Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Àwọn Èèyàn Ọlọ́run Padà Sí Ilẹ̀ Wọn

Àwọn Èèyàn Ọlọ́run Padà Sí Ilẹ̀ Wọn

Ọ̀WỌ́ àwọn òkè ńláńlá méjì pàtàkì ló yí ilẹ̀ olókè tó tẹ́jú tá a mọ̀ sí orílẹ̀-èdè Ìráànì lónìí ká, ìyẹn ni, ọ̀wọ́ àwọn òkè Ẹ́líbọ́sì (tó wà ní gúúsù Òkun Kásípíà) àti ọ̀wọ́ àwọn òkè Ságírósì (tó wà ní gúúsù ìlà oòrùn ibi tí òkun ti ya wọ ilẹ̀ Páṣíà). Àwọn àfonífojì gígùn tó jẹ́ ilẹ̀ ọlọ́ràá tó sì ní àwọn gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ tí koríko bò ló là wọ́n láàárín. Ojú ọjọ́ máa ń dára gan-an láwọn àfonífojì wọ̀nyí, àmọ́ láwọn apá ibí gíga, tó gbẹ táútáú, tí afẹ́fẹ́ sì máa ń gbá mọ́ féfé, ojú ọjọ́ máa ń tútù gan-an nígbà òtútù. Ìtòsí ibí ni aṣálẹ̀ tó jẹ́ ilẹ̀ olókè tó tẹ́jú wà, níbi tí èèyàn kò fi bẹ́ẹ̀ pọ̀ sí. Àgbègbè tó fẹ̀ lọ rabidun yìí, ní apá ìlà oòrùn Mesopotámíà, ni Ilẹ̀ Ọba Mídíà òun Páṣíà ti jáde wá.

Apá àríwá ilẹ̀ olókè tó tẹ́jú yìí ni àwọn ará Mídíà fìdí kalẹ̀ sí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé nígbà tó yá, wọ́n tàn dé Àméníà àti Sìlíṣíà. Àmọ́ àwọn ará Páṣíà ní tiwọn wà ní apá gúúsù ilẹ̀ olókè títẹ́jú náà, ìyẹn ìhà ìlà oòrùn Àfonífojì Tígírísì. Nígbà ìṣàkóso Kírúsì, ní ìlàjì ọ̀rúndún kẹfà ṣááju Sànmánì Tiwa, àwọn ìjọba méjèèjì yìí para pọ̀, wọ́n sì di Agbára Ayé Mídíà òun Páṣíà.

Lọ́dún 539 ṣááju Sànmánì Tiwa, Kírúsì ṣẹ́gun Bábílónì. Ilẹ̀ ọba rẹ̀ sì nasẹ̀ dé ilẹ̀ Íńdíà níhà ìlà oòrùn. Lápá ìwọ̀ oòrùn, ó nasẹ̀ dé ilẹ̀ Íjíbítì àti ibi tó wá di ilẹ̀ Tọ́kì lónìí. Ó wá bá a mu gẹ́lẹ́ bí Dáníẹ́lì ṣe ṣàpèjúwe Ilẹ̀ Ọba Mídíà òun Páṣíà gẹ́gẹ́ bí “béárì” arebipa tó “jẹ ẹran púpọ̀.” (Da 7:5) Ìṣàkóso Kírúsì jẹ́ ìṣàkóso aláàánú tó sì ń gba nǹkan mọ́ra. Ó pín ilẹ̀ ọba náà sí ẹlẹ́kùnjẹkùn. Gómìnà kan ló ń ṣàkóso ẹkùn kan, lọ́pọ̀ ìgbà, ó máa ń jẹ́ ará Páṣíà, àmọ́ àwọn baálẹ̀ táwọn náà ní agbára díẹ̀ níkàáwọ́ máa ń wà lábẹ́ rẹ̀. Wọ́n yọ̀ǹda fún àwọn èèyàn tí wọ́n wà ní ilẹ̀ ọba náà kí wọ́n máa bá àṣà ìṣẹ̀dálẹ̀ àti ìsìn wọn lọ.

Ìlànà yìí ni Kírúsì tẹ̀ lé tó fi gba àwọn Júù láyè láti padà sí Jerúsálẹ́mù láti lọ mú ìjọsìn tòótọ́ bọ̀ sípò, kí wọ́n sì tún Jerúsálẹ́mù kọ́, gẹ́gẹ́ bí Ẹ́sírà àti Nehemáyà ṣe fi hàn. Ǹjẹ́ o rò pé ọ̀nà tí Ábúráhámù gbà láti Yúfírétì wá sí Kákémíṣì ni àwùjọ ńlá yìí gbà padà, àbí ó ṣeé ṣe kó jẹ́ ọ̀nà Tádímórì àti Damásíkù tí kò fi bẹ́ẹ̀ jìnnà ni wọ́n gbà? Bíbélì kò sọ. (Wo ojú ìwé 6 àti 7.) Bí àkókò ti ń lọ, àwọn Júù tún tẹ̀ dó sí àwọn apá ibòmíràn ní ilẹ̀ ọba náà, irú bí àgbègbè tí odò Náílì ti wọnú òkun àti láwọn apá ìkangun gúúsù lọ́hùn-ún. Àwọn Júù tí kò fi Bábílónì sílẹ̀ pọ̀ díẹ̀, ó sì ṣeé ṣe kó jẹ́ pé èyí ni ìdí tí àpọ́sítélì Pétérù fi ṣèbẹ̀wò síbẹ̀ ní ọ̀pọ̀ ọ̀rúndún lẹ́yìn ìgbà náà. (1Pe 5:13) Dájúdájú, kékeré kọ́ ni Ilẹ̀ Ọba Mídíà òun Páṣíà ṣe nínú báwọn Júù ṣe dẹni tí kò gbé lójú kan mọ́ lákòókò ìjọba Gíríìsì àti Róòmù, tí wọ́n di agbára ayé lẹ́yìn náà.

Lẹ́yìn tí àwọn ará Mídíà àti Páṣíà ṣẹ́gun ilẹ̀ Bábílónì, níbi tí ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn ti máa ń móoru gan-an, wọ́n sọ ìlú náà di ibùjókòó ìṣètò ìlú. Ṣúṣánì, tó ti jẹ́ olú ìlú Élámù nígbà kan rí wà lára àwọn ìlú tó jẹ́ ìlú ọba. Ìlú yìí ni Ahasuwérúsì Ọba Páṣíà náà, (tó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé òun ni Sásítà Kìíní) ti fi Ẹ́sítérì ṣe ayaba rẹ̀ nígbà kan rí tó sì fọ́ ètekéte kan láti pa àwọn èèyàn Ọlọ́run yán-án-yán jákèjádò ilẹ̀ ọba gbígbòòrò yẹn. Àwọn olú ìlú méjì mìíràn tó tún wà ní Mídíà òun Páṣíà ni Ekibátánà (tó wà ní àgbègbè tó ga tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀wá [1,900] mítà, tí ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn rẹ̀ sì máa ń gbádùn mọ́ni). Bákan náà ni Paságedì, (tí òun náà jẹ́ àgbègbè gíga bákan náà. Nǹkan bí àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta [650] kìlómítà ni síhà gúúsù ìlà oòrùn).

Báwo ni agbára ayé yẹn ṣe dópin? Nígbà tí Mídíà òun Páṣíà wà ní òtéńté agbára rẹ̀, ó gbìyànjú láti paná ọ̀tẹ̀ tí àwọn Gíríìkì gbé dìde níhà àríwá ilẹ̀ ọba náà. Ní àkókò yìí, ilẹ̀ Gírísì pín sí ẹkùn ìlú mẹ́rin tí wọ́n ń dá ìjọba ara wọn ṣe, tí wọ́n sì jẹ́ arógunyọ̀. Àmọ́ àwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin para pọ̀ láti ṣẹ́gun àwọn agbo ọmọ ogun Páṣíà nínú ogun àjàkú-akátá tó wáyé ní ìlú Márátọ̀n àti Sálámísì. Èyí ló pilẹ̀ bí ilẹ̀ Gíríìsì, tó ti dọ̀kan, ṣe wá gborí mọ́ Mídíà òun Páṣíà lọ́wọ́.

[Àwòrán ilẹ̀ tó wà ní ojú ìwé 24]

(Láti rí bá a ṣe to ọ̀rọ̀ sójú ìwé, wo ìtẹ̀jáde náà gan-an)

Ilẹ̀ Ọba Mídíà òun Páṣíà

A2 MAKEDÓNÍÀ

A2 TÍRÉSÌ

A4 Kírénè

A4 LÍBÍÀ

B2 Bìsáńṣíọ̀mù

B2 LÌDÍÀ

B3 Sádísì

B4 Mémúfísì (Nófì)

B4 ÍJÍBÍTÌ

B5 No-ámónì (Tíbésì)

B5 Síénè

D3 SÌLÍṢÍÀ

D3 Tásù

D3 Ísọ́sì

D3 Kákémíṣì

D3 Tádímórì

D3 SÍRÍÀ

D3 Sídónì

D3 Damásíkù

D3 Tírè

D4 Jerúsálẹ́mù

E2 Fásísì

E2 ÀMÉNÍÀ

E3 ÁSÍRÍÀ

E3 Nínéfè

E4 Bábílónì

Ẹ3 MÍDÍÀ

Ẹ3 Ekibátánà (Akimétà)

Ẹ3 HAIRIKÁNÍÀ

Ẹ4 Ṣúṣánì (Súsà)

Ẹ4 ÉLÁMÙ

Ẹ4 Paságedì

Ẹ4 Pasẹpólíìsì

Ẹ4 PÁṢÍÀ

F3 PÁTÍÀ

F4 DIRANGÍÁNÀ

G2 Marakáńdà (Samakáńdì)

G3 SOGIDÍÁNÀ

G3 BÁKÍTÍRÍÀ

G3 ÁRÍÀ

G4 ARAKÓṢÍÀ

G4 GEDIRÓSÍÀ

GB5 ÍŃDÍÀ

[Àwọn ìbòmíì]

A2 GÍRÍÌSÌ

A3 Márátọ̀n

A3 Áténì

A3 Sálámísì

D1 SÍKÍTÍÀ

D4 Élátì (Élótì)

D4 Témà

E4 ARÉBÍÀ

[Àwọn Òkè]

Ẹ3 ÒKÈ Ẹ́LÍBỌ́SÌ

Ẹ4 ÒKÈ SÁGÍRÓSÌ

[Omi]

B3 Òkun Mẹditaréníà (Òkun Ńlá)

D2 Òkun Dúdú

D5 Òkun Pupa

Ẹ2 Òkun Kásípíà

Ẹ4 Ibi Tí Òkun Ti Ya Wọ Ilẹ̀ Páṣíà

[Odò]

B4 Náílì

D3 Yúfírétì

E3 Tígírísì

GB4 Íńdọ́sì

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 24]

Àwọn ọmọ ogun Kírúsì ní láti gba àwọn Òkè Ságírósì kọjá kí wọ́n tó ó lè dé Bábílónì

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 25]

Òkè: Ọ̀nà Àbáwọlé Gbogbo Àwọn Orílẹ̀-Èdè ní Pasẹpólíìsì

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 25]

Inú Àkámọ́: Sàréè Kírúsì ní Paságedì