Ohun Tó O Kọ́ Ní Apá 2
Kí ìwọ àti ẹni tó ń kọ́ ẹ lẹ́kọ̀ọ́ jíròrò àwọn ìbéèrè yìí:
Kí ni Ọlọ́run máa ṣe sí ẹ̀sìn èké?
(Wo Ẹ̀kọ́ 13.)
Ka Ẹ́kísódù 20:4-6.
Báwo ló ṣe máa ń rí lára Jèhófà táwọn èèyàn bá ń lo ère nínú ìjọsìn wọn?
(Wo Ẹ̀kọ́ 14.)
Ta ni Jésù?
(Wo Ẹ̀kọ́ 15.)
Èwo nínú àwọn ìwà àti ìṣe Jésù lo fẹ́ràn jù?
(Wo Ẹ̀kọ́ 17.)
Ka Jòhánù 13:34, 35 àti Ìṣe 5:42.
Àwọn wo ni Kristẹni tòótọ́ lóde òní? Kí ló mú kó o gbà pé Kristẹni tòótọ́ ni wọ́n?
Ta ni orí ìjọ Kristẹni, báwo ló sì ṣe ń darí rẹ̀?
(Wo Ẹ̀kọ́ 20.)
Ka Mátíù 24:14.
Báwo ni àsọtẹ́lẹ̀ yìí ṣe ń ṣẹ lónìí?
Àwọn wo lo ti wàásù ìhìn rere fún?
Ṣé o rò pé ìrìbọmi ṣe pàtàkì? Kí nìdí tó o fi sọ bẹ́ẹ̀?
(Wo Ẹ̀kọ́ 23.)
Báwo lo ṣe lè dáàbò bo ara ẹ lọ́wọ́ Sátánì àtàwọn ẹ̀mí èṣù?
(Wo Ẹ̀kọ́ 24.)
Kí nìdí tí Ọlọ́run fi dá wa?
(Wo Ẹ̀kọ́ 25.)
Kí nìdí táwa èèyàn fi ń jìyà tá a sì ń kú?
(Wo Ẹ̀kọ́ 26.)
Ka Jòhánù 3:16.
Kí ni Jèhófà ṣe fún wa ká lè bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú?
(Wo Ẹ̀kọ́ 27.)
Ka Oníwàásù 9:5.
Kí ló ń ṣẹlẹ̀ sáwọn tó ti kú?
Kí ni Jésù máa ṣe fún àìmọye èèyàn tó ti kú?
Kí ló mú kí Ìjọba Ọlọ́run dáa ju gbogbo ìjọba èèyàn lọ?
Ṣé o gbà pé Ìjọba Ọlọ́run ti ń ṣàkóso? Kí nìdí tó o fi sọ bẹ́ẹ̀? Ìgbà wo ló bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso?
(Wo Ẹ̀kọ́ 32.)