Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ẹ̀sìn Kristẹni Gbilẹ̀ Dé Àwọn Orílẹ̀-èdè Mìíràn

Ẹ̀sìn Kristẹni Gbilẹ̀ Dé Àwọn Orílẹ̀-èdè Mìíràn

ORÍ Òkè Ólífì lẹ́bàá Bẹ́tánì ni Jésù ti gbé iṣẹ́ ìwàásù kan tí yóò yí ayé padà lé àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ lọ́wọ́. Iṣẹ́ ìwàásù náà á bẹ̀rẹ̀ ní Jerúsálẹ́mù, tó wà ní nǹkan bíi kìlómítà mẹ́ta síhà ìwọ̀ oòrùn Òkè Ólífì. Àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ á mú ọ̀rọ̀ ìhìn rere náà dé Jùdíà àti Samáríà nítòsí, lẹ́yìn náà, ní kẹ̀rẹ̀kẹ̀rẹ̀ yóò dé “apá ibi jíjìnnà jù lọ ní ilẹ̀ ayé.”—Iṣe 1:4, 8, 12.

Láìpẹ́ lẹ́yìn tí Jésù sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyẹn, Àjọyọ̀ Pẹ́ńtíkọ́sì mú kí àwọn Júù àti àwọn aláwọ̀ṣe jákèjádò Ilẹ̀ Ọba Róòmù kóra jọ sí Jerúsálẹ́mù láti àwọn àgbègbè tí a fi hàn lórí àwòrán tó wà nísàlẹ̀ àpilẹ̀kọ yìí. Ìwàásù tí àpọ́sítélì Pétérù ṣe fún wọn lọ́jọ́ yẹn mú kí ó tètè ṣeé ṣe fún ẹ̀sìn Kristẹni láti gbilẹ̀ kíákíá.—Iṣe 2:9-11.

Kò pẹ́ púpọ̀ tí inúnibíni fi tú àwọn ọmọlẹ́yìn Kristi ká ní Jerúsálẹ́mù. Pétérù àti Jòhánù wà lára àwọn tó ran àwọn ará Samáríà lọ́wọ́ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ ìhìn rere kí wọ́n sì tẹ́wọ́ gbà á. (Iṣe 8:1, 4, 14-16) Lẹ́yìn tí Fílípì jẹ́rìí fún ará Etiópíà kan lójú ọ̀nà aṣálẹ̀ tó dà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ “láti Jerúsálẹ́mù lọ sí Gásà,” ẹ̀sìn Kristẹni gbilẹ̀ dé Áfíríkà. (Iṣe 8:26-39) Ó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ pé àkókò yìí ni ìhìn rere náà tún sèso ní Lídà, tó wà ní Pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ṣárónì, àti ní èbúté ti Jópà. (Iṣe 9:35, 42) Láti ibẹ̀, Pétérù kọjá lọ sí Kesaréà ó sì ran Kọ̀nílíù, ọ̀gá ọmọ ogun Róòmù, àwọn ìbátan rẹ̀ àti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ láti di Kristẹni tí a fẹ̀mí yàn.—Iṣe 10:1-48.

Pọ́ọ̀lù, tó ti ń fìgbà kan rí ṣenúnibíni sí àwọn Kristẹni, di àpọ́sítélì fún àwọn orílẹ̀-èdè. Ó rìnrìn àjò lórí ilẹ̀ àti lórí òkun nígbà ìrìn àjò míṣọ́nnárì mẹ́tẹ̀ẹ̀ta àti ìrìn àjò tó rìn lójú òkun lọ sí Róòmù. Àwọn àpọ́sítélì àti àwọn mìíràn tan ìhìn rere náà kálẹ̀ dé àwọn apá ibi tó pọ̀ ní Ilẹ̀ Ọba Róòmù. Pọ́ọ̀lù ní in lọ́kàn láti dé Sípéènì. (Wo ojú ìwé 2.) Pétérù sì rìn jìnnà dé ìyànníyàn Bábílónì níhà ìlà oòrùn. (1Pe 5:13) Lóòótọ́, àwọn ọmọlẹ́yìn Kristi tan ẹ̀sìn Kristẹni kálẹ̀ dé àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn lábẹ́ ìdarí tó múná dóko látọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn. Nígbà tó fi máa di ọdún 60 sí 61 Sànmánì Tiwa, ‘a ti wàásù ìhìn rere náà nínú gbogbo ìṣẹ̀dá tí ń bẹ lábẹ́ ọ̀run.’ (Kol 1:6, 23) Láti ìgbà náà wá, ìhìn rere ti tipa báyìí dé “apá ibi jíjìnnà jù lọ ní ilẹ̀ ayé.”

[Àwòrán ilẹ̀ tó wà ní ojú ìwé 32]

(Láti rí bá a ṣe to ọ̀rọ̀ sójú ìwé, wo ìtẹ̀jáde náà gan-an)

Bí Ẹ̀sìn Kristẹni Ṣe Gbilẹ̀

Àwọn Ibi Tí A Ti Kọ́kọ́ Wàásù Ìhìn Rere Náà

B1 ÍLÍRÍKÓNÌ

B1 ÍTÁLÌ

B1 Róòmù

D1 MAKEDÓNÍÀ

D2 GÍRÍÌSÌ

D2 Áténì

D2 KÍRÉTÈ

D3 Kírénè

D3 LÍBÍÀ

E1 BÍTÍNÍÀ

E2 GÁLÁTÍÀ

E2 ÉṢÍÀ

E2 FÍRÍJÍÀ

E2 PANFÍLÍÀ

E2 KÍPÍRỌ́SÌ

E3 ÍJÍBÍTÌ

E4 ETIÓPÍÀ

Ẹ1 PỌ́ŃTÙ

Ẹ2 KAPADÓKÍÀ

Ẹ2 SÌLÍṢÍÀ

Ẹ2 MESOPOTÁMÍÀ

Ẹ2 SÍRÍÀ

Ẹ3 SAMÁRÍÀ

Ẹ3 Jerúsálẹ́mù

Ẹ3 JÙDÍÀ

F2 MÍDÍÀ

F3 Bábílónì

F3 ÉLÁMÙ

F4 ÁRÉBÍÀ

G2 PÁTÍÀ

[Omi]

D2 Òkun Mẹditaréníà

E1 Òkun Dúdú

Ẹ4 Òkun Pupa

F3 Ibi Tí Òkun Ti Ya Wọ Ilẹ̀ Páṣíà

[Àwòrán ilẹ̀ tó wà ní ojú ìwé 32, 33]

(Láti rí bá a ṣe to ọ̀rọ̀ sójú ìwé, wo ìtẹ̀jáde náà gan-an)

Ìrìn Àjò Pọ́ọ̀lù

Ìrìn Àjò Míṣọ́nnárì Àkọ́kọ́ (Iṣe 13:1-14:28)

GB3 Áńtíókù (ti Síríà)

GB3 Séléúkíà

G4 KÍPÍRỌ́SÌ

G3 Sálámísì

G4 Páfósì

G3 PANFÍLÍÀ

F3 Pẹ́gà

F3 PÍSÍDÍÀ

F2 Áńtíókù (ti Písídíà)

G2 Íkóníónì

G2 LIKAÓNÍÀ

G2 Lísírà

G3 Déébè

G2 Lísírà

G2 Íkóníónì

F2 Áńtíókù (ti Písídíà)

F3 PÍSÍDÍÀ

G3 PANFÍLÍÀ

F3 Pẹ́gà

F3 Atalíà

GB3 Áńtíókù (ti Síríà)

Ìrìn Àjò Míṣọ́nnárì Ẹlẹ́ẹ̀kejì (Iṣe 15:36–18:22)

GB3 Áńtíókù (ti Síríà)

GB3 SÍRÍÀ

GB3 SÌLÍṢÍÀ

GB3 Tásù

G3 Déébè

G2 Lísírà

G2 Íkóníónì

F2 Áńtíókù (ti Písídíà)

F2 FÍRÍJÍÀ

G2 GÁLÁTÍÀ

Ẹ2 MÁÍSÍÀ

Ẹ2 Tíróásì

Ẹ1 SÁMÓTÍRÁSÌ

E1 Neapólísì

E1 Fílípì

D1 MAKEDÓNÍÀ

E1 Áńfípólì

E1 Tẹsalóníkà

E1 Bèróà

D2 GÍRÍÌSÌ

E2 Áténì

E2 Kọ́ríńtì

E3 ÁKÁYÀ

Ẹ2 Éfésù

G4 Kesaréà

GB5 Jerúsálẹ́mù

GB3 Áńtíókù (ti Síríà)

Ìrìn Àjò Míṣọ́nnárì Ẹlẹ́ẹ̀kẹta (Iṣe 18:22–21:19)

GB3 SÍRÍÀ

GB3 Áńtíókù (ti Síríà)

G2 GÁLÁTÍÀ

F2 FÍRÍJÍÀ

GB3 SÌLÍṢÍÀ

GB3 Tásù

G3 Déébè

G2 Lísírà

G2 Íkóníónì

F2 Áńtíókù (ti Písídíà)

Ẹ2 Éfésù

Ẹ2 ÉṢÍÀ

Ẹ2 Tíróásì

E1 Fílípì

D1 MAKEDÓNÍÀ

E1 Áńfípólì

E1 Tẹsalóníkà

E1 Bèróà

D2 GÍRÍÌSÌ

E2 Áténì

E2 Kọ́ríńtì

E1 Bèróà

E1 Tẹsalóníkà

E1 Áńfípólì

E1 Fílípì

Ẹ2 Tíróásì

Ẹ2 Ásósì

Ẹ2 Mítílénè

Ẹ2 KÍÓSÌ

Ẹ2 SÁMÓSÌ

Ẹ3 Mílétù

Ẹ3 Kọ́sì

Ẹ3 RÓDÉSÌ

F3 Pátárà

GB4 Tírè

GB4 Tólémáísì

G4 Kesaréà

GB5 Jerúsálẹ́mù

Ìrìn Àjò sí Róòmù (Iṣe 23:11–28:31)

GB5 Jerúsálẹ́mù

G4 Kesaréà

GB4 Sídónì

F3 Máírà

F3 LÍKÍÀ

Ẹ3 Kínídọ́sì

E3 KÍRÉTÈ

E4 KÁÚDÀ

A3 MÁLÍTÀ

A3 SÍSÍLÌ

A3 Sírákúsì

A1 ÍTÁLÌ

B2 Régíómù

A1 Pútéólì

A1 Róòmù

Ojú Ọ̀nà Ẹlẹ́sẹ̀ (Wo inú ìtẹ̀jáde)

[Ìjọ méje]

Ẹ2 Págámù

Ẹ2 Tíátírà

Ẹ2 Sádísì

Ẹ2 Símínà

Ẹ2 Éfésù

F2 Filadẹ́fíà

F2 Laodíkíà

[Àwọn ìbòmíì]

Ẹ3 PÁTÍMỌ́SÌ

F2 Kólósè

F5 Alẹkisáńdíríà

F5 ÍJÍBÍTÌ

G1 BÍTÍNÍÀ

G5 Jópà

G5 Lídà

G5 Gásà

GB1 PỌ́ŃTÙ

GB2 KAPADÓKÍÀ

GB4 Damásíkù

GB4 Pẹ́là

[Omi]

Òkun Mẹditaréníà

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 33]

Gbọ̀ngàn ìwòran ní Mílétù, ìlú tí Pọ́ọ̀lù ti pàdé àwọn alàgbà tó wá láti Éfésù

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 33]

Pẹpẹ Súúsì ní Págámù. Àwọn Kristẹni tó wà ní ìlú yìí gbé “ni ibi tí ìtẹ́ Sátánì wà”—Iṣi 2:13