Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Bí Ilẹ̀ Ísírẹ́lì Ṣe Rí Nígbà Ayé Dáfídì àti Sólómọ́nì

Bí Ilẹ̀ Ísírẹ́lì Ṣe Rí Nígbà Ayé Dáfídì àti Sólómọ́nì

ỌLỌ́RUN ṣèlérí pé òun á fún irú-ọmọ Ábúrámù ní ilẹ̀ náà “láti odò Íjíbítì dé odò . . . Yúfírétì.” (Jẹ 15:18; Ẹk 23:31; Di 1:7, 8; 11:24) Nǹkan bí irínwó ọdún kọjá lẹ́yìn ìgbà tí Jóṣúà wọ ilẹ̀ Kénáánì, kí Ilẹ̀ Ìlérí tó gbòòrò dé ibi ti Ọlọ́run ṣèlérí.

Dáfídì Ọba ṣẹ́gun ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Árámù ní Sóbà ń ṣàkóso, èyí tó fẹ̀ débi odò Yúfírétì ní ìhà àríwá Síríà. a Ní ìhà gúúsù, ṣíṣẹ́gun tí Dáfídì ṣẹ́gun àwọn Filísínì mú kí ilẹ̀ tó ń ṣàkóso gbòòrò dé ẹnubodè Íjíbítì.—2Sa 8:3; 1Kr 18:1-3; 20:4-8; 2Kr 9:26.

Lẹ́yìn náà, Sólómọ́nì ṣàkóso “láti Odò [Yúfírétì] dé ilẹ̀ àwọn Filísínì àti dé ààlà Íjíbítì.” Àkóso rẹ̀ jẹ́ àpẹẹrẹ àkóso alálàáfíà ti Mèsáyà náà. (1Ọb 4:21-25; 8:65; 1Kr 13:5; Sm 72:8; Sek 9:10) Síbẹ̀, ohun tí a sábà máa ń sọ ni pé Ísírẹ́lì gbòòrò láti “Dánì dé Bíá-ṣébà.”—2Sa 3:10; 2Kr 30:5.

Sólómọ́nì Ọba ṣàìgbọràn sí Ọlọ́run nípa kíkó àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ẹṣin jọ. (Di 17:16; 2Kr 9:25) Ó rọrùn fún un láti kó ìwọ̀nyí gba àwọn ọ̀nà àti òpópó tó já síra kọjá. (Joṣ 2:22; 1Ọb 11:29; Ais 7:3; Mt 8:28) Ìwọ̀nba díẹ̀ la mọ̀ nípa àwọn ọ̀nà àti òpópó wọ̀nyí, irú bí “òpópó tí ó gòkè lọ láti Bẹ́tẹ́lì sí Ṣékémù àti síhà gúúsù Lẹ́bónà.”—Ond 5:6; 21:19.

Ìwé The Roads and Highways of Ancient Israel sọ pé: “Ìṣòro kan tí a sábà máa ń ní tí a bá ń ṣàyẹ̀wò bí àwọn ọ̀nà ṣe já síra ní ìlú Ísírẹ́lì ìgbàanì ni pé kò sí àmì tó ṣeé fojú rí mọ́, tí a lè fi mọ bí ojú ọ̀nà orílẹ̀-èdè náà ṣe rí nígbà Májẹ̀mú Láéláé, nítorí pé wọn kì í la títì [ní ìgbà yẹn].” Síbẹ̀, ìrísí àyíká àti àwọn àwókù tí àwọn awalẹ̀pìtàn hú jáde ní ìlú náà fi ẹ̀rí hàn pé ó ṣeé ṣe kí irú àwọn ọ̀nà bẹ́ẹ̀ wà tẹ́lẹ̀ rí.

Bí ọ̀nà bá ṣe rí ló ń pinnu ibi tí àwọn agbo ọmọ ogun á gbà kọjá. (1Sa 13:17, 18; 2Ọb 3:5-8) Kí àwọn Filísínì bàa lè gbógun ti Ísírẹ́lì, wọ́n gba Ékírónì àti Gátì kọjá lọ sí àgbègbè tó wà ní “àárín Sókóhì àti Ásékà.” Àwọn ọmọ ogun Sọ́ọ̀lù sì pàdé wọn níbẹ̀ ní “pẹ̀tẹ́lẹ̀ rírẹlẹ̀ Éláhì.” Lẹ́yìn tí Dáfídì pa Gòláyátì, àwọn Filísínì sá padà lọ sí Gátì àti Ékírónì, Dáfídì sì gòkè padà lọ sí Jerúsálẹ́mù.—1Sa 17:1-54.

Ibi àwọn ojú ọ̀nà àdáyébá tó gba Ṣẹ́fẹ́là kọjá lọ sí àwọn òkè Jùdíà ni Lákíṣì (E10), Ásékà (E9) àti Bẹti-ṣémẹ́ṣì (E9) wà. Ìyẹn ló mú kí àwọn ìlú wọ̀nyí jẹ́ ibi tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ti lè bẹ́gi dínà àwọn ọ̀tá tí wọ́n bá gba Ojú Ọ̀nà Òkun kọjá láti wá gbógun ja ìlú wọn.—1Sa 6:9, 12; 2Ọb 18:13-17.

[Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]

a Ààlà ilẹ̀ àwọn ọmọ Rúbẹ́nì gbòòrò dé ibi Aṣálẹ̀ Síríà. Ní ìkángun ìlà oòrùn aṣálẹ̀ yìí ni odò Yúfírétì wà.—1Kr 5:9, 10.

[Àwọn àwòrán ilẹ̀ tó wà ní ojú ìwé 17]

(Láti rí bá a ṣe to ọ̀rọ̀ sójú ìwé, wo ìtẹ̀jáde náà gan-an)

Àwọn Àgbègbè àti Ojú Ọ̀nà Ní Àkókò Àwọn Ọba

Àwọn Ààlà (Lákòókò Sólómọ́nì)

Tífísà

Hámátì

Tádímórì

Bérótáì (Kúnì?)

Sídónì

Damásíkù

Tírè

Dánì

Jerúsálẹ́mù

Gásà

Áróérì

Bíá-ṣébà

Támárì

Esioni-gébérì

Élátì (Élótì)

[Àwọn Odò]

Yúfírétì

A. O. Íjíbítì

Dáfídì àti Sólómọ́nì (àwọn ọ̀nà)

B10 Gásà

D8 Jópà

D9 Áṣídódì

D10 Áṣíkẹ́lónì

D11 Síkílágì

D12 AGINJÙ PÁRÁNÌ

E5 Dórì

E6 Héfà

E8 Áfékì

E8 Rámà

E9 Ṣáálíbímù

E9 Gésérì

E9 Mákásì

E9 Ékírónì

E9 Bẹti-ṣémẹ́ṣì

E9 Gátì

E9 Ásékà

E10 Sókò(hì)

E10 Ádúlámù

E10 Kéílà

E10 Lákíṣì

E11 Játírì

E12 Bíá-ṣébà

Ẹ2 Tírè

Ẹ4 Kábúlù

Ẹ5 Jókínéámù (Jókíméámù?)

Ẹ5 Mẹ́gídò

Ẹ6 Táánákì

Ẹ6 Árúbótì

Ẹ7 Pírátónì

Ẹ8 Lébónà

Ẹ8 Sérédà

Ẹ8 Bẹ́tẹ́lì

Ẹ9 Bẹti-hórónì Ìsàlẹ̀

Ẹ9 Bẹti-hórónì Òkè

Ẹ9 Gébà

Ẹ9 Gíbéónì

Ẹ9 Gíbíà

Ẹ9 Kiriati-jéárímù

Ẹ9 Nóbù

Ẹ9 Baali-pérásímù

Ẹ9 Jerúsálẹ́mù

Ẹ9 Bẹ́tílẹ́hẹ́mù

Ẹ10 Tékóà

Ẹ10 Hébúrónì

Ẹ11 Sífù

Ẹ11 Hóréṣì?

Ẹ11 Kámẹ́lì

Ẹ11 Máónì

Ẹ11 Éṣítémóà

F5 Ẹ́ń-dórì

F5 Ṣúnémù

F5 Jésíréélì

F6 Bẹti-ṣéánì

F7 Tírísà

F7 Ṣékémù

F8 Sárétánì

F8 Ṣílò

F8 Ọ́fírà?

F9 Jẹ́ríkò

F11 Ẹ́ń-gédì

G2 Ebẹli-bẹti-máákà

G2 Dánì

G3 Hásórì

G3 MÁÁKÀ

G5 Lo-débárì (Débírì)

G5 Rógélímù

G6 Ebẹli-méhólà

G7 Súkótù

G7 Máhánáímù

GB1 SÍRÍÀ

GB4 GÉṢÚRÌ

GB6 Ramoti-gílíádì

GB8 Rábà

GB9 Médébà

GB11 Áróérì

GB12 MÓÁBÙ

I4 Hélámù?

I9 ÁMÓNÌ

[Ojú Ọ̀nà Pàtàkì]

D10 Ojú Ọ̀nà Òkun

GB6 Ojú Ọ̀nà Ọba

[Àwọn Òkè]

F5 Òkè Gíbóà

[Omi]

D8 Òkun Mẹditaréníà (Òkun Ńlá)

F10 Òkun Iyọ̀ (Òkun Òkú)

G4 Òkun Gálílì

[Ìsun Omi tàbí Kànga]

Ẹ9 Ẹ́ń-rógélì

[Àwọn àwòrán tó wà ní ojú ìwé 16]

Lápá ọ̀tún: Àfonífojì Éláhì tó dojú kọ àwọn òkè Júdà tó wà ní ìhà ìlà oòrùn

Ìsàlẹ̀: Àwọn ojú ọ̀nà tó já síra mú kó ṣeé ṣe láti rìn yí ká Ilẹ̀ Ìlérí