Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

‘Nígbà Tí Jèhófà Gbé Àwọn Onídàájọ́ Dìde’

‘Nígbà Tí Jèhófà Gbé Àwọn Onídàájọ́ Dìde’

‘Nígbà Tí Jèhófà Gbé Àwọn Onídàájọ́ Dìde’

KÒ ṢÒRO láti rí ibi tí Òkè Tábórì (F4) wà lórí àwòrán ilẹ̀. Gúúsù ìwọ̀-oòrùn Òkun Gálílì ló wà, níbi Àfonífojì Jésíréélì. Ìwọ ṣáà fojú inú wo ẹgbàárùn-ún [10,000] ẹgbẹ́ ọmọ ogun tí wọ́n pé jọ sórí òkè náà. Jèhófà lo Onídàájọ́ Bárákì àti Dèbórà, wòlíì obìnrin, láti kó àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jọ láti gbógun lọ bá Jábínì ọba ilẹ̀ Kénáánì tó ti ń fojú àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì gbolẹ̀ fún ogún ọdún. Lábẹ́ ìdarí Sísérà tó jẹ́ olórí ogun, ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún [900] kẹ̀kẹ́ ogun Jábínì Ọba, tí wọ́n ní àwọn dòjé irin tó lè pani kú fin-ínfin-ín, wọ́n gbéra láti Háróṣétì wá sí ipadò gbígbẹ ti odò Kíṣónì, tó wà láàárín Mẹ́gídò àti Òkè Tábórì.

Onídàájọ́ Bárákì kó àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì lọ sí àfonífojì náà láti lọ wà á kò pẹ̀lú agbo ọmọ ogun Sísérà. Jèhófà gba ogun yìí jà fún àwọn ènìyàn rẹ̀ nípa jíjẹ́ kí alagbalúgbú omi ya dé lójijì láti sọ ipadò náà di ẹrẹ̀ pẹ̀tẹ̀pẹ̀tẹ̀, tí àwọn kẹ̀kẹ́ ogun Sísérà sì ń rì sí i. Èyí mú kí jìnnìjìnnì bo àwọn ará Kénáánì. (Ond 4:1-5:31) Ọ̀kan péré nìyẹn lára àwọn ọ̀nà tí Ọlọ́run gbà jà fún Ísírẹ́lì tó sì fi àwọn ọ̀tá wọn lé wọn lọ́wọ́ ní àkókò àwọn Onídàájọ́.

Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ti ṣẹ́gun àwọn ará Kénáánì tán, àwọn ẹ̀yà Ísírẹ́lì jogún ilẹ̀ wọn. Wàyí o, kíyè sí ibi tí àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà Léfì fìdí kalẹ̀ sí. Àwọn ìlú tó di ti ẹ̀yà Síméónì, tó jẹ́ ẹ̀yà kékeré, wà nínú ìpínlẹ̀ ti Júdà. Lẹ́yìn ikú Jóṣúà, ìfàsẹ́yìn bá orílẹ̀-èdè náà, wọ́n ya ìyàkuyà nípa tẹ̀mí, wọ́n sì di oníwàkiwà. Ísírẹ́lì sì wá “wà nínú hílàhílo gidigidi” nítorí pé àwọn ọ̀tà rẹ̀ fòòró rẹ̀. Nígbà tí ìyọ́nú tún sún Jèhófà láti ṣíjú àánú wò wọ́n, ‘Ó gbé àwọn onídàájọ́ dìde’—àwọn ọkùnrin méjìlá tí wọ́n kún fún ìgbàgbọ́ àti ìgboyà—tí wọ́n ń gba Ísírẹ́lì sílẹ̀ fún odindi ọ̀ọ́dúnrún [300] ọdún.—Ond 2:15, 16, 19.

Gídíónì Onídàájọ́ lo ọ̀ọ́dúnrún [300] ọmọ ogun tí kò dira púpọ̀, ṣùgbọ́n ti ẹsẹ̀ wọ́n yá nílẹ̀, láti gbógun ti ọ̀kẹ́ mẹ́fà ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbàájọ [135,000] jagunjagun tó ti Mídíánì wá. Àárín Òkè Gíbóà àti Òkè Mórè ni wọ́n ti ja ìjà ọ̀hún. Nígbà tí Gídíónì ṣẹ́gun àwọn ọ̀tà náà, ó lépa wọn lọ sínú aṣálẹ̀, ní ìlà oòrùn.—Ond 6:1-8:32.

Jẹ́fútà, ọmọ Gílíádì látinú ẹ̀yà Mánásè, gba àwọn ìlú Ísírẹ́lì tó wà ní ìlà oòrùn Jọ́dánì sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ọmọ Ámónì tí ń pọ́n wọn lójú. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé Ojú Ọ̀nà Ọba, téèyàn lè gbà já sí Ramoti-gílíádì àti àgbègbè Áróérì ni Jẹ́fútà gbà kó bàa lè ṣẹ́gun.—Ond 11:1-12:7.

Àgbègbè etíkun tó yí Gásà àti Áṣíkẹ́lónì ká ni Sámúsìnì ti fi àjùlọ han àwọn Filísínì. Gásà wà ní àgbègbè tó lómi dáadáa tó sì dára gan-an fún iṣẹ́ àgbẹ̀. Sámúsìnì lo ọ̀ọ́dúnrún [300] kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ láti tanná ran àwọn pápá ọkà, àwọn ọgbà àjàrà àti àwọn oko ólífì àwọn Filísínì.—Ond 15:4, 5.

Gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ Bíbélì ṣe fi hàn, tàbí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà tí àwọn onídàájọ́ náà ti wá ṣe fi hàn, kò sí ibi tí àwọn onídàájọ́ ò sí ní ilẹ̀ ìlérí. Ibi yòówù kí wọ́n ti ṣe iṣẹ́ wọn, ohun tó dájú ni pé lákòókò ìṣòro, Jèhófà ràdọ̀ bo àwọn èèyàn rẹ̀ tó fi ìrònúpìwàdà hàn.

[Àwòrán ilẹ̀ tó wà ní ojú ìwé 15]

(Láti rí bá a ṣe to ọ̀rọ̀ sójú ìwé, wo ìtẹ̀jáde náà gan-an)

Ẹ̀yà Àwọn Onídàájọ́

Àwọn Onídàájọ́

1. Ótíníẹ́lì (Tribe of Mánásè)

2. Éhúdù (Tribe of Júdà)

3. Ṣámúgárì (Tribe of Júdà)

4. Bárákì (Tribe of Náfútálì)

5. Gídíónì (Tribe of Ísákárì)

6. Tólà (Tribe of Mánásè)

7. Jáírì (Tribe of Mánásè)

8. Jẹ́fútà (Tribe of Gádì)

9. Íbísánì (Tribe of Áṣérì)

10. Ẹ́lónì (Tribe of Sébúlúnì)

11. Ábídónì (Tribe of Éfúráímù)

12. Sámúsìnì (Tribe of Júdà)

Ààlà Ilẹ̀ Ẹ̀yà Kọ̀ọ̀kan (Wo inú ìtẹ̀jáde)

Àwọn Ìlú Àdádó ti Mánásè

Ẹ4 Dórì

Ẹ5 Mẹ́gídò

Ẹ5 Táánákì

F4 Ẹ́ń-dórì

F5 Bẹti-ṣéánì (Bẹti-ṣánì)

F5 Íbíléámù (Gati-rímónì)

Àwọn Ìlú Àdádó ti Síméónì

D9 Ṣárúhénì (Ṣááráímù) (Ṣílíhímù)

D10 Bẹti-lẹ́báótì (Bẹti-bírì)

E8 Étérì (Tókénì)

E9 Síkílágì

E9 Áyínì

E9 Hasari-súsà?

E9 Áṣánì

E9 Bíá-ṣébà

E10 Hasari-ṣúálì

Ẹ9 Étámì

Ẹ9 Bẹti-mákábótì

Ẹ9 Bẹ́túélì? (Kẹ́sílì?)

Ẹ9 Ṣébà? (Jéṣúà)

Ẹ10 Baalati-béérì (Báálì)

Ẹ10 Ésémù

Àwọn Ìlú Ìsádi Àwọn Ọmọ Léfì

Ẹ8 Hébúrónì

F3 Kédéṣì

F6 Ṣékémù

GB4 Gólánì

GB5 Ramoti-gílíádì

GB8 Bésérì

Ojú Ọ̀nà Pàtàkì

B10 Ojú Ọ̀nà Òkun

G10 Ojú Ọ̀nà Ọba

Àwọn Ẹ̀yà Ísírẹ́lì

DÁNÌ (D7)

E7 Jópà

Ẹ8 Sórà

JÚDÀ (D9)

D8 Áṣíkẹ́lónì

D9 Gásà

D9 Ṣárúhénì (Ṣááráímù) (Ṣílíhímù)

D10 Bẹti-lẹ́báótì (Bẹti-bírì)

D12 Ásímónì

D12 Kádéṣì

E7 Jábínéélì

E8 Étérì (Tókénì)

E9 Síkílágì

E9 Áyínì

E9 Hasari-súsà?

E9 Áṣánì

E9 Bíá-ṣébà

E10 Hasari-ṣúálì

Ẹ8 Léhì

Ẹ8 Bẹ́tílẹ́hẹ́mù

Ẹ8 Hébúrónì

Ẹ9 Étámì

Ẹ9 Bẹti-mákábótì

Ẹ9 Bẹ́túélì? (Kẹ́sílì?)

Ẹ9 Ṣébà? (Jéṣúà)

Ẹ10 Baalati-béérì (Báálì)

Ẹ10 Ésémù

ÁṢÉRÌ (Ẹ3)

Ẹ2 Tírè

Ẹ4 Háróṣétì

Ẹ4 Dórì

F1 Sídónì

MÁNÁSÈ (Ẹ5)

Ẹ6 Ṣámírù (Samáríà)

Ẹ6 Pírátónì

F6 Ṣékémù

G6 Ebẹli-méhólà

ÉFÚRÁÍMÙ (Ẹ7)

Ẹ7 Timunati-sérà

F6 Tápúà

F6 Ṣílò

F7 Bẹ́tẹ́lì (Lúsì)

NÁFÚTÁLÌ (F3)

F2 Bẹti-ánátì

F3 Kédéṣì

G3 Hásórì

SÉBÚLÚNÌ (F4)

Ẹ4 Bẹ́tílẹ́hẹ́mù

ÍSÁKÁRÌ (F5)

Ẹ5 Mẹ́gídò

Ẹ5 Kédéṣì (Kíṣíónì)

Ẹ5 Táánákì

F4 Ẹ́ń-dórì

F5 Bẹti-ṣítà

F5 Bẹti-ṣéánì (Bẹti-ṣánì)

F5 Íbíléámù (Gati-rímónì)

BẸ́ŃJÁMÍNÌ (F7)

F7 Gílígálì

F8 Jerúsálẹ́mù

DÁNÌ (G2)

G2 Dánì (Láíṣì)

MÁNÁSÈ (GB3)

GB4 Gólánì

GÁDÌ (I6)

G6 Súkótù

G6 Pénúélì

G6 Mísípà (Mísípè)

G7 Jógíbéhà

GB5 Ramoti-gílíádì

GB7 Rábà

GB7 Ebẹli-kérámímù

RÚBẸ́NÌ (GB8)

G7 Héṣíbónì

G9 Áróérì

GB7 Mínítì

GB8 Bésérì

[Àwọn ìbòmíì]

I1 Damásíkù

[Àwọn Òkè]

F4 Òkè Tábórì

F4 Mórè

F6 Òkè Ébálì

F5 Òkè Gíbóà

F6 Òkè Gérísímù

[Omi]

D5 Òkun Mẹditaréníà (Òkun Ńlá)

F9 Òkun Iyọ̀

G4 Òkun Gálílì

[Àwọn Odò]

B11 A.O. Íjíbítì

F4 Odò Jọ́dánì

G6 A.O. Jábókù

G9 A.O. Áánónì

G11 A.O. Séréédì

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 14]

Àfonífojì Jésíréélì wà ní ìsàlẹ̀ Òkè Tábórì, ní ìpínlẹ̀ Ísákárì

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 14]

Àwọn kẹ̀kẹ́ ẹṣin Sísérà rì sínú ẹrẹ̀ tó wà ní ojú ọ̀gbàrá Kíṣónì