Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ilẹ̀ Ọba Gíríìsì àti Ti Róòmù Nípa Lórí Àwọn Júù

Ilẹ̀ Ọba Gíríìsì àti Ti Róòmù Nípa Lórí Àwọn Júù

Ilẹ̀ Ọba Gíríìsì àti Ti Róòmù Nípa Lórí Àwọn Júù

IBI tí a mọ̀ sí Ilẹ̀ Ọba Gíríìsì bẹ̀rẹ̀ sí í gbòòrò láti ibi àwọn òkè ńlá Makedóníà. Níbi àwọn òkè ńlá yìí ni Alẹkisáńdà tó ṣẹ̀ṣẹ̀ lé díẹ̀ lẹ́ni ogún ọdún ti bẹ̀rẹ̀ sí í wá ọ̀nà àtiṣẹ́gun àwọn ìlú tó wà ní apá ìlà oòrùn. Lọ́dún 334 ṣááju Sànmánì Tiwa, ó darí àwọn ọmọ ogun rẹ̀ lọ sí Hẹ́lísípọ́ńtì (Dadinẹ́sì), níbi ààlà ilẹ̀ Yúróòpù àti Éṣíà. Bí “àmọ̀tẹ́kùn” tí ń bẹ́ gìjà-gìjà, làwọn Gíríìkì tí ń jagun fún Alẹkisáńdà yìí ṣe ń jà lọ ràì tí wọ́n sì ń ṣẹ́gun. (Da 7:6) Alẹkisáńdà borí àwọn ará Páṣíà nítòsí Tírọ́ì tó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ibi Odò Gíráníkọ́sì, Alẹkisáńdà sì ṣẹ́gun wọn ní ìlú Ísọ́sì.

Àwọn Gíríìkì kógun wọ Síríà àti Fòníṣíà, wọ́n sì ṣẹ́gun ìlú Tírè lẹ́yìn tí wọ́n ti dó tì í fún oṣù méje. (Isk 26:4, 12) Alẹkisáńdà dá Jerúsálẹ́mù sí, ṣùgbọ́n ó ṣẹ́gun Gásà. (Sek 9:5) Gbàrà tó dé Íjíbítì, ló tẹ ìlú Alẹkisáńdíríà tó wá di ojúkò káràkátà àti ẹ̀kọ́ ìwé dó. Nígbà tí Alẹkisáńdà tún padà gba Ilẹ̀ Ìlérí kọjá, ó tún ṣẹ́gun àwọn ará Páṣíà, ní Gọgamílà, tó wà nítòsí àwókù Nínéfè.

Alẹkisáńdà dorí kọ gúúsù láti ṣẹ́gun àwọn ibùdó àkóso Páṣíà tó wà ní Bábílónì, Ṣúṣánì (Súsà) àti Pasẹpólísì. Lẹ́yìn náà ló yára la gbogbo ilẹ̀ abẹ́ àkóso Páṣíà kọjá, títí lọ dé ibi Odò Íńdọ́sì tó wà ní ilẹ̀ Pakísítánì òde òní. Láàárín ọdún mẹ́jọ péré, Alẹkisáńdà ti ṣẹ́gun orílẹ̀-èdè tó pọ̀ jù lọ lára gbogbo orílẹ̀-èdè tó wà láyé nígbà yẹn. Ṣùgbọ́n ní ọdún 323 ṣááju Sànmánì Tiwa, nígbà tó ti di ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n, àrùn ibà lù ú pa ní Bábílónì.—Da 8:8.

Ọwọ́ àwọn Hélénì [ará Gíríìsì] ranlẹ̀ dáadáa ní Ilẹ̀ Ìlérí. Àwọn kan tó ti wà lára àwọn ọmọ ogun Alẹkisáńdà rí ń gbé ní àgbègbè náà. Nígbà tó sì fi máa di ọ̀rúndún kìíní, àwùjọ àwọn tí ń sọ èdè Gíríìkì ti tẹ ìlú (Dekapólì) dó. (Mt 4:25; Mk 7:31) Bẹ́ẹ̀ ló di pé Ìwé Mímọ́ lédè Hébérù wà ní èdè Gíríìkì. Kóínè (èdè Gíríìkì ti tẹrú tọmọ ń sọ) ni wọ́n sì fi tan ẹ̀kọ́ Kristẹni kálẹ̀ nílé lóko.

Ilẹ̀ Ọba Róòmù

Kí ló ń ṣẹlẹ̀ ní ìwọ̀ oòrùn? Ìlú Róòmù—tí kò ju àpapọ̀ àwọn abúlé kóó-kòò-kó kan létí Odò Táíbà lọ tẹ́lẹ̀—wá di àjànàkú tí ń migbó kìjikìji. Ní àsẹ̀yìnwá àsẹ̀yìnbọ̀, ẹgbẹ́ ọmọ ogun tí kì í bà á tì àti ìjọba àjùmọ̀ṣe tí Ilẹ̀ Ọba Róòmù ń lò mú kó ṣeé ṣe fún un láti gba gbogbo àgbègbè tó wà lábẹ́ àkóso àwọn ọ̀gágun Alẹkisáńdà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin. Nígbà tó fi máa di ọ̀rúndún 30 ṣááju Sànmánì Tiwa, Ilẹ̀ Ọba Róòmù ti di àràbà tápá ò lè ká mọ́, ìyẹn sì jẹ́ àpẹẹrẹ ọ̀nà tó kọ́kọ́ gbà fara hàn gẹ́gẹ́ bí ‘ẹranko tí ń bani lẹ́rù’ tí Dáníẹ́lì rí nínú ìran.—Da 7:7.

Ilẹ́ Ọba Róòmù gbilẹ̀ láti ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì títí lọ dé Àríwá Áfíríkà, ó sì gbilẹ̀ láti Òkun Àtìláńtíìkì tó fi dé Ibi Tí Òkun Ti Ya Wọ Ilẹ̀ Páṣíà. Nítorí pé ilẹ̀ ọba náà yí òkun Mẹditaréníà ká, Òkun Wa (Mare Nostrum) làwọn ará Róòmù ń pè é.

Abẹ́ àkóso Ilẹ̀ Ọba Róòmù ni àwọn Júù wà, nítorí náà, Ilẹ̀ Ọba Róòmù nípa lórí wọn. (Mt 8:5-13; Iṣe 10:1, 2) Ìrìbọmi Jésù àti ikú rẹ̀ wáyé nígbà ìṣàkóso Olú Ọba Tìbéríù. Àwọn alákòóso ìlú Róòmù kan ṣenúnibíni lọ́nà rírorò sí àwọn Kristẹni ṣùgbọ́n wọn ò lè pa ìsìn tòótọ́ run. Lẹ́yìn ọ̀rúndún mẹ́tàlá, ẹ̀ya àwọn ará Jámánì ní àríwá àti àwọn akóguntini tí ń ṣí kirí ní ìlà oòrùn, tẹ ilẹ̀ ọba náà lórí ba.

[Àwòrán ilẹ̀ tó wà ní ojú ìwé 26]

(Láti rí bá a ṣe to ọ̀rọ̀ sójú ìwé, wo ìtẹ̀jáde náà gan-an)

Ilẹ̀ Ọba Gíríìsì

Lẹ́yìn ikú Alẹkisáńdà, mẹ́rin lára àwọn ọ̀gágun rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso ilẹ̀ ọba gbígbòòro náà

Kasáńdà

Lisimákù

Tólẹ́mì Kìíní

Sẹ̀lẹ́úkọ́sì Kìíní

A2 ▪ GÍRÍÌSÌ

A2 ▪ Áténì

A2 ▪ ÁKÁYÀ

A3 ○ Kírénè

A3 ○ LÍBÍÀ

B2 ▫ Bìsáńṣíọ̀mù

B3 ○ KÍPÍRỌ́SÌ

B4 ○ No-ámónì (Tíbésì)

D3 Pálímírà (Tádímórì)

D3 ○ Gérásà

D3 ○ Filadẹ́fíà

D3 ○ Jerúsálẹ́mù

D5 ○ Síénè

G2 • Alẹkisáńdíríà Magiánà

Ojú Ọ̀nà Alẹkisáńdà

A2 ▪ MAKEDÓNÍÀ

A2 ▪ Pẹ́là

A2 ▫ TÍRÉSÌ

B2 ▫ Tírọ́ì

B2 ▫ Sádísì

B2 ▫ Éfésù

B2 ▫ Gọ́díọ̀mù

D2 ▫ Áńkarà

D3 • Tásù

D3 • Ísọ́sì

D3 • Áńtíókù (ti Síríà)

D3 ○ Tírè

D4 ○ Gásà

B4 ○ ÍJÍBÍTÌ

B4 ○ Mémúfísì

B4 ○ Alẹkisáńdíríà

B4 ○ Omi Aṣálẹ̀ Síwà

B4 ○ Mémúfísì

D4 ○ Gásà

D3 ○ Tírè

D3 ○ Damásíkù

D3 • Alépò

E3 • Nísíbísì

E3 • Gọgamílà

E3 • Bábílónì

E3 • Ṣúṣánì

Ẹ4 • PÁṢÍÀ

Ẹ4 • Pasẹpólísì

Ẹ4 • Paságedì

Ẹ3 • MÍDÍÀ

Ẹ3 • Ekibátánà

Ẹ3 • Rééjì

Ẹ3 • Hẹkatómífílọ́sì

Ẹ3 • PÁTÍÀ

G3 • ÁRÍÀ

G3 • Alẹkisáńdíríà ti Áríà

G3 • Alẹkisáńdíríà Purọfitásíà

F4 • DIRANGÍÁNÀ

G4 • ARAKÓṢÍÀ

G4 • Alẹkisáńdíríà ti Arakoṣíórọ̀mù

GB3 • Kábúlù

G3 • Dirapúsákà

GB3 • Alẹkisáńdíríà Tibi Odò Ókísọ̀

G3 • Dirapúsákà

G3 • BÁKÍTÍRÍÀ

G3 • Bákítírà

G2 • Dábẹ́ńtì

G2 • SOGIDÍÁNÀ

G2 • Marakáńdà

G2 • Bùkárà

G2 • Marakáńdà

GB2 • Alẹkisáńdíríà Ẹ́síkátè

G2 • Marakáńdà

G2 • Dábẹ́ńtì

G3 • Bákítírà

G3 • BÁKÍTÍRÍÀ

G3 • Dirapúsákà

GB3 • Kábúlù

GB3 • Tásílà

GB5 • ÍŃDÍÀ

GB4 • Alẹkisáńdíríà

G4 • GEDIRÓSÍÀ

F4 • Púrà

Ẹ4 • PÁṢÍÀ

F4 • Alẹkisáńdíríà

F4 • KARIMÁNÍÀ

Ẹ4 • Paságedì

Ẹ4 • Pasẹpólísì

Ẹ3 • Ṣúṣánì

E3 • Bábílónì

[Àwọn ìbòmíì]

A3 KÍRÉTÈ

E4 ARÉBÍÀ

[Omi]

B3 Òkun Mẹditaréníà

D5 Òkun Pupa

Ẹ4 Ibi Tí Òkun Ti Ya Wọ Ilẹ̀ Páṣíà

G5 Òkun Arébíà

[Odò]

B4 Náílì

E3 Yúfírétì

E3 Tígírísì

G4 Íńdọ́sì

[Àwòrán ilẹ̀ tó wà ní ojú ìwé 27]

(Láti rí bá a ṣe to ọ̀rọ̀ sójú ìwé, wo ìtẹ̀jáde náà gan-an)

Ilẹ̀ Ọba Róòmù

A1 ILẸ̀ GẸ̀Ẹ́SÌ

A3 SÍPÉÈNÌ

B1 JÀMÁNÍÀ

B2 GỌ́Ọ̀LÙ

B2 ÍTÁLÌ

B2 Róòmù

B3 Kátéèjì

D2 ÍLÍRÍKÓNÌ

D3 GÍRÍÌSÌ

D3 Ákíṣíọ́mù

D3 Kírénè

E2 Bìsáńṣíọ̀mù (Kọnsitantinópù)

E3 ÉṢÍÀ KÉKERÉ

E3 Éfésù

E3 Alépò

E3 Áńtíókù (ti Síríà)

E3 Damásíkù

E3 Gérásà (Járáṣì)

E3 Jerúsálẹ́mù

E3 Alẹkisáńdíríà

E4 ÍJÍBÍTÌ

[Omi]

A2 Òkun Àtìláńtíìkì

D3 Òkun Mẹditaréníà

E2 Òkun Dúdú

E4 Òkun Pupa

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 26]

Nígbà tí Tólẹ́mì Kejì tún ìlú Rábà kọ́ tán, ó sọ ọ́ ní Filadẹ́fíà. Àwókù gbọ̀ngàn ìṣeré ńlá kan ní ìlú Róòmù rèé

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 27]

Ìlú Gérásà (Járáṣì) ní Dekapólì

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 27]

Àwọn ojú ọ̀nà tí ilẹ̀ ọba Róòmù ṣe, bí irú èyí nítòsí Alépò, gbòòrò títí lọ dé Yúróòpù, Àríwá Áfíríkà àti Àárín Gbùngbùn Ìlà Oòrùn ayé. Àwọn Kristẹni rìnrìn àjò gba ọ̀nà yìì kọjá láti tan òtítọ́ Bíbélì kálẹ̀