́jọ́, a mú ẹ̀mí rẹ̀ kúrò. Heb 6:4-8

A kò gbọ́dọ̀ gbàdúrà fún irúfẹ́ àwọn aláìronú-pìwàdà bẹ́ẹ̀. 1Jo 5:16, 17

16. Hẹ́ẹ̀lì (Hédíìsì, Ṣìọ́ọ̀lù)

  A. Kì í ṣe ibi gidi kan tí a ti ń fi iná dáni lóró

Jóòbù tí ń jẹ̀rora gbàdúrà láti lọ síbẹ̀. Job 14:13

Ibi àìlè-ṣe-nǹkankan. Sm 6:5; Onw 9:10; Ais 38:18, 19

A gbé Jésù dìde kúrò nínú isà òkú, hẹ́ẹ̀lì. Iṣe 2:27, 31, 32; Sm 16:10

Hẹ́ẹ̀lì yóò jọ̀wọ́ òkú inú rẹ̀ lọ́wọ́, a ó pa á run. Iṣi 20:13, 14

 B. Iná ṣàpẹẹrẹ ìparun yán-án yán-án

Ìkékúrò sínú ikú ni a fi iná ṣàpẹẹrẹ. Mt 25:41, 46; 13:30

Ẹni ibi aláìronú-pìwàdà yóò pa run láé bí ẹni pé nípasẹ̀ iná. Heb 10:26, 27

Ikú ayérayé ni iná “ìdálóró” Sátánì. Iṣi 20:10, 14, 15

 D. Ìròyìn nípa ọlọ́rọ̀ àti Lásárù kì í ṣe ẹ̀rí ìdálóró ayérayé

Kì í ṣe ináyìíná bí oókan àyà kì í ti í ṣe oókan àyà Ábúráhámù gan-an. Lk 16:22-24

Ojú rere Ábúráhámù pẹ̀lú jẹ́ ìfiwéra pẹ̀lú òkùnkùn. Mt 8:11, 12

Ìparun yán-án-yán Bábílónì ni a pè ní ìdálóró oníná. Iṣi 18:8-10, 21

17. Ìbatisí

  A. Ohun kan tí a ń béèrè lọ́wọ́ Kristẹni

Jésù fi àpẹẹrẹ lélẹ̀. Mt 3:13-15; Heb 10:7

Àmì sísẹ́ ara ẹni tàbí ìyàsímímọ́. Mt 16:24; 1Pe 3:21

Kìkì fún àwọn tí ó dàgbà tó láti kẹ́kọ̀ọ́. Mt 28:19, 20; Iṣe 2:41

Ìrìbọmi nínú omi ni ọ̀nà tí ó tọ̀nà. Iṣe 8:38, 39; Joh 3:23

 B. Kò wẹ ẹ̀ṣẹ̀ nù

A kò batisí Jésù láti wẹ ẹ̀ṣẹ̀ nù. 1Pe 2:22; 3:18

Ẹ̀jẹ̀ Jésù ni ó ń wẹ ẹ̀ṣẹ̀ nù. 1Jo 1:7

18. Ìgbàlà

  A. Ìgbàlà ń ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá nípasẹ̀ ẹbọ ìràpadà Jésù

Ìwàláàyè jẹ́ ẹ̀bùn Ọlọ́run nípasẹ̀ Ọmọ rẹ̀. 1Jo 4:9, 14; Ro 6:23

Ìgbàlà ṣeé ṣe kìkì nípasẹ̀ ẹbọ Jésù. Iṣe 4:12

Iṣẹ́ kankan kò ṣeé ṣe nínú “ìrònúpìwàdà lórí ibùsùn ikú.” Jak 2:14, 26

A gbọ́dọ̀ ṣiṣẹ́ tokuntokun láti rí ìgbàlà. Lk 13:23, 24; 1Ti 4:10

 B. “Ìgbàlà lẹ́ẹ̀kan, ìgbàlà gbogbo ìgbà” kò bá Ìwé Mímọ́ mu

Àwọn tí ó jẹ́ alábàápín ẹ̀mí mímọ́ lè ṣubú. Heb 6:4, 6; 1Kọ 9:27

A pa ọ̀pọ̀ lára ọmọ Ísírẹ́lì run bí a tilẹ̀ gbà wọ́n là kúrò ní Íjíbítì. Jud 5

Ìgbàlà kì í ṣe lẹ́sẹ̀ kan náà. Flp 2:12; 3:12-14; Mt 10:22

Àwọn tí ń yí padà burú ju ti ìṣáájú lọ. 2Pe 2:20, 21

 D. “Ìgbàlà gbogbo ayé” kò bá Ìwé Mímọ́ mu

Ìrònúpìwàdà kò ṣeé ṣe fún àwọn kan. Heb 6:4-6

Ọlọ́run kò ní inúdídùn sí ikú ẹni burúkú. Isk 33:11; 18:32

Ṣùgbọ́n ìfẹ́ kò lè gbójúfo àìṣòdodo dá. Heb 1:9

A ó pa àwọn ẹni burúkú run. Heb 10:26-29; Iṣi 20:7-15

19. Ìgbéyàwó

  A. Ìdè ìgbéyàwó gbọ́dọ̀ ní ọlá

A fi í wé Kristi àti ìyàwó. Ef 5:22, 23

Ibùsùn ìgbéyàwó gbọ́dọ̀ jẹ́ aláìlẹ́gbin. Heb 13:4

A fún tọkọtaya ní ìtọ́ni láti má ṣe pínyà. 1Kọ 7:10-16

Por·neiʹa nìkan ni ìdí tí ó bá Ìwé Mímọ́ mu fún ìkọ̀sílẹ̀. Mt 19:9

 B. Àwọn Kristẹni gbọ́dọ̀ bọ̀wọ̀ fún ìlànà ipò orí

Ọkọ gẹ́gẹ́ bí orí ní láti nífẹ̀ẹ́, bójútó ìdílé. Ef 5:23-31

Aya, wà ní ìtẹríba, nífẹ̀ẹ́, ṣe ìgbọràn sí ọkọ. 1Pe 3:1-7; Ef 5:22

Àwọn ọmọ ní láti jẹ́ onígbọràn. Ef 6:1-3; Kol 3:20

 D. Ẹrù iṣẹ́ àwọn Kristẹni òbí sí àwọn ọmọ

Gbọ́dọ̀ fi ìfẹ́ hàn, lo àkókò pẹ̀lú wọn, àfiyèsí. Tit 2:4

Má ṣe mú wọn bínú. Kol 3:21

Ṣe ìpèsè, títí kan àwọn ohun tẹ̀mí. 2Kọ 12:14; 1Ti 5:8

Fún wọn ní ìdánilẹ́kọ̀ọ́ fún ìyè. Ef 6:4; Owe 22:6, 15; 23:13, 14

 E. Kristẹni gbọ́dọ̀ gbé kìkì Kristẹni níyàwó

Gbéyàwó kìkì “nínú Olúwa.” 1Kọ 7:39; Di 7:3, 4; Ne 13:26

 Ẹ. Ìkóbìnrinjọ kò bá Ìwé Mímọ́ mu

Ní ìpilẹ̀ṣẹ̀, aya kan ni ọkùnrin kan gbọ́dọ̀ ní. Jẹ 2:18, 22-25

Jésù dá ọ̀pá ìdiwọ̀n yìí padà fún Kristẹni. Mt 19:3-9

Àwọn Kristẹni ìpilẹ̀ṣẹ̀ kì í ṣe akóbìnrinjọ. 1Kọ 7:2, 12-16; Ef 5:28-31

20. Ìjẹ́rìí

  A. Gbogbo Kristẹni gbọ́dọ̀ jẹ́rìí, kí wọ́n sọ ìhìn rere

A gbọ́dọ̀ jẹ́wọ́ Jésù níwájú ènìyàn láti rí ìtẹ́wọ́gbà. Mt 10:32

A gbọ́dọ̀ jẹ́ olùṣe Ọ̀rọ̀, kí a fi ìgbàgbọ́ hàn. Jak 1:22-24; 2:24

Àwọn ẹni tuntun, pẹ̀lú, ní láti di olùkọ́. Mt 28:19, 20

Ìpolongo ní gbangba ń mú ìgbàlà wá. Ro 10:10

 B. Àìní wà fún ìbẹ̀wò léraléra, ìjẹ́rìí àìdabọ̀

A gbọ́dọ̀ fúnni ní ìkìlọ̀ nípa òpin. Mt 24:14

Jeremáyà kéde òpin Jerúsálẹ́mù fún ọ̀pọ̀ ọdún. Jer 25:3

Bí àwọn Kristẹni ìjimìjí, a kò lè dáwọ́ dúró. Iṣe 4:18-20; 5:28, 29

 D. A gbọ́dọ̀ jẹ́rìí kí a lè bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀

A gbọ́dọ̀ kìlọ̀ nípa òpin tí ó sún mọ́lé. Isk 33:7; Mt 24:14

Ìkùnà mú ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wá. Isk 33:8, 9; 3:18, 19

Pọ́ọ̀lù bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀; ó sọ ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ òtítọ́. Iṣe 20:26, 27; 1Kọ 9:16

Ó ń gba ẹlẹ́rìí àti ẹni tí ń gbọ́ là. 1Ti 4:16; 1Kọ 9:22

21. Ìjọba

  A. Ohun tí Ìjọba Ọlọ́run yóò ṣe fún aráyé

Láti mú ìfẹ́ Ọlọ́run ṣẹ. Mt 6:9, 10; Sm 45:6; Iṣi 4:11

Ìjọba kan tí ó ní ọba àti àwọn òfin. Ais 9:6, 7; 2:3; Sm 72:1, 8

Yóò pa ìwà burúkú run, ṣàkóso gbogbo ilẹ̀ ayé. Da 2:44; Sm 72:8

Ẹgbẹ̀rún ọdún ìṣàkóso láti mú aráyé, Párádísè, padà bọ̀ sípò. Iṣi 21:2-4; 20:6

 B. Iṣẹ́ bẹ̀rẹ̀ nígbà tí àwọn ọ̀tá Kristi ṣì wà láàyè síbẹ̀

Lẹ́yìn tí a gbé Kristi dìde, ó dúró pẹ́. Sm 110:1; Heb 10:12, 13

Ó gba agbára, bá Sátánì jagun. Sm 110:2; Iṣi 12:7-9; Lk 10:18

A gbé Ìjọba kalẹ̀ nígbà náà, ègbé ayé tẹ̀ lé e. Iṣi 12:10, 12

Ìdààmú ìsinsìnyí túmọ̀ sí àkókò láti fara mọ́ Ìjọba náà. Iṣi 11:15-18

 D. Kì í ṣe ‘nínú ọkàn-àyà,’ a kò mú un dàgbà nípasẹ̀ ìsapá ènìyàn

Ìjọba náà ń bẹ ní ọ̀run, kì í ṣe ilẹ̀ ayé. 2Ti 4:18; 1Kọ 15:50; Sm 11:4

Kì í ṣe ‘nínú ọkàn-àyà’; Farisí ni Jésù ń bá sọ̀rọ̀. Lk 17:20, 21

Kì í ṣe apákan ayé yìí. Joh 18:36; Lk 4:5-8; Da 2:44

Yóò rọ́pò àwọn ìjọba, ọ̀pá ìdiwọ̀n ayé. Da 2:44

22. Ìjọsìn Àwọn Baba Ńlá

  A. Ìjọsìn àwọn baba ńlá jẹ́ asán

Àwọn baba ńlá ti kú, wọn kò mọ nǹkan kan. Onw 9:5, 10

Àwọn baba ńlá ìpilẹ̀ṣẹ̀ kò yẹ ní jíjọ́sìn. Ro 5:12, 14; 1Ti 2:14

Ọlọ́run ka irúfẹ́ ìjọsìn bẹ́ẹ̀ léèwọ̀. Ẹk 34:14; Mt 4:10

 B. A lè bọlá fún ẹ̀dá ènìyàn, ṣùgbọ́n Ọlọ́run nìkan ni a gbọ́dọ̀ jọ́sìn

Àwọn ọ̀dọ́ gbọ́dọ̀ bọlá fún àgbàlagbà. 1Ti 5:1, 2, 17; Ef 6:1-3

Ṣùgbọ́n Ọlọ́run nìkan ni a gbọ́dọ̀ jọ́sìn. Iṣe 10:25, 26; Iṣi 22:8, 9

23. Ìjọsìn Màríà

  A. Màríà ìyá Jésù, kì í ṣe “ìyá Ọlọ́run”

Ọlọ́run kò ní ìbẹ̀rẹ̀. Sm 90:2; 1Ti 1:17

Màríà ni ìyá Ọmọ Ọlọ́run, nínú ipò ẹ̀dá lórí ilẹ̀ ayé. Lk 1:35

 B. Màríà kì í ṣe “wúndíá títí lọ”

Ó ṣe ìgbéyàwó pẹ̀lú Jósẹ́fù. Mt 1:19, 20, 24, 25

Ó bí àwọn ọmọ mìíràn yàtọ̀ sí Jésù. Mt 13:55, 56; Lk 8:19-21

Àwọn wọ̀nyí kì í ṣe “arákùnrin rẹ̀ nípa ti ẹ̀mí” nígbà yẹn. Joh 7:3, 5

24. Ikú

  A. Okùnfà ikú

Ènìyàn ní ìbẹ̀rẹ̀ pípé, ìrètí ìyè aláìlópin. Jẹ 1:28, 31

Àìgbọràn mú ìdájọ́ ikú wá. Jẹ 2:16, 17; 3:17, 19

Ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú ti kọjá sórí gbogbo àwọn ọmọ Ádámù. Ro 5:12

 B. Ipò tí àwọn òkú wà

A dá Ádámù láti jẹ́ ọkàn kan, a kò fún un ní ọkàn. Jẹ 2:7; 1Kọ 15:45

Ènìyàn, tí í ṣe ọkàn, ni ó máa ń kú. Isk 18:4; Ais 53:12; Job 11:20

Àwọn òkú jẹ́ aláìní ìmọ̀lára, wọn kò mọ nǹkan kan. Onw 9:5, 10; Sm 146:3, 4

Àwọn òkú sùn, wọ́n ń dúró de àjíǹde. Joh 11:11-14, 23-26; Iṣe 7:60

 D. Kò ṣeé ṣe láti bá òkú sọ̀rọ̀

Àwọn òkú kò wà láàyè pẹ̀lú Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ẹ̀mí. Sm 115:17; Ais 38:18

A kìlọ̀ fúnni lòdì sí gbígbìyànjú láti bá òkú sọ̀rọ̀. Ais 8:19; Le 19:31

A-bá-iwin-gbìmọ̀, aláfọ̀ṣẹ, ni a dá lẹ́bi. Di 18:10-12; Ga 5:19-21

25. Ilẹ̀ Ayé

  A. Ète Ọlọ́run fún ilẹ̀ ayé

A dá Párádísè sórí ilẹ̀ ayé fún ẹ̀dá ènìyàn pípé. Jẹ 1:28; 2:8-15

Ète Ọlọ́run dájú. Ais 55:11; 46:10, 11

Ilẹ̀ ayé yóò kún fún ènìyàn àlàáfíà, àwọn ènìyàn pípé. Ais 45:18; Sm 72:7; Ais 9:6, 7

A óò mú Párádísè padà bọ̀ sípò nípasẹ̀ Ìjọba náà. Mt 6:9, 10; Iṣi 21:3-5

 B. A kò ní pa á run tàbí sọ ọ́ di òfo láé

Ilẹ̀ ayé gidi yóò wà títí láé. Onw 1:4; Sm 104:5

Aráyé ti ìgbà Nóà ni a pa run, kì í ṣe ilẹ̀ ayé. 2Pe 3:5-7; Jẹ 7:23

Àpẹẹrẹ ń fúnni ní ìrètí lílàájá nígbà tiwa. Mt 24:37-39

Ẹni burúkú pa run; “ogunlọ́gọ̀ ńlá” làájá. 2Tẹ 1:6-9; Iṣi 7:9, 14

26. Ìpadàbọ̀ Kristi

  A. Ẹ̀dá ènìyàn kò lè fojú rí ìpadàbọ̀ rẹ̀

Ó sọ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn pé ayé kì yóò rí òun mọ́. Joh 14:19

Kìkì ọmọ ẹ̀yìn ni ó rí ìgòkè rẹ̀; ìpadàbọ̀ bákan náà. Iṣe 1:6, 10, 11

Ní ọ̀run, ó jẹ́ ẹ̀mí tí a kò lè fojú rí. 1Ti 6:14-16; Heb 1:3

Ó padà nínú agbára Ìjọba ti ọ̀run. Da 7:13, 14

 B. A fi àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tí a lè fojú rí mọ̀ ọ́n

Àwọn ọmọ ẹ̀yìn béèrè fún àmì wíwàníhìn-ín. Mt 24:3

Àwọn Kristẹni “rí” wíwàníhìn-ín nípasẹ̀ òye. Efe 1:18

Ọ̀pọ̀ ìṣẹ̀lẹ̀ fi ẹ̀rí wíwàníhìn-ín rẹ̀ hàn. Lk 21:10, 11

Àwọn ọ̀tá “rí i” bí ìparun ti já lù wọ́n. Iṣi 1:7

27. Ìràpadà

  A. Ìwàláàyè Jésù bí ènìyàn ni a fi san “ìràpadà fún gbogbo ènìyàn”

Jésù fi ìwàláàyè rẹ̀ fúnni gẹ́gẹ́ bí ìràpadà. Mt 20:28

Ìníyelórí ẹ̀jẹ̀ tí ó ta sílẹ̀ pèsè ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀. Heb 9:14, 22

Ẹbọ kan ti tó títí láé. Ro 6:10; Heb 9:26

Àǹfààní rẹ̀ kì í ṣàdédé dé; a gbọ́dọ̀ mọyì rẹ̀. Joh 3:16

 B. Ó jẹ́ iye tí ó ṣe rẹ́gí

A dá Ádámù ní pípé. Di 32:4; Onw 7:29; Jẹ 1:31

Ó sọ ìjẹ́pípé nù fún ara rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀ nípasẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀. Ro 5:12, 18

Àwọn ọmọ di aláìní ìrànlọ́wọ́; a nílò ẹni bí Ádámù gẹ́lẹ́. Sm 49:7; Di 19:21

Ìwàláàyè Jésù bí ènìyàn pípé jẹ́ ìràpadà. 1Ti 2:5, 6; 1Pe 1:18, 19

28. Ìṣe Ìrántí, Máàsì

  A. Ṣíṣe ìrántí Oúnjẹ Alẹ́ Olúwa

A ń ṣe é lẹ́ẹ̀kan lọ́dún ní ọjọ́ Ìrékọjá. Lk 22:1, 17-20; Ẹk 12:14

A ń ṣe ìrántí ikú ìrúbọ Kristi. 1Kọ 11:26; Mt 26:28

Àwọn tí ó ní ìrètí ti ọ̀run a máa ṣàjọpín. Lk 22:29, 30; 12:32, 37

Bí ẹnì kan ṣe ń mọ̀ pé òun ní irúfẹ́ ìrètí bẹ́ẹ̀. Ro 8:15-17

 B. Máàsì kò bá Ìwé Mímọ́ mu

Ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ ń béèrè títa ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀. Heb 9:22

Kristi nìkan ni Alárinà májẹ̀mú tuntun. 1Ti 2:5, 6; Joh 14:6

Kristi ń bẹ ní ọ̀run; àlùfáà kò lè mú un sọ̀ kalẹ̀ wá. Iṣe 3:20, 21

Kò sí ìdí láti tún ẹbọ Kristi rú. Heb 9:24-26; 10:11-14

29. Ìṣẹ̀dá

  A. Ó bá ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì tòótọ́ mu; ó já ẹfolúṣọ̀n ní koro

Ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì bá ìtòlẹ́sẹẹsẹ ìṣẹ̀dá mu. Jẹ 1:11, 12, 21, 24, 25

Òótọ́ ni òfin Ọlọ́run nípa “àwọn irú.” Jẹ 1:11, 12; Jak 3:12

 B. Àwọn ọjọ́ ìṣẹ̀dá kì í ṣe ọjọ́ oníwákàtí mẹ́rìnlélógún

“Ọjọ́” lè wulẹ̀ túmọ̀ sí sáà àkókò kan. Jẹ 2:4

Ọjọ́ lọ́dọ̀ Ọlọ́run lè jẹ́ àkókò gígùn kan. Sm 90:4; 2Pe 3:8

30. Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Ọjọ́ Ìṣẹ̀lẹ̀

  A. 1914 (C.E.) ni òpin Àwọn Ìgbà Kèfèrí

Ìlà àwọn olùṣàkóso ìjọba dáwọ́ dúró, 607 B.C.E. Isk 21:25-27

“Ìgbà méje” ní láti kọjá kí a tó mú ìṣàkóso padà. Da 4:32, 16, 17

Méje jẹ́ 31/2 lọ́nà méjì, tàbí 1,260 ọjọ́ lọ́nà méjì. Iṣi 12:6, 14; 11:2, 3

Ọjọ́ kan fún ọdún kan. [Ó jẹ́ 2,520 ọdún] Isk 4:6; Nu 14:34

Yóò máa bá a lọ títí di ìgbà ìgbékalẹ̀ Ìjọba. Lk 21:24; Da 7:13, 14

31. Ìwà Burúkú, Wàhálà Ayé

  A. Ẹni tí ó ń fa wàhálà ayé

Ìṣàkóso burúkú ni ó ń fa àìfararọ òde òní. Owe 29:2; 28:28

Olùṣàkóso ayé jẹ́ ọ̀tá Ọlọ́run. 2Kọ 4:4; 1Jo 5:19; Joh 12:31

Èṣù ni ó ń mú ègbé wá, àkókò rẹ̀ kúrú. Iṣi 12:9, 12

A ó de Èṣù, àlàáfíà ológo yóò tẹ̀ lé e. Iṣi 20:1-3; 21:3, 4

 B. Ìdí tí a fi fàyè gba ìwà burúkú

Èṣù pe ìdúróṣinṣin ẹ̀dá sí Ọlọ́run níjà. Job 1:11, 12

A fún olùṣòtítọ́ ní àǹfààní láti fi ìdúróṣinṣin hàn. Ro 9:17; Owe 27:11

A fi Èṣù hàn ní òpùrọ́, a ó yanjú àríyànjiyàn. Joh 12:31

A ó fi ìyè àìnípẹ̀kun ṣe èrè fún olùṣòtítọ́. Ro 2:6, 7; Iṣi 21:3-5

 D. Àkókò òpin tí a fà gùn jẹ́ ìpèsè aláàánú

Bí ti ọjọ́ Nóà, ó gba àkókò láti ṣe ìkìlọ̀. Mt 24:14, 37-39

Ọlọ́run kò fi nǹkan falẹ̀, ṣùgbọ́n ó láàánú. 2Pe 3:9; Ais 30:18

Bíbélì ràn wá lọ́wọ́ kí ó má bàa bá wa lójijì. Lk 21:36; 1Te 5:4

Wá ìpèsè Ọlọ́run nísinsìnyí fún ààbò. Ais 2:2-4; Sef 2:3

 E. Àtúnṣe sí wàhálà ayé kì í ṣe láti ọwọ́ ènìyàn

Ènìyàn ń bẹ̀rù, wọ́n ń dààmú gidigidi. Lk 21:10, 11; 2Ti 3:1-5

Ìjọba Ọlọ́run ni yóò ṣe àṣeyọrí sí rere, kì í ṣe ènìyàn. Da 2:44; Mt 6:10

Láti wà láàyè, wá àlàáfíà pẹ̀lú Ọba náà nísinsìnyí. Sm 2:9, 11, 12

32. Ìwòsàn, Àwọn Ahọ́n Àjèjì

  A. Ìwòsàn tẹ̀mí ní àwọn àǹfààní wíwàpẹ́títí

Àìsàn tẹ̀mí ń pani run. Ais 1:4-6; 6:10; Ho 4:6

Ìwòsàn tẹ̀mí ni iṣẹ́ pàtàkì tí a fi ránni. Joh 6:63; Lk 4:18

Ó ń mú ẹ̀ṣẹ̀ kúrò; ó ń fúnni láyọ̀, ìyè. Jak 5:19, 20; Iṣi 7:14-17

 B. Ìjọba Ọlọ́run yóò mú ìwòsàn ti ara wíwàpẹ́títí wá

Jésù wo àwọn àrùn sàn, ó wàásù ìbùkún Ìjọba náà. Mt 4:23

Ìjọba náà ni a ṣèlérí bí ohun àmúlò fún ìwòsàn wíwàpẹ́títí. Mt 6:10; Ais 9:7

Ikú pàápàá ni a óò mú kúrò. 1Kọ 15:25, 26; Iṣi 21:4; 20:14

 D. Ìgbàgbọ́ wò-ó-sàn òde òní kò ní ẹ̀rí ìfọwọ́sí àtọ̀runwá

Àwọn ọmọ ẹ̀yìn kò wo ara wọn sàn lọ́nà ìyanu. 2Kọ 12:7-9; 1Ti 5:23

Ẹ̀bùn iṣẹ́ ìyanu dópin lẹ́yìn ọjọ́ àwọn àpọ́sítélì. 1Kọ 13:8-11

Ìwòsàn kì í ṣe ẹ̀rí dídájú fún ojú rere Ọlọ́run. Mt 7:22, 23; 2Tẹ 2:9-11

 E. Sísọ̀rọ̀ ní àwọn ahọ́n àjèjì jẹ́ ìpèsè onígbà kúkúrú

Ó jẹ́ àmì; ẹ̀bùn títóbi jù ni a ní láti wá. 1Kọ 14:22; 12:30, 31

Ẹ̀bùn ẹ̀mí lọ́nà iṣẹ́ ìyanu ni a sọ tẹ́lẹ̀ pé yóò kọjá lọ. 1Kọ 13:8-10

Iṣẹ́ ìyanu kì í ṣe ẹ̀rí dídájú fún ojú rere Ọlọ́run. Mt 7:22, 23; 24:24

33. Ìyè

  A. Ìyè àìnípẹ̀kun ni a mú dájú fún aráyé onígbọràn

Ọlọ́run, ẹni tí kò lè purọ́, ti ṣèlérí ìyè. Tit 1:2; Joh 10:27, 28

Ìyè ayérayé ni a mú dájú fún àwọn tí ń lo ìgbàgbọ́. Joh 11:25, 26

A ó pa ikú run. 1Kọ 15:26; Iṣi 21:4; 20:14; Ais 25:8

 B. Ìyè ti ọ̀run ni a fi mọ sọ́dọ̀ àwọn tí ó wà nínú ara Kristi

Ọlọ́run yan àwọn mẹ́ńbà bí ó ti wù ú. Mt 20:23; 1Kọ 12:18

Kìkì 144,000 ni a mú láti orí ilẹ̀ ayé. Iṣi 14:1, 4; 7:2-4; 5:9, 10

Àní Jòhánù Oníbàtisí pàápàá kì yóò sí nínú Ìjọba ọ̀run. Mt 11:11

 D. Ìyè lórí ilẹ̀ ayé ni a ṣèlérí fún àìníye ènìyàn, “àwọn àgùntàn mìíràn”

Iye kéréje yóò wà pẹ̀lú Jésù ní ọ̀run. Iṣi 14:1, 4; 7:2-4

“Àwọn àgùntàn mìíràn” kì í ṣe arákùnrin Kristi. Joh 10:16; Mt 25:32, 40

Ọ̀pọ̀ ènìyàn ń kórajọ nísinsìnyí fún lílàájá lórí ilẹ̀ ayé. Iṣi 7:9, 15-17

A óò jí àwọn mìíràn dìde fún ìyè lórí ilẹ̀ ayé. Iṣi 20:12; 21:4

34. Jèhófà, Ọlọ́run

  A. Orúkọ Ọlọ́run

“Ọlọ́run” kì í ṣe orúkọ pàtó; Olúwa wa ní orúkọ tirẹ̀. 1Kọ 8:5, 6

A ń gbàdúrà fún ìsọdimímọ́ orúkọ rẹ̀. Mt 6:9, 10

Jèhófà ni orúkọ Ọlọ́run. Sm 83:18; Ẹk 6:2, 3; 3:15; Ais 42:8

Orúkọ náà wà nínú KJ. Ẹk 6:3 (Dy àlàyé etí ìwé). Sm 83:18; Ais 12:2; 26:4

Jésù sọ orúkọ náà di mímọ̀. Joh 17:6, 26; 5:43; 12:12, 13, 28

 B. Wíwà Ọlọ́run

Kò ṣeé ṣe láti rí Ọlọ́run kí a sì yè. Ẹk 33:20; Joh 1:18; 1Jo 4:12

Kò sí ìdí láti rí Ọlọ́run kí a tó lè gbà gbọ́. Heb 11:1; Ro 8:24, 25; 10:17

A mọ Ọlọ́run nípasẹ̀ àwọn iṣẹ́ rẹ̀ tí a fojú rí. Ro 1:20; Sm 19:1, 2

Ìmúṣẹ àsọtẹ́lẹ̀ fi hàn pé Ọlọ́run wà. Ais 46:8-11

 D. Àwọn ànímọ́ Ọlọ́run

Ọlọ́run jẹ́ ìfẹ́. 1Jo 4:8, 16; Ẹk 34:6; 2Kọ 13:11; Mik 7:18

Ó tayọ nínú ọgbọ́n. Job 12:13; Ro 11:33; 1Kọ 2:7

Olódodo, a máa ṣe ìdájọ́ òdodo. Di 32:4; Sm 37:28

Ó jẹ́ Olódùmarè, ó ní agbára gbogbo. Job 37:23; Iṣi 7:12; 4:11

 E. Kì í ṣe gbogbo ènìyàn ni ń sin Ọlọ́run kan náà

Ọ̀nà tí ó dára lójú kì í fi ìgbà gbogbo tọ̀nà. Owe 16:25; Mt 7:21

Ọ̀nà méjì, ọ̀kanṣoṣo ni ó lọ sí ìyè. Mt 7:13, 14; Di 30:19

Ọ̀pọ̀ ọlọ́run ṣùgbọ́n Ọlọ́run tòótọ́ kan ṣoṣo. 1Kọ 8:5, 6; Sm 82:1

Mímọ Ọlọ́run tòótọ́ ṣe kókó fún ìyè. Joh 17:3; 1Jo 5:20

35. Jésù

  A. Jésù jẹ́ Ọmọ Ọlọ́run àti Ọba tí a yàn

Àkọ́bí Ọlọ́run, ó dá ohun gbogbo. Iṣi 3:14; Kol 1:15-17

A ṣe é ní ènìyàn tí a bí nípasẹ̀ obìnrin, ó rẹlẹ̀ ju áńgẹ́lì. Ga 4:4; Heb 2:9

A fi ẹ̀mí Ọlọ́run bí i, pẹ̀lú ìpín ní ọ̀run. Mt 3:16, 17

A gbé e ga ju bí ó ti wà ṣáájú kí ó tó di ènìyàn. Flp 2:9, 10

 B. Ìgbàgbọ́ nínú Jésù Kristi ṣe kókó fún ìgbàlà

Kristi ni Irú-Ọmọ Ábúráhámù tí a ṣèlérí. Jẹ 22:18; Ga 3:16

Jésù nìkan ni Àlùfáà Àgbà, ìràpadà. 1Jo 2:1, 2; Heb 7:25, 26; Mt 20:28

Ìyè nípasẹ̀ mímọ Ọlọ́run àti Kristi, ìgbọràn. Joh 17:3; Iṣe 4:12

 D. Ohun tí a ń béèrè ju wíwulẹ̀ gba Jésù gbọ́

Iṣẹ́ gbọ́dọ̀ bá ìgbàgbọ́ rìn. Jak 2:17-26; 1:22-25

A ní láti ṣègbọràn sí àwọn àṣẹ, ṣe iṣẹ́ tí ó ṣe. Joh 14:12, 15; 1Jo 2:3

Kì í ṣe gbogbo ẹni tí ń lo orúkọ Olúwa ni yóò wọ Ìjọba náà. Mt 7:21-23

36. Mẹ́talọ́kan

  A. Ọlọ́run, Baba náà, Ẹnì kan, tí ó tóbi jù lọ ní àgbáyé

Ọlọ́run kì í ṣe ẹni mẹ́ta. Di 6:4; Mal 2:10; Mk 10:18; Ro 3:29, 30

A dá Ọmọ; Ọlọ́run nìkan ni ó wà ṣáájú. Iṣi 3:14; Kol 1:15; Ais 44:6

Ọlọ́run ni olùṣàkóso àgbáyé nígbà gbogbo. Flp 2:5, 6; Da 4:35

A ní láti gbé Ọlọ́run ga lékè ohun gbogbo. Flp 2:10, 11

 B. Ọmọ rẹlẹ̀ sí Baba ṣáájú àti lẹ́yìn wíwá sí ilẹ̀ ayé

Ọmọ ṣe ìgbọràn ní ọ̀run, Baba ni ó rán an. Joh 8:42; 12:49

Ó ṣe ìgbọràn lórí ilẹ̀ ayé, Baba tóbi jù ú lọ. Joh 14:28; 5:19; Heb 5:8

A gbé e ga ní ọ̀run, síbẹ̀ ó tẹríba. Flp 2:9; 1Kọ 15:28; Mt 20:23

Jèhófà ni orí àti Ọlọ́run Kristi. 1Kọ 11:3; Joh 20:17; Iṣi 1:6

 D. Jíjẹ́ ọ̀kan Ọlọ́run àti Kristi

Ìgbà gbogbo ni wọ́n máa ń wà ní ìṣọ̀kan pípé. Joh 8:28, 29; 14:10

Jíjẹ́ ọ̀kan, bí ti ọkọ àti aya. Joh 10:30; Mt 19:4-6

Gbogbo onígbàgbọ́ gbọ́dọ̀ ní ìṣọ̀kan kan náà. Joh 17:20-22; 1Kọ 1:10

Ìjọsìn kan ṣoṣo ti Jèhófà nípasẹ̀ Kristi títí láé. Joh 4:23, 24

 E. Ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run ni ipá agbéṣẹ́ṣe rẹ̀

Ipá kan ni, kì í ṣe ẹnì kan. Mt 3:16; Joh 20:22; Iṣe 2:4, 17, 33

Kì í ṣe ẹnì kan ní ọ̀run pẹ̀lú Ọlọ́run àti Kristi. Iṣe 7:55, 56; Iṣi 7:10

Ọlọ́run ń darí rẹ̀ láti mú àwọn ète rẹ̀ ṣẹ. Sm 104:30; 1Kọ 12:4-11

Àwọn olùsin Ọlọ́run ń rí i gbà, a fi ń darí wọn. 1Kọ 2:12, 13; Ga 5:16

37. Òjíṣẹ́

  A. Gbogbo Kristẹni gbọ́dọ̀ jẹ́ òjíṣẹ́

Jésù jẹ́ òjíṣẹ́ Ọlọ́run. Ro 15:8, 9; Mt 20:28

Àwọn Kristẹni ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ rẹ̀. 1Pe 2:21; 1Kọ 11:1

A gbọ́dọ̀ wàásù láti ṣàṣeparí iṣẹ́ òjíṣẹ́ náà. 2Ti 4:2, 5; 1Kọ 9:16

 B. Àwọn ẹ̀rí ìtóótun fún iṣẹ́ òjíṣẹ́ náà

Ẹ̀mí Ọlọ́run àti ìmọ̀ Ọ̀rọ̀ rẹ̀. 2Ti 2:15; Ais 61:1-3

Tẹ̀ lé àwòkọ́ṣe Kristi ní wíwàásù. 1Pe 2:21; 2Ti 4:2, 5

Ọlọ́run ń dáni lẹ́kọ̀ọ́ nípasẹ̀ ẹ̀mí, ètò. Joh 14:26; 2Kọ 3:1-3

38. Ọjọ́ Àjọ̀dún, Ọjọ́ Ìbí

  A. Ọjọ́ ìbí, Kérésìmesì, ni àwọn Kristẹni ìjímìjí kò ṣe

Àwọn tí kì í ṣe olùjọsìn tòótọ́ ni ó ń ṣe é. Jẹ 40:20; Mt 14:6

Ọjọ́ ikú Jésù ni a ní láti máa rántí. Lk 22:19, 20; 1Kọ 11:25, 26

Àríyá aláriwo àjọ̀dún kò tọ̀nà. Ro 13:13; Ga 5:21; 1Pe 4:3

39. Ọjọ́ Ìkẹyìn

  A. Ohun tí “òpin ayé” túmọ̀ sí

Ògógóró ètò àwọn nǹkan. Mt 24:3; 2Pe 3:5-7; Mk 13:4

Kì í ṣe òpin ilẹ̀ ayé, bí kò ṣe ti ètò burúkú. 1Jo 2:17

Àkókò òpin wà ṣáájú ìparun. Mt 24:14

Àsálà fún olódodo; Ayé Tuntun tẹ̀ lé e. 2Pe 2:9; Iṣi 7:14-17

 B. Àìní wà fún wíwà lójúfò sí àwọn àmì ọjọ́ ìkẹyìn

Ọlọ́run pèsè àwọn àmì fún ìtọ́sọ́nà wa. 2Ti 3:1-5; 1Tẹ 5:1-4

Ayé kùnà láti mọ ìjẹ́pàtàkì rẹ̀. 2Pe 3:3, 4, 7; Mt 24:39

Ọlọ́run kò fi nǹkan falẹ̀, ṣùgbọ́n ó ń fúnni ní ìkìlọ̀. 2Pe 3:9

Èrè fún wíwà lójúfò, bíbìkítà. Lk 21:34-36

40. Ọkàn

  A. Ohun tí ọkàn jẹ́

Ènìyàn jẹ́ ọkàn. Jẹ 2:7; 1Kọ 15:45; Joṣ 11:11; Iṣe 27:37

A pe àwọn ẹranko pẹ̀lú ní ọkàn. Nu 31:28; Iṣi 16:3; Le 24:18

Ọkàn ní ẹ̀jẹ̀, ó máa ń jẹun, ó lè kú. Jer 2:34; Le 7:18; Isk 18:4

A máa ń sọ pé ènìyàn ní ọkàn, nítorí pé ó ní ìwàláàyè. Mk 8:36; Joh 10:15

 B. Ìyàtọ̀ tí ó wà láàárín ọkàn àti ẹ̀mí

Ìwàláàyè gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tàbí ẹ̀dá jẹ́ ọkàn. Joh 10:15; Le 17:11

Ipá ìwàláàyè tí ń mú ọkàn ṣiṣẹ́ ni a ń pè ní “ẹ̀mí.” Sm 146:4; 104:29

Nígbà tí ènìyàn bá kú, àkóso ipá ìwàláàyè padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run. Onw 12:7

Ọlọ́run nìkan ni ó lè mú ipá ìwàláàyè ṣiṣẹ́. Isk 37:12-14

41. Ọ̀run

  A. Kìkì 144,000 ní ń lọ sí ọ̀run

Díẹ̀; láti jẹ ọba pẹ̀lú Kristi. Iṣi 5:9, 10; 20:4

Jésù ni aṣáájú; a yan àwọn mìíràn lẹ́yìn náà. Kol 1:18; 1Pe 2:21

Ọ̀pọ̀ àwọn mìíràn yóò gbé orí ilẹ̀ ayé. Sm 72:8; Iṣi 21:3, 4

144,000 wà ní ipò pàtàkì tí àwọn mìíràn kò ní. Iṣi 14:1, 3; 7:4, 9

42. Sábáàtì

  A. Ọjọ́ Sábáàtì kò de àwọn Kristẹni

A mú Òfin kúrò lórí ìpìlẹ̀ ikú Jésù. Ef 2:15

Sábáàtì kò de àwọn Kristẹni. Kol 2:16, 17; Ro 14:5, 10

A bá wọn wí fún pípa Sábáàtì mọ́, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Ga 4:9-11; Ro 10:2-4

Wọ́n wọ inú ìsinmi Ọlọ́run nípasẹ̀ ìgbàgbọ́ àti ìgbọràn. Heb 4:9-11

 B. Ísírẹ́lì ìgbàanì nìkan ni a béèrè pé kí ó pa Sábáàtì mọ́

Ẹ̀yìn Ìjádelọ ni a kọ́kọ́ pa Sábáàtì mọ́. Ẹk 16:26, 27, 29, 30

Ó jẹ́ fún kìkì Ísírẹ́lì ti ara bí àmì. Ẹk 31:16, 17; Sm 147:19, 20

Àwọn ọdún Sábáàtì ni a béèrè fún lábẹ́ Òfin pẹ̀lú. Ẹk 23:10, 11; Le 25:3, 4

Sábáàtì kì í ṣe ọ̀ranyàn fún Kristẹni. Ro 14:5, 10; Ga 4:9-11

 D. Sábáàtì ìsinmi Ọlọ́run (ọjọ́ keje “ọ̀sẹ̀” ìṣẹ̀dá)

Ó bẹ̀rẹ̀ ní òpin ìṣẹ̀dá orí ilẹ̀ ayé. Jẹ 2:2, 3; Heb 4:3-5

Ó wà títí kọjá ọjọ́ Jésù lórí ilẹ̀ ayé. Heb 4:6-8; Sm 95:7-9, 11

Àwọn Kristẹni sinmi kúrò nínú iṣẹ́ ìmọtara-ẹni-nìkan. Heb 4:9, 10

Yóò dópin nígbà tí Ìjọba náà bá parí iṣẹ́ nípa ilẹ̀ ayé. 1Kọ 15:24, 28

43. Ṣọ́ọ̀ṣì

  A. Ṣọ́ọ̀ṣì jẹ́ ti ẹ̀mí, a kọ́ ọ lé orí Kristi

Ọlọ́run kì í gbé tẹ́ńpìlì tí a fi ọwọ́ ènìyàn kọ́. Iṣe 17:24, 25; 7:48

Ṣọ́ọ̀ṣì tòótọ́ jẹ́ tẹ́ńpìlì ti ẹ̀mí ti àwọn òkúta ààyè. 1Pe 2:5, 6

Kristi, òkúta igun ilé; àwọn àpọ́sítélì, ìpìlẹ̀ onípò kejì. Ef 2:20

A ní láti sin Ọlọ́run ní ẹ̀mí àti ní òtítọ́. Joh 4:24

 B. A kò kọ́ ṣọ́ọ̀ṣì sórí Pétérù

Jésù kò sọ pé a kọ́ ṣọ́ọ̀ṣì sórí Pétérù. Mt 16:18

A fi hàn pé Jésù ni “àpáta ràbàtà” náà. 1Kọ 10:4

Pétérù fi hàn pé Jésù ni ìpìlẹ̀. 1Pe 2:4, 6-8; Iṣe 4:8-12

44. Wòlíì Èké

  A. A sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa àwọn wòlíì èké; wọ́n wà nígbà ayé àwọn àpọ́sítélì

Ìlànà fún mímọ àwọn wòlíì èké. Di 18:20-22; Lk 6:26

A sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; èso wọn ni a ó fi mọ̀ wọ́n. Mt 24:23-26; 7:15-23